Ìfihàn 22 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ìfihàn 22:1-21

Omi iyè

1Ó sì fi odò omi ìyè kan hàn mi, tí ó mọ́ bí Kirisitali, tí ń tí ibi ìtẹ́ Ọlọ́run àti tí Ọ̀dọ́-Àgùntàn jáde wá, 222.2: Gẹ 2.9.Ní àárín ìgboro rẹ̀, àti níhà èkínní kejì odò náà, ni igi ìyè gbé wà, tí o máa ń so onírúurú èso méjìlá, a sì máa so èso rẹ̀ ni oṣooṣù ewé igi náà sí wà fún mímú àwọn orílẹ̀-èdè láradà. 322.3: Sk 14.11.Ègún kì yóò sì ṣí mọ: ìtẹ́ Ọlọ́run àti tí Ọ̀dọ́-àgùntàn ni yóò sì máa wà níbẹ̀; àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò sì máa sìn ín: 422.4: Sm 17.15.Wọ́n ó si máa rí ojú rẹ̀; orúkọ rẹ̀ yóò si máa wà ni iwájú orí wọn. 5Òru kì yóò sí mọ́; wọn kò sì ní wa ìmọ́lẹ̀ fìtílà, tàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn; nítorí pé Olúwa Ọlọ́run ni yóò tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn: wọn ó sì máa jẹ ọba láé àti láéláé.

6Ó sì wí fún mi pé, “Òdodo àti òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ wọ̀nyí: Olúwa Ọlọ́run ẹ̀mí àwọn wòlíì ni ó sì ran angẹli rẹ̀ láti fi ohun tí ó ní láti ṣẹlẹ̀ láìpẹ́ yìí hàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.”

7“Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán! Ìbùkún ni fún ẹni tí ń pa ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ inú ìwé yìí mọ́!”

8Èmi, Johanu, ni ẹni tí ó gbọ́ tí ó sì ri nǹkan wọ̀nyí. Nígbà tí mo sì gbọ́ tí mo sì rí, mo wólẹ̀ láti foríbalẹ̀ níwájú ẹsẹ̀ angẹli náà, tí o fi nǹkan wọ̀nyí hàn mi, 9Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Wó ò, má ṣe bẹ́ẹ̀: ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ ni èmi, àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ wòlíì, àti ti àwọn tí ń pa ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí mọ́: foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run!”

10Ó sì wí fún mi pé, “má ṣe fi èdìdì di ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí inú ìwé yìí: nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀. 1122.11: Da 12.10.Ẹni tí ń ṣe aláìṣòótọ́, kí ó máa ṣe aláìṣòótọ́ nì só: àti ẹni tí ń ṣe ẹlẹ́gbin, kí ó máa ṣe ẹ̀gbin nì só: àti ẹni tí ń ṣe olódodo, kí ó máa ṣe òdodo nì só: Àti ẹni tí ń ṣe mímọ́, kí ó máa ṣe mímọ́ nì só.”

1222.12: Isa 40.10; Jr 17.10.“Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán; èrè mí sì ń bẹ pẹ̀lú mi, láti sán fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ yóò tí rí. 1322.13: Isa 44.6; 48.12.Èmi ni Alfa àti Omega, ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn, ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti òpin.

14“Ìbùkún ni fún àwọn ti ń fọ aṣọ wọn, kí wọ́n lè ni ẹ̀tọ́ láti wá sí ibi igi ìyè náà, àti kí wọ́n lè gbà àwọn ẹnu ibodè wọ inú ìlú náà. 15Nítorí ni òde ni àwọn ajá gbé wà, àti àwọn oṣó, àti àwọn àgbèrè, àti àwọn apànìyàn, àti àwọn abọ̀rìṣà, àti olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ràn èké tí ó sì ń hùwà èké.

16“Èmi, Jesu, ni ó rán angẹli mi láti jẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí fún yin ní tí àwọn ìjọ. Èmi ni gbòǹgbò àti irú-ọmọ Dafidi, àti ìràwọ̀ òwúrọ̀ tí ń tàn.”

1722.17: Isa 55.1.Ẹ̀mí àti ìyàwó wí pé, “Máa bọ!” Àti ẹni tí ó ń gbọ́ kí ó wí pé, “Máa bọ̀!” Àti ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ kí ó wá, àti ẹni tí o bá sì fẹ́, kí ó gba omi ìyè náà lọ́fẹ̀ẹ́.

18Èmi kìlọ̀ fún olúkúlùkù ẹni tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ inú ìwé yìí pé, bí ẹnikẹ́ni ba fi kún wọn, Ọlọ́run yóò fi kún àwọn ìyọnu tí a kọ sínú ìwé yìí fún un. 19Bí ẹnikẹ́ni bá sì mú kúrò nínú ọ̀rọ̀ ìwé ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, Ọlọ́run yóò sì mú ipa tirẹ̀ kúrò nínú ìwé ìyè, àti kúrò nínú ìlú mímọ́ náà, àti kúrò nínú àwọn ohun tí a kọ sínú ìwé yìí.

