Yeremia 31 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Yeremia 31:1-40

Mahamisho Kurudi Kwa Shangwe

131:1 Law 26:12; Yer 30:22“Wakati huo, nitakuwa Mungu wa koo zote za Israeli nao watakuwa watu wangu,” asema Bwana.

231:2 Hes 14:20; Kut 33:14; Kum 12:9Hili ndilo asemalo Bwana:

“Watu watakaopona upanga

watapata upendeleo jangwani;

nitakuja niwape Israeli pumziko.”

331:3 Rum 11:28; Kum 4:37; Hos 11:4; Yn 6:44Bwana alitutokea wakati uliopita, akisema:

“Nimekupenda kwa upendo wa milele,

nimekuvuta kwa wema.

431:4 Yer 30:18-19; 2Fal 19:21; Mwa 31:27; Kut 15:20; Yer 30:19Nitakujenga tena nawe utajengeka upya,

ewe Bikira Israeli.

Utachukua tena matari yako

na kwenda kucheza na wenye furaha.

531:5 Yer 33:13; Oba 1:19; Isa 65:12; Amo 9:14; Kum 20:6; Yer 50:19; Isa 37:30Utapanda tena shamba la mizabibu

juu ya vilima vya Samaria,

wakulima watapanda

na kufurahia matunda yake.

631:6 Kum 33:19; Mik 4:2; Isa 52:8; 56:10; Yer 50:4-5Itakuja siku wakati walinzi watakapowapigia kelele

juu ya vilima vya Efraimu wakisema,

‘Njooni, twendeni juu Sayuni,

kwake Bwana Mungu wetu.’ ”

731:7 Kum 28:13; Isa 61:9; Za 14:7; 28:9; Isa 37:31; 12:6Hili ndilo asemalo Bwana:

“Mwimbieni Yakobo kwa furaha,

mpigieni kelele aliye mkuu wa mataifa.

Zifanyeni sifa zenu zisikike, nanyi mseme,

‘Ee Bwana, okoa watu wako,

mabaki ya Israeli.’

831:8 Yer 3:18; Mwa 33:13; Za 106:47; Isa 42:16; Eze 34:16; 34:12-14Tazama, nitawaleta kutoka nchi ya kaskazini

na kuwakusanya kutoka miisho ya dunia.

Miongoni mwao watakuwepo vipofu na viwete,

mama wajawazito na wenye utungu wa kuzaa.

Umati mkubwa wa watu utarudi.

931:9 Ezr 3:12; Za 126:5; Isa 63:13; Za 126:5; Isa 63:13; 40:4; 49:11; Kut 4:22; Hes 20:8Watakuja wakilia;

wataomba wakati ninawarudisha.

Nitawaongoza kando ya vijito vya maji

katika mapito yaliyo tambarare ambapo hawatajikwