Ọbadiah 1 – YCB & JCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ọbadiah 1:1-21

1Ìran ti Ọbadiah.

1-21: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Am 1.11-12; Ml 1.2-5.Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu.

Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá:

A sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé,

“Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”

2“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí;

ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọpọ̀,

3Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ,

ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta,

tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga,

ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé,

‘ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’

4Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì,

bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀,

láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,”

ni Olúwa wí.

5“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá,

bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru,

Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́:

wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́?

Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá,

wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?

6Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau,

tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.

7Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ

ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ:

Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ;

àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́,

ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”

8Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà,

Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run,

àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?

9A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, Ìwọ Temani,

gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau

ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.

10Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ,

ìtìjú yóò bò ọ,

a ó sì pa ọ run títí láé.

11Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan,

ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ,

tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ

tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu,

ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.

12Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ,

ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀

ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda,

ní ọjọ́ ìparun wọn

ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀

ní ọjọ́ wàhálà wọn.

13Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ,

ní ọjọ́ àjálù wọn.

Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀

nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn.

Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó,

ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.

14Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà

láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò.

Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú

wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.

15“Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé

lórí gbogbo àwọn kèfèrí.

Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà;

ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.

16Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi

bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí

Wọn yóò mu wọn yóò sì mu àmutẹ́rùn

wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò wà rí

17Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni

Wọn yóò sì jẹ́ mímọ́

àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn

18Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná

àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná

ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko

wọn yóò fi iná sí i,

wọn yóò jo run.

Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.”

Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.

19Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau,

àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni

ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní.

Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria;

Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.

20Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani

yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati;

àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi

yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní

21Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá

láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau.

Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

Japanese Contemporary Bible

オバデヤ書 1:1-21

1

オバデヤの幻

1神である主は幻によって、これからエドムの地に起こることをオバデヤに示しました。

オバデヤは言いました。

「主から知らせがあった。

神は国々に使者を遣わして、

次のようにお命じになったと。

『よく聞け。軍を動員し、エドムを滅ぼすのだ。』

2エドムよ。わたしはおまえを国々の中で小さい者とし、

さげすまれる者としよう。

3おまえは人が寄りつけないような高い断崖に住んで、

高慢になっている。

『だれも、ここまで登って来られまい』と誇っている。

思い違いをしてはならない。

4おまえが鷲のように高く舞い上がり、

星の間に巣を設けても、

わたしはおまえを引きずり降ろす」

と主は言います。

5「夜中にどろぼうが来るほうが、はるかにましだ。

根こそぎ持って行きはしないから。

あるいは、ぶどう畑の実を全部盗まれるほうがましだ。

少なくとも落ちた実は残るだろうから。

6だがおまえは、隅から隅まで家捜しされ、奪われる。

宝はすべて見つけ出され、持ち去られる。

7同盟国はみな敵に回り、

この地からおまえを追い出そうとする。

平和を約束しながら、滅ぼすことを企んでいる。

信頼する友が罠をしかけ、

反撃はことごとく失敗する。

8その日、エドム中を捜しても、

賢い者など残っていない」

と主は言う。

「わたしがエドムの賢者たちを愚かにするからだ。

9テマンの最も強力な兵士もあわてふためき、

虐殺者を防げなくなる。

10どうして、そんな目に会うのだろうか。

それは兄弟イスラエルにしたことへの報いだ。

今、おまえの罪は白日のもとにさらされる。

何の抵抗もできず、さんざん辱しめられ、

永遠に切り捨てられる。

11イスラエルが困っていた時、見捨てたからだ。

イスラエルに侵入した者が財宝を持ち去り、

くじでエルサレムを分け合っていても、

知らん顔をして、指一本動かそうとしなかった。

まるで敵のようだった。

12おまえは、そうすべきではなかった。

侵入者がイスラエルを遠い異国へ連れ去るのを見て、

ほくそ笑むべきではなかった。

彼らの不幸を喜ぶべきではなかった。

彼らが困っている時にあざけるべきでなかった。

13そればかりか、災いにつけ込んで、

イスラエルの地に入り、略奪した。

彼らを犠牲にして豊かになったのだ。

14おまえは十字路に立って、逃げようとする者を殺した。

彼らが恐ろしい窮地に立たされた日に、

生き延びた者を捕らえ、敵の手に渡した。

15主はすぐにすべての国に復讐する。

イスラエルにしたとおりのことが、

おまえの身に起こる。

人にしたとおりのことが自分に返ってくる。

16わたしの聖なる山で、

おまえたちはわたしの罰の杯を飲んだ。

回りの国々も飲むことになる。

そうだ、飲んで、よろめきながらあとずさりし、

歴史から姿を消す。

そのような国々は、もう存在しなくなる。

17しかし、エルサレムは避難所となり、逃げ道となる。

イスラエルは再びその地を占領する。

18イスラエルは、

エドムの乾燥した平野に放たれた火となる。

そこには、だれも生き残らない。」

主が、そう語ったのです。

19そして、ネゲブに住む私の民は

エドムの丘陵地を占有し、

ユダの低地に住む者はペリシテの平野を所有し、

エフライムやサマリヤの平野を取り戻します。

ベニヤミンの部族はギルアデを所有します。

20捕囚のイスラエル人は帰って来て、

フェニキヤの海岸地帯を

遠く北のツァレファテまで占領します。

小アジヤに連れて行かれた者も故国に帰り、

ネゲブの辺境の村々を征服します。

21救う者たちがエルサレムに来て、

エドムすべてを支配するからです。

そして、主が王となられるのです。