20Ẹni tí ó jẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí wí pé, “Nítòótọ́ èmi ń bọ̀ kánkán.”

Àmín, Máa bọ̀, Jesu Olúwa!

2122.21: 2Tẹ 3.18.Oore-ọ̀fẹ́ Jesu Olúwa kí ó wà pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́. Àmín.

Persian Contemporary Bible

مکاشفه 22:1-21

1آنگاه رودخانهٔ آب حيات را به من نشان داد كه مثل بلور، صاف و زلال بود. رودخانه از تخت خدا و «برّه» جاری می‌شد، 2و از وسط جادهٔ اصلی می‌گذشت. دو طرف رودخانه، درختان حيات قرار داشت كه سالی دوازده بار ميوه می‌دادند يعنی هر ماه يک نوع ميوهٔ تازه. برگهايش نيز شفابخش بود و برای درمان قومها به کار می‌رفت.

3در شهر چيزی بدی يافت نخواهد شد، چون تخت خدا و «برّه» در آنجاست. خدمتگزاران خدا، او را پرستش خواهند كرد، 4و رويش را خواهند ديد و نامش روی پيشانی‌شان نوشته خواهد بود. 5در آنجا ديگر شب نخواهد بود. احتياجی هم به چراغ و خورشيد نخواهد بود، چون خداوند بزرگ نور ايشان خواهد بود و ايشان تا ابد سلطنت خواهند كرد.

6آنگاه فرشته به من گفت: «اين سخنان راست و قابل اعتماد است. و خدايی كه وقايع آينده را از قبل به انبيا خود اطلاع می‌دهد، فرشتهٔ خود را فرستاده است تا آنچه را كه بزودی روی خواهد داد به شما اطلاع دهد.»

عيسی بزودی می‌آيد

7عيسی مسيح می‌فرمايد: «گوش كنيد! من بزودی می‌آيم. خوشا به حال كسانی كه آنچه را كه در اين كتاب پيشگويی شده، باور می‌كنند.»

8من، يوحنا، تمام اين چيزها را ديدم و شنيدم و زانو زدم تا فرشته‌ای را كه آنها را به من نشان داده بود، پرستش كنم. 9ولی او بار ديگر به من گفت: «نه، اين كار را نكن. من نيز مانند تو و برادرانت يعنی انبيا خدا، و تمام كسانی كه به حقايق اين كتاب اعتماد دارند، از خدمتگزاران عيسی می‌باشم. پس فقط خدا را پرستش كن.»

10سپس به من دستور داده، گفت: «پيشگويی‌های اين كتاب را در دسترس همه بگذار، چون بزودی به وقوع خواهند پيوست. 11وقتی آن زمان فرا رسد، بدكاران باز هم به كارهای بد خود ادامه خواهند داد و فاسدان باز هم فاسدتر خواهند شد، ولی نیکان، نیکتر و پاكان، پاکتر می‌گردند.»

12عيسی مسيح می‌فرمايد: «چشم به راه باشيد، من به زودی می‌آيم و برای هر كس مطابق اعمالش پاداشی با خود خواهم آورد. 13من الف و يا، آغاز و پايان، اول و آخر هستم. 14خوشا به حال كسانی كه لباسهایشان را دائماً می‌شويند. آنها اجازهٔ ورود به شهر و خوردن ميوهٔ درخت حيات را خواهند داشت. 15اما فاسدان، جادوگران، زناكاران، قاتلان، بت‌پرستان، دروغگويان و متقلبان، به شهر راه نخواهند يافت.

16«من، عيسی، فرشتهٔ خود را نزد شما فرستادم تا همه چيز را با كليساها در ميان بگذارم. من از اصل و نسب داوود هستم. من ستارهٔ درخشندهٔ صبح می‌باشم.»

17روح و عروس می‌گويند: «بيا!» هر کس اين را می‌شنود، بگويد: «بيا!» هر كه تشنه است بيايد، و هر کس مايل است بيايد، و از آب حيات به رايگان بنوشد.

18به كسی كه پيشگويی‌های اين كتاب را می‌شنود با صراحت می‌گويم كه اگر به نوشته‌های اين كتاب چيزی اضافه كند، خدا بلاهای اين كتاب را بر سرش خواهد آورد. 19و اگر از اين پيشگويی‌ها مطلبی كم كند، خداوند او را از درخت حيات و شهر مقدس كه آن را شرح دادم، بی‌نصيب خواهد ساخت. 20كسی كه اين چيزها را گفته است، می‌فرمايد: «بله، من بزودی می‌آيم!»

«آمين! ای عيسای خداوند، بيا!»

21فيض خداوند ما عيسی مسيح بر همهٔ شما باد! آمين!