Òwe 1 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 1:1-33

Èròǹgbà àti kókó-ọ̀rọ̀

1Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.

2Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́,

Láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.

3Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo,

àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;

4láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀,

ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.

5Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀,

sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.

6Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe,

àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.

7Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀,

ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.

Ọ̀rọ̀ ìyànjú láti ṣàfẹ́rí ọgbọ́n

8Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ,

má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.

9Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ

àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.

10Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́,

má ṣe gbà fún wọn.

11Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa;

jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan,

jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;

12Jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú,

àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò;

13A ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí

a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa;

14Da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa,

a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà”

15Ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ,

má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn;

16Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀,

wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.

17Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀,

ní ojú ẹyẹ!

18Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn.

Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà

19Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́;

yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.

Ìkìlọ̀ láti má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀

201.20,21: Òw 8.1-3.Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó

ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;

21Láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde

Ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:

22“Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó?

Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó?

Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?

23Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni,

Ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín

kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.

24Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè

kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,

25Níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi,

tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,

26Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín;

èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.

27Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle,

Nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà,

nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.

28“Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn;

wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.

29Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀

tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.

30Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi

tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,

31Wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn

wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún

32Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n

ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;

33Ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu

yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

箴言 1:1-33

箴言的价值

1这是大卫的儿子以色列所罗门的箴言。

2为使人认识智慧和教诲,

领悟真知灼见;

3为使人接受劝诫,

为人处事仁义、公平、正直;

4使愚昧人明智,

使青年有知识和明辨力;

5使智者听了长学问,

明哲听了得指引;

6使人领悟箴言和比喻,

明白智者的话和谜语。

7知识始于敬畏耶和华,

愚人轻视智慧和教诲。

8孩子啊,

你要听从父亲的教诲,

不可背弃母亲的训言。

9因为这要作你头上的华冠,

颈上的项链。

10孩子啊,恶人若引诱你,

千万不要听从。

11他们若说:“跟我们来吧,

我们去埋伏杀人,

暗害无辜者取乐;

12我们要像阴间一样生吞他们,

整个吞没他们,

使他们如坠入坟墓的人;

13我们必得到各样宝物,

把战利品装满我们的房屋。

14跟我们一起干吧,

大家有福同享!”

15孩子啊,

不要走他们的道,

切莫行他们的路。

16因为他们奔向罪恶,

急速地去杀人流血。

17在飞鸟眼前设网罗,徒劳无功。

18他们埋伏,却自流己血;

他们伏击,却自害己命。

19这就是贪爱不义之财者的结局,

不义之财终要夺去他们的性命。

智慧的劝诫

20智慧在大街上高喊,

在广场上扬声,

21在热闹的市集宣告,

在城门口演说:

22“你们愚昧人喜爱愚昧,

嘲讽者以嘲弄为乐,

无知者厌恶知识,

要到什么时候呢?

23你们若因我的责备而回转,

我就向你们显明我的旨意1:23 我就向你们显明我的旨意”希伯来文是“我就将我的灵浇灌你们”。

叫你们明白我的话语。

24我呼唤你们,

你们却充耳不闻;

我向你们招手,

你们却视若无睹。

25你们漠视我的劝诫,

不接受我的责备。

26因此,

你们遭遇灾难时,

我必发笑;

惊恐临到你们时,

我必嗤笑——

27那时,恐惧如风暴袭击你们,

灾难如旋风临到你们,

忧愁和苦难吞没你们。

28你们呼求我,

我也不回答;

你们恳切地寻找我,

却找不到。

29因为你们厌恶知识,

不愿意敬畏耶和华,

30不接受我的劝诫,

又藐视我的责备。

31所以,你们必自食其果,

因自己的恶谋而吃尽苦头。

32愚昧人背离正道,

自招灭亡;

愚顽人逍遥自在,

毁掉自己。

33然而,那听从我的必安然居住,

得享安宁,

不怕灾祸。”