Zaburi 64 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Zaburi 64:1-10

Zaburi 64

Kuomba Ulinzi Dhidi Ya Maadui

Kwa mwimbishaji. Zaburi ya Daudi.

164:1 Za 142:2; 140:1Ee Mungu, unisikie ninapoeleza lalamiko langu,

uyahifadhi maisha yangu kutokana na vitisho vya adui.

264:2 Za 56:6; 59:2; 143:9; Kut 1:10Unifiche kutokana na shauri la siri la waovu,

kutokana na zile kelele za kundi la watenda mabaya.

364:3 Za 7:13; 58:7; 57:4; 55:21; Isa 49:2Wananoa ndimi zao kama panga

na kuelekeza maneno yao kama mishale ya kufisha.

464:4 Za 10:8; 11:2; 55:19; Ay 9:23Hurusha mishale kutoka kwenye mavizio kwa mtu asiye na hatia,

humrushia ghafula bila woga.

564:5 Za 91:3; 140:5; 119:110; 141:9; Ay 22:13Kila mmoja humtia moyo mwenzake

katika mipango mibaya;

huzungumza juu ya kuficha mitego yao,

nao husema, “Ni nani ataiona?”

6Hufanya shauri baya la dhuluma na kusema,

“Tumebuni mpango mkamilifu!”

Hakika nia na moyo wa mwanadamu vina hila.

7Bali Mungu atawapiga kwa mishale,

nao ghafula wataangushwa.

864:8 Mit 12:13; 18:7; 2Fal 10:21; Za 109:25; 59:12; Kum 28:37Atageuza ndimi zao wenyewe dhidi yao

na kuwaleta kwenye maangamizi;

wote wawaonao watatikisa vichwa vyao

kwa dharau.

964:9 Za 40:3; Yer 51:10Wanadamu wote wataogopa,

watatangaza kazi za Mungu

na kutafakari yale aliyoyatenda.

1064:10 Ay 22:19Wenye haki na wafurahi katika Bwana,

na wakimbilie kwake;

wanyofu wote wa moyo na wamsifu yeye!

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 64:1-10

Saamu 64

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

1Gbóhùn mi, Ọlọ́run, bí mo ti ń sọ àròyé mi

pa ọkàn mi mọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹ̀rù àwọn ọ̀tá.

2Pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ ìmọ̀ ìkọ̀kọ̀ àwọn ènìyàn búburú

kúrò nínú ọ̀pọ̀ igbe lọ́wọ́ ìrúkèrúdò oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.

3Wọ́n pọ́n ahọ́n wọn bí idà,

wọ́n sì fa ọrun wọn le láti tafà wọn, àní ọ̀rọ̀ kíkorò.

4Wọ́n tafà ní ìkọ̀kọ̀ sí àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀:

wọ́n tafà si lójijì, wọn kò sì bẹ̀rù.

5Wọ́n, gba ara wọn níyànjú nínú èrò búburú,

wọ́n sọ̀rọ̀ lórí dídẹkùn sílẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀

wọ́n wí pé, “Ta ni yóò rí wa?”

6Wọ́n gbìmọ̀ àìṣòdodo, wọ́n wí pé,

“A wa ti parí èrò tí a gbà tán”

lóòótọ́ àyà àti ọkàn ènìyàn kún fún àrékérekè.

7Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ta wọ́n ní ọfà;

wọn ó sì gbọgbẹ́ lójijì.

8Ahọ́n wọn yóò sì dojú ìjà kọ wọ́n, yóò sì run wọ́n,

Gbogbo ẹni tí ó bá rí wọn yóò sì mi orí fún wọn.

9Gbogbo ènìyàn yóò máa bẹ̀rù

wọn ó kéde iṣẹ́ Ọlọ́run

wọn ó dúró lé ohun tí ó ṣe.

10Jẹ́ kí olódodo kí ó yọ̀ nínú Olúwa

yóò sì rí ààbò nínú rẹ̀.

Gbogbo ẹni ìdúró ṣinṣin ní ọkàn yóò máa yìn ín.