Psalms 3 – NIV & YCB

New International Version

Psalms 3:1-8

Psalm 3In Hebrew texts 3:1-8 is numbered 3:2-9.

A psalm of David. When he fled from his son Absalom.

1Lord, how many are my foes!

How many rise up against me!

2Many are saying of me,

“God will not deliver him.”3:2 The Hebrew has Selah (a word of uncertain meaning) here and at the end of verses 4 and 8.

3But you, Lord, are a shield around me,

my glory, the One who lifts my head high.

4I call out to the Lord,

and he answers me from his holy mountain.

5I lie down and sleep;

I wake again, because the Lord sustains me.

6I will not fear though tens of thousands

assail me on every side.

7Arise, Lord!

Deliver me, my God!

Strike all my enemies on the jaw;

break the teeth of the wicked.

8From the Lord comes deliverance.

May your blessing be on your people.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 3:1-8

Saamu 3

Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu.

1Olúwa, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí!

Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!

2Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé

“Ọlọ́run kò nígbà á là.” Sela.

3Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, Olúwa;

ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.

4Olúwa ni mo kígbe sókè sí,

ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. Sela.

5Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn;

mo sì tún padà jí, nítorí Olúwa ni ó ń gbé mi ró.

6Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹgbẹ̀rún ènìyàn

tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.

7Dìde, Olúwa!

Gbà mí, Ọlọ́run mi!

Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n;

kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.

8Láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìgbàlà ti wá.

Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. Sela.