Salmos 11 – OL & YCB

O Livro

Salmos 11:1-7

Salmo 11

Salmo de David. Para o diretor do coro.

1No Senhor me refugio!

Sendo assim, como são capazes de me dizer:

“Foge como um pássaro para o cimo da montanha,

para que encontres segurança?”

2Porque os maus já retesaram os seus arcos,

puseram as flechas na corda,

para atirarem contra todos os que têm um coração íntegro.

3Na realidade, os alicerces da lei e da ordem estão desfeitos,

que pode fazer o justo?

4O Senhor ainda está presente no seu santo templo;

ele ainda está a governar lá dos céus,

donde vigia atentamente todos os povos.

5Se por um lado põe à prova a vida do justo,

por outro, aborrece o mau e os que amam a violência.

6O Senhor fará chover fogo e enxofre sobre os maus;

um vento tempestuoso os queimará.

7Porque o Senhor é justo e ama a justiça.

Os retos verão o seu rosto.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 11:1-7

Saamu 11

Fún adarí orin. Ti Dafidi.

1Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa.

Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé:

“Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.

2Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀;

wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn

láti tafà níbi òjìji

sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.

3Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́

kí ni olódodo yóò ṣe?”

4Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀;

Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run.

Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn;

ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.

5Olúwa ń yẹ olódodo wò,

ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá

ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.

6Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò

ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó;

àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.

7Nítorí, olódodo ní Olúwa,

o fẹ́ràn òdodo;

ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.