Òwe 1 – YCB & KSS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 1:1-33

Èròǹgbà àti kókó-ọ̀rọ̀

1Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.

2Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́,

Láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.

3Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo,

àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;

4láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀,

ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.

5Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀,

sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.

6Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe,

àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.

7Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀,

ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.

Ọ̀rọ̀ ìyànjú láti ṣàfẹ́rí ọgbọ́n

8Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ,

má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.

9Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ

àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.

10Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́,

má ṣe gbà fún wọn.

11Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa;

jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan,

jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;

12Jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú,

àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò;

13A ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí

a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa;

14Da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa,

a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà”

15Ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ,

má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn;

16Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀,

wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.

17Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀,

ní ojú ẹyẹ!

18Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn.

Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà

19Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́;

yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.

Ìkìlọ̀ láti má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀

201.20,21: Òw 8.1-3.Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó

ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;

21Láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde

Ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:

22“Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó?

Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó?

Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?

23Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni,

Ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín

kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.

24Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè

kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,

25Níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi,

tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,

26Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín;

èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.

27Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle,

Nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà,

nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.

28“Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn;

wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.

29Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀

tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.

30Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi

tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,

31Wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn

wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún

32Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n

ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;

33Ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu

yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”

Kurdi Sorani Standard

پەندەکانی سلێمان 1:1-33

پێشەکی: ئامانج و بابەت

1پەندەکانی سلێمانی کوڕی داود، پاشای ئیسرائیل،

2بۆ زانینی دانایی و تەمبێکردن،

بۆ پەیبردن بە وشەکانی تێگەیشتن،

3بۆ وەرگرتنی تەمبێکردن و وریایی،

ڕاستودروستی و دادپەروەری و ڕاستەڕێیی،

4بۆ بەخشینی ژیری بە ساویلکە،

بە لاویش زانیاری و سەلیقە1‏:4 سەلیقە: کارکردن بە لێکدانەوە و ئارامی. هەروەها ڕازگری و پاراستنی نهێنی.‏،

5(دانا گوێی لێ دەگرێت و فێربوونی زیاد دەبێت،

تێگەیشتووش ڕاوێژی باشی دەست دەکەوێت،)

6بۆ تێگەیشتنی پەند و نموونە،

قسەی دانایان و مەتەڵەکانیان.

7لەخواترسی سەرەتای زانیارییە،

بەڵام گێلەکان سووکایەتی بە دانایی و تەمبێکردن دەکەن.

هاندان بۆ دەستگرتن بە دانایی

ئاگادارکردنەوە لە دژی فریودان

8ڕۆڵە، گوێ لە تەمبێکردنی باوکت بگرە و

فێرکردنی دایکت پشتگوێ مەخە،

9چونکە تاجەگوڵینەی نیعمەتن بۆ سەرت،

گەردانەن بۆ ملت.

10ڕۆڵە، ئەگەر گوناهباران فریویان دایت،

ڕازی مەبە.

11ئەگەر گوتیان: «لەگەڵمان وەرە،

بۆسە بۆ خوێنڕشتن بنێینەوە،

بەبێ هۆ بۆ بێتاوانێک خۆمان مات بکەین،

12وەک جیهانی مردووان بە زیندووێتی هەڵیانلووشین و

بە ساغی وەک ئەوانەی لە گۆڕ دەنرێن.

13هەموو گەنجینەیەکی بەهادار دەدۆزینەوە و

ماڵمان پڕ دەکەین لە دەستکەوت.

14پشکی خۆت هەڵبدە ناومان،

بە هەموومان یەک کیسەمان دەبێت.»

15ڕۆڵە، لەگەڵیان بە ڕێگادا مەڕۆ،

پێیەکانت قەدەغە بکە لە ڕێڕەوەکانیان،

16چونکە پێیەکانیان بەرەو خراپە ڕادەکەن،

بۆ خوێنڕشتن پەلە دەکەن.

17بێ سوودە دانانەوەی تۆڕ

لەبەرچاوی هەموو باڵدارێک.

18بۆ خوێنی خۆیان بۆسەیان ناوەتەوە،

خۆیان تەنها بۆ گیانی خۆیان ماتداوە.

19ئاوایە ڕێچکەی هەموو ئەوانەی بەدوای دەستکەوتی ناڕەواوەن،

سەری خاوەنی دەخوات.

ئاگادارکردنەوە لە ڕەتکردنەوەی دانایی

20دانایی لە کۆڵان هاوار دەکات،

لە گۆڕەپانەکان دەنگ بەرز دەکاتەوە،

21لە شەقامە قەرەباڵغەکاندا بانگ دەکات،

لە دەروازەی شارەکاندا قسەی خۆی دەکات:

22«هەتا کەی ئەی ساویلکەکان حەز لە ساویلکەیی دەکەن؟

هەتا کەی گاڵتەجاڕان بە گاڵتەکردن دڵخۆش دەبن،

گێلەکانیش ڕقیان لە زانیاری دەبێتەوە؟

23بگەڕێنەوە کاتێک سەرزەنشتتان دەکەم!

ئینجا ڕۆحی خۆمتان بەسەردا دەڕێژم،

وشەکانی خۆمتان پێ دەناسێنم.

24بەڵام بانگهێشتم کردن، ڕەتتان کردەوە،

دەستم درێژکرد، کەس گوێی پێنەدا،

25هەموو ڕاوێژێکی منتان پشتگوێ خست،

سەرزەنشتی منتان وەرنەگرت،

26جا منیش لە کارەساتتان پێدەکەنم.

گاڵتە دەکەم کە ترستان لێ نیشت،

27کە ترستان وەک گەردەلوول لێ نیشت و

وێرانیتان وەک ڕەشەبا هاتە سەر و

تەنگانە و ناخۆشی بەسەرتانی دادا.

28«ئینجا بانگم دەکەن، بەڵام من وەڵام نادەمەوە،

بە پەرۆشییەوە بەدوامدا دەگەڕێن بەڵام نامدۆزنەوە.

29لەبەر ئەوەی ڕقیان لە زانیاری بووەوە،

لەخواترسییان هەڵنەبژارد،

30لەبەر ئەوەی ڕاوێژی منیان وەرنەگرت،

بە سووکییەوە تەماشای هەموو سەرزەنشتەکانی منیان کرد،

31بۆیە لە بەرهەمی ڕێگای خۆیان دەخۆن،

لە بەری پیلانەکانیان تێر دەبن،

32چونکە هەڵگەڕانەوەی ساویلکەکان دەیانکوژێت،

بێباکی گێلەکان لەناویان دەبات.

33بەڵام ئەوەی گوێ لە من بگرێت بە ئاسوودەیی نیشتەجێ دەبێت،

لە ترسی خراپە دەحەسێتەوە.»