Ìfihàn 19 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ìfihàn 19:1-21

Haleluya

1Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí mo gbọ́ ohùn ńlá ní ọ̀run bí ẹni pé tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, ń wí pé:

“Haleluya!

Ti Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà, àti ọlá àti agbára,

219.2: De 32.43.nítorí òtítọ́ àti òdodo ni ìdájọ́ rẹ̀.

Nítorí o ti ṣe ìdájọ́ àgbèrè ńlá a nì,

tí o fi àgbèrè rẹ̀ ba ilẹ̀ ayé jẹ́, ó sì ti gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ̀ náà.”

319.3: Isa 34.10.Àti lẹ́ẹ̀kejì wọ́n wí pé:

“Haleluya!

Èéfín rẹ̀ sì gòkè lọ láé àti láéláé.”

4Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún nì, àti àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin nì sì wólẹ̀, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run tí ó jókòó lórí ìtẹ́, wí pé:

“Àmín, Haleluya!”

519.5: Sm 115.13.Ohùn kan sì ti ibi ìtẹ́ náà jáde wá, wí pé:

“Ẹ máa yin Ọlọ́run wa,

ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo,

ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù rẹ̀,

àti èwe àti àgbà!”

6Mo sì gbọ́ bí ẹni pé ohùn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àti bí ìró omi púpọ̀, àti bí ìró àrá ńláńlá, ń wí pé:

“Haleluya!

Nítorí Olúwa Ọlọ́run wa, Olódùmarè ń jẹ ọba.

719.7: Sm 118.24.Ẹ jẹ́ kí a yọ̀, kí inú wa kí ó sì dùn gidigidi,

kí a sì fi ògo fún un.

Nítorí pé ìgbéyàwó Ọ̀dọ́-Àgùntàn dé,

aya rẹ̀ sì ti múra tán.

8Òun ni a sì fi fún pé kí ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀

wíwẹ́ tí ó funfun gbòò.”

(Nítorí pé aṣọ ọ̀gbọ̀ nì dúró fún iṣẹ́ òdodo àwọn ènìyàn mímọ́.)

9Ó sì wí fún mi pé, “Kọ̀wé rẹ̀, ‘Ìbùkún ni fún àwọn tí a pè sí àsè alẹ́ ìgbéyàwó ọ̀dọ́-àgùntàn.’ ” Ó sì wí fún mi pé: “Ìwọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ òtítọ́ Ọlọ́run.”

10Mo sì wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ láti foríbalẹ̀ fún un. Ó sì wí fún mi pé, “Wò ó, má ṣe bẹ́ẹ̀: ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ ni èmi, àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ tí wọ́n di ẹ̀rí Jesu mú. Foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run: nítorí pé ẹ̀rí Jesu ni ìsọtẹ́lẹ̀.”

Ẹni tó gun ẹṣin funfun

1119.11: El 1.1.Mo sì rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, sì wò ó, ẹṣin funfun kan; ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ni à ń pè ní Olódodo àti Olóòtítọ́, nínú òdodo ni ó sì ń ṣe ìdájọ́, tí ó ń jagun. 1219.12: Da 10.6.Ojú rẹ̀ dàbí ọ̀wọ́-iná, àti ní orí rẹ̀ ni adé púpọ̀ wà; ó sì ní orúkọ kan tí a kọ, tí ẹnikẹ́ni kò mọ́, bí kò ṣe òun tìkára rẹ̀. 13A sì wọ̀ ọ́ ní aṣọ tí a tẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀: a sì ń pe orúkọ rẹ̀ ní Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. 14Àwọn ogun tí ń bẹ ní ọ̀run tí a wọ̀ ní aṣọ ọ̀gbọ̀ wíwẹ́, funfun àti mímọ́, sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn lórí ẹṣin funfun. 1519.15: Sm 2.9.Àti láti ẹnu rẹ̀ ni idà mímú ti ń jáde lọ, kí ó lè máa fi sá àwọn orílẹ̀-èdè: “Òun ó sì máa fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn.” Ó sì ń tẹ ìfúntí àti ìbínú Ọlọ́run Olódùmarè. 1619.16: De 10.17; Da 2.47.Ó sì ní lára aṣọ rẹ̀ àti ni ìtàn rẹ̀ orúkọ kan tí a kọ:

ọba àwọn ọba àti olúwa àwọn olúwa.

1719.17: El 39.4,17-20.Mo sì rí angẹli kan dúró nínú oòrùn; ó sì fi ohùn rara kígbe, ó ń wí fún gbogbo àwọn ẹyẹ tí ń fò ní agbede-méjì ọ̀run pé: “Ẹ wá ẹ sì kó ara yín jọ pọ̀ sí àsè ńlá Ọlọ́run; 18kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ ẹran-ara àwọn ọba, àti ẹran-ara àwọn olórí ogun àti ẹran-ara àwọn ènìyàn alágbára, àti ẹran àwọn ẹṣin, àti ti àwọn tí ó jókòó lórí wọn, àti ẹran-ara ènìyàn gbogbo, àti ti òmìnira, àti ti ẹrú, àti ti èwe àti ti àgbà.”

19Mo sì rí ẹranko náà àti àwọn ọba ayé, àti àwọn ogun wọn tí a gbá jọ láti bá ẹni tí ó jókòó lórí ẹṣin náà àti ogun rẹ̀ jagun. 20A sì mú ẹranko náà, àti wòlíì èké nì pẹ̀lú rẹ̀, tí ó ti ń ṣe iṣẹ́ ìyanu níwájú rẹ̀, èyí tí ó fi ń tan àwọn tí ó gba ààmì ẹranko náà àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ fún àwòrán rẹ̀ jẹ. Àwọn méjèèjì yìí ni a sọ láààyè sínú adágún iná tí ń fi sulfuru jó. 21Àwọn ìyókù ni a sì fi idà ẹni tí ó jókòó lórí ẹṣin náà pa, àní idà tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde: Gbogbo àwọn ẹyẹ sì ti ipa ẹran-ara wọn yó.

New International Version

Revelation 19:1-21

Threefold Hallelujah Over Babylon’s Fall

1After this I heard what sounded like the roar of a great multitude in heaven shouting:

“Hallelujah!

Salvation and glory and power belong to our God,

2for true and just are his judgments.

He has condemned the great prostitute

who corrupted the earth by her adulteries.

He has avenged on her the blood of his servants.”

3And again they shouted:

“Hallelujah!

The smoke from her goes up for ever and ever.”

4The twenty-four elders and the four living creatures fell down and worshiped God, who was seated on the throne. And they cried:

“Amen, Hallelujah!”

5Then a voice came from the throne, saying:

“Praise our God,

all you his servants,

you who fear him,

both great and small!”

6Then I heard what sounded like a great multitude, like the roar of rushing waters and like loud peals of thunder, shouting:

“Hallelujah!

For our Lord God Almighty reigns.

7Let us rejoice and be glad

and give him glory!

For the wedding of the Lamb has come,

and his bride has made herself ready.

8Fine linen, bright and clean,

was given her to wear.”

(Fine linen stands for the righteous acts of God’s holy people.)

9Then the angel said to me, “Write this: Blessed are those who are invited to the wedding supper of the Lamb!” And he added, “These are the true words of God.”

10At this I fell at his feet to worship him. But he said to me, “Don’t do that! I am a fellow servant with you and with your brothers and sisters who hold to the testimony of Jesus. Worship God! For it is the Spirit of prophecy who bears testimony to Jesus.”

The Heavenly Warrior Defeats the Beast

11I saw heaven standing open and there before me was a white horse, whose rider is called Faithful and True. With justice he judges and wages war. 12His eyes are like blazing fire, and on his head are many crowns. He has a name written on him that no one knows but he himself. 13He is dressed in a robe dipped in blood, and his name is the Word of God. 14The armies of heaven were following him, riding on white horses and dressed in fine linen, white and clean. 15Coming out of his mouth is a sharp sword with which to strike down the nations. “He will rule them with an iron scepter.”19:15 Psalm 2:9 He treads the winepress of the fury of the wrath of God Almighty. 16On his robe and on his thigh he has this name written:

king of kings and lord of lords.

17And I saw an angel standing in the sun, who cried in a loud voice to all the birds flying in midair, “Come, gather together for the great supper of God, 18so that you may eat the flesh of kings, generals, and the mighty, of horses and their riders, and the flesh of all people, free and slave, great and small.”

19Then I saw the beast and the kings of the earth and their armies gathered together to wage war against the rider on the horse and his army. 20But the beast was captured, and with it the false prophet who had performed the signs on its behalf. With these signs he had deluded those who had received the mark of the beast and worshiped its image. The two of them were thrown alive into the fiery lake of burning sulfur. 21The rest were killed with the sword coming out of the mouth of the rider on the horse, and all the birds gorged themselves on their flesh.