Ìfihàn 22 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ìfihàn 22:1-21

Omi iyè

1Ó sì fi odò omi ìyè kan hàn mi, tí ó mọ́ bí Kirisitali, tí ń tí ibi ìtẹ́ Ọlọ́run àti tí Ọ̀dọ́-Àgùntàn jáde wá, 222.2: Gẹ 2.9.Ní àárín ìgboro rẹ̀, àti níhà èkínní kejì odò náà, ni igi ìyè gbé wà, tí o máa ń so onírúurú èso méjìlá, a sì máa so èso rẹ̀ ni oṣooṣù ewé igi náà sí wà fún mímú àwọn orílẹ̀-èdè láradà. 322.3: Sk 14.11.Ègún kì yóò sì ṣí mọ: ìtẹ́ Ọlọ́run àti tí Ọ̀dọ́-àgùntàn ni yóò sì máa wà níbẹ̀; àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò sì máa sìn ín: 422.4: Sm 17.15.Wọ́n ó si máa rí ojú rẹ̀; orúkọ rẹ̀ yóò si máa wà ni iwájú orí wọn. 5Òru kì yóò sí mọ́; wọn kò sì ní wa ìmọ́lẹ̀ fìtílà, tàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn; nítorí pé Olúwa Ọlọ́run ni yóò tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn: wọn ó sì máa jẹ ọba láé àti láéláé.

6Ó sì wí fún mi pé, “Òdodo àti òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ wọ̀nyí: Olúwa Ọlọ́run ẹ̀mí àwọn wòlíì ni ó sì ran angẹli rẹ̀ láti fi ohun tí ó ní láti ṣẹlẹ̀ láìpẹ́ yìí hàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.”

7“Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán! Ìbùkún ni fún ẹni tí ń pa ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ inú ìwé yìí mọ́!”

8Èmi, Johanu, ni ẹni tí ó gbọ́ tí ó sì ri nǹkan wọ̀nyí. Nígbà tí mo sì gbọ́ tí mo sì rí, mo wólẹ̀ láti foríbalẹ̀ níwájú ẹsẹ̀ angẹli náà, tí o fi nǹkan wọ̀nyí hàn mi, 9Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Wó ò, má ṣe bẹ́ẹ̀: ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ ni èmi, àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ wòlíì, àti ti àwọn tí ń pa ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí mọ́: foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run!”

10Ó sì wí fún mi pé, “má ṣe fi èdìdì di ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí inú ìwé yìí: nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀. 1122.11: Da 12.10.Ẹni tí ń ṣe aláìṣòótọ́, kí ó máa ṣe aláìṣòótọ́ nì só: àti ẹni tí ń ṣe ẹlẹ́gbin, kí ó máa ṣe ẹ̀gbin nì só: àti ẹni tí ń ṣe olódodo, kí ó máa ṣe òdodo nì só: Àti ẹni tí ń ṣe mímọ́, kí ó máa ṣe mímọ́ nì só.”

1222.12: Isa 40.10; Jr 17.10.“Kíyèsi i, èmi ń bọ̀ kánkán; èrè mí sì ń bẹ pẹ̀lú mi, láti sán fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ yóò tí rí. 1322.13: Isa 44.6; 48.12.Èmi ni Alfa àti Omega, ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn, ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti òpin.

14“Ìbùkún ni fún àwọn ti ń fọ aṣọ wọn, kí wọ́n lè ni ẹ̀tọ́ láti wá sí ibi igi ìyè náà, àti kí wọ́n lè gbà àwọn ẹnu ibodè wọ inú ìlú náà. 15Nítorí ni òde ni àwọn ajá gbé wà, àti àwọn oṣó, àti àwọn àgbèrè, àti àwọn apànìyàn, àti àwọn abọ̀rìṣà, àti olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ràn èké tí ó sì ń hùwà èké.

16“Èmi, Jesu, ni ó rán angẹli mi láti jẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí fún yin ní tí àwọn ìjọ. Èmi ni gbòǹgbò àti irú-ọmọ Dafidi, àti ìràwọ̀ òwúrọ̀ tí ń tàn.”

1722.17: Isa 55.1.Ẹ̀mí àti ìyàwó wí pé, “Máa bọ!” Àti ẹni tí ó ń gbọ́ kí ó wí pé, “Máa bọ̀!” Àti ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ kí ó wá, àti ẹni tí o bá sì fẹ́, kí ó gba omi ìyè náà lọ́fẹ̀ẹ́.

18Èmi kìlọ̀ fún olúkúlùkù ẹni tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ inú ìwé yìí pé, bí ẹnikẹ́ni ba fi kún wọn, Ọlọ́run yóò fi kún àwọn ìyọnu tí a kọ sínú ìwé yìí fún un. 19Bí ẹnikẹ́ni bá sì mú kúrò nínú ọ̀rọ̀ ìwé ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, Ọlọ́run yóò sì mú ipa tirẹ̀ kúrò nínú ìwé ìyè, àti kúrò nínú ìlú mímọ́ náà, àti kúrò nínú àwọn ohun tí a kọ sínú ìwé yìí.

20Ẹni tí ó jẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí wí pé, “Nítòótọ́ èmi ń bọ̀ kánkán.”

Àmín, Máa bọ̀, Jesu Olúwa!

2122.21: 2Tẹ 3.18.Oore-ọ̀fẹ́ Jesu Olúwa kí ó wà pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́. Àmín.

New Serbian Translation

Откривење 22:1-21

1Анђео ми је, затим, показао реку воде живота, бистру као кристал, која извире из престола Божијег и Јагњетовог 2и протиче кроз главну улицу града. На обе стране реке стајало је дрво живота које рађа дванаестоструки род, један род месечно. Лишће овог дрвета је за исцељење народима. 3Тамо неће бити никаквог проклетства. У граду ће бити Божији и Јагњетов престо, а његове ће му се слуге клањати. 4Они ће гледати његово лице, и његово име биће на њиховим челима. 5Ноћи више неће бити, а неће им више требати ни светлости сунчеве ни месечеве, јер ће им сам Господ Бог светлити, а они ће владати од сад и довека.

6Анђео ми рече: „Ове речи су поуздане и истините. Господ Бог, који надахњује пророке, послао је свог анђела да покаже својим слугама шта мора да се догоди ускоро.

7Ево, долазим убрзо! Благо оном који држи пророчке речи ове књиге.“

8Ја, Јован, чуо сам и видео све ово. Кад сам све то чуо и видео, пао сам ничице пред ноге анђела који ми је све то показао, да му се поклоним. 9Али он ми рече: „Не чини то! Слуга сам као и ти и твоја браћа пророци који држе речи ове књиге. Богу се поклони!“ 10Још ми рече: „Немој да запечатиш пророчке речи ове књиге, јер се време приближило. 11Неправедник нека и даље чини неправду, нечисти нека се и даље каља, а ко је праведан нека и даље чини што је праведно, и ко је свет нека се и даље посвећује.“

12„Ево, долазим убрзо, и носим плату са собом, да платим свакоме по његовим делима. 13Ја сам Алфа и Омега, Први и Последњи, Почетак и Свршетак. 14Благо онима који перу своју одећу, јер ће добити право да приступе дрвету живота и уђу на градска врата. 15А напољу су пси, врачари, блудници, убице и идолопоклоници и сви који воле и чине лаж.

16Ја, Исус, послао сам свога анђела да вам објави ову поруку за цркве. Ја сам Корен и Потомак Давидов, сјајна звезда Даница.“

17Дух и невеста кажу: „Дођи!“ И ко слуша ово, нека каже: „Дођи!“ Ко год је жедан нека дође; ко хоће, нека узме воду живота забадава. 18Упозоравам сваког ко слуша пророчке речи ове књиге: дода ли им ко нешто, томе ће Бог додати зла записана у овој књизи. 19А одузме ли ко нешто од речи ове пророчке књиге, Бог ће одузети његов део од дрвета живота и од светог града, о којима је написано у овој књизи.

20Онај који преноси ово сведочанство, каже: „Да, долазим убрзо!“

Амин! Дођи, Господе Исусе!

21Милост Господа Исуса нека буде са свима. Амин.