1Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù,
wúrà dídára di àìdán!
Òkúta ibi mímọ́ wá túká
sí oríta gbogbo òpópó.
2Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye,
tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe
wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán
iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!
3Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn
fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn,
ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn
bí ògòǹgò ní aginjù.
4Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́
lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn;
àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ
Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.
5Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára
di òtòṣì ní òpópó.
Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀
ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.
6Ìjìyà àwọn ènìyàn mi
tóbi ju ti Sodomu lọ,
tí a sí ní ipò ní òjijì
láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.
7Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì,
wọ́n sì funfun ju wàrà lọ
wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa,
ìrísí wọn dàbí safire.
8Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú;
wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó.
Ara wọn hun mọ́ egungun;
ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.
9Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn
ju àwọn tí ìyàn pa;
tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò
fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.
10Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú
ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ
tí ó di oúnjẹ fún wọn
nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.
11Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀;
ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde.
Ó da iná ní Sioni
tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.
12Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́,
tàbí àwọn ènìyàn ayé,
wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ
odi ìlú Jerusalẹmu.
13Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì
àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà,
tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo
sílẹ̀ láàrín rẹ̀.
14Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó
bí ọkùnrin tí ó fọ́jú.
Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n
tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.
15“Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn.
“Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!”
Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé,
“Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”
16Olúwa ti tú wọn ká fúnrarẹ̀;
kò sí bojútó wọn mọ́.
Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́,
àti àánú fún àwọn àgbàgbà.
17Síwájú sí i, ojú wa kùnà
fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán;
láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò
fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.
18Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri,
àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́.
Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye
nítorí òpin wa ti dé.
19Àwọn tí ń lé wa yára
ju idì ojú ọ̀run lọ;
wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè
wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.
20Ẹni ààmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa,
ni wọ́n fi tàkúté wọn mú.
Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀
ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
21Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu,
ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi.
Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú;
ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.
22Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin;
kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́.
Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà
yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.
This chapter is an acrostic poem, the verses of which begin with the successive letters of the Hebrew alphabet. 1How the gold has lost its luster,
the fine gold become dull!
The sacred gems are scattered
at every street corner.
2How the precious children of Zion,
once worth their weight in gold,
are now considered as pots of clay,
the work of a potter’s hands!
3Even jackals offer their breasts
to nurse their young,
but my people have become heartless
like ostriches in the desert.
4Because of thirst the infant’s tongue
sticks to the roof of its mouth;
the children beg for bread,
but no one gives it to them.
5Those who once ate delicacies
are destitute in the streets.
Those brought up in royal purple
now lie on ash heaps.
6The punishment of my people
is greater than that of Sodom,
which was overthrown in a moment
without a hand turned to help her.
7Their princes were brighter than snow
and whiter than milk,
their bodies more ruddy than rubies,
their appearance like lapis lazuli.
8But now they are blacker than soot;
they are not recognized in the streets.
Their skin has shriveled on their bones;
it has become as dry as a stick.
9Those killed by the sword are better off
than those who die of famine;
racked with hunger, they waste away
for lack of food from the field.
10With their own hands compassionate women
have cooked their own children,
who became their food
when my people were destroyed.
11The Lord has given full vent to his wrath;
he has poured out his fierce anger.
He kindled a fire in Zion
that consumed her foundations.
12The kings of the earth did not believe,
nor did any of the peoples of the world,
that enemies and foes could enter
the gates of Jerusalem.
13But it happened because of the sins of her prophets
and the iniquities of her priests,
who shed within her
the blood of the righteous.
14Now they grope through the streets
as if they were blind.
They are so defiled with blood
that no one dares to touch their garments.
15“Go away! You are unclean!” people cry to them.
“Away! Away! Don’t touch us!”
When they flee and wander about,
people among the nations say,
“They can stay here no longer.”
16The Lord himself has scattered them;
he no longer watches over them.
The priests are shown no honor,
the elders no favor.
17Moreover, our eyes failed,
looking in vain for help;
from our towers we watched
for a nation that could not save us.
18People stalked us at every step,
so we could not walk in our streets.
Our end was near, our days were numbered,
for our end had come.
19Our pursuers were swifter
than eagles in the sky;
they chased us over the mountains
and lay in wait for us in the desert.
20The Lord’s anointed, our very life breath,
was caught in their traps.
We thought that under his shadow
we would live among the nations.
21Rejoice and be glad, Daughter Edom,
you who live in the land of Uz.
But to you also the cup will be passed;
you will be drunk and stripped naked.
22Your punishment will end, Daughter Zion;
he will not prolong your exile.
But he will punish your sin, Daughter Edom,
and expose your wickedness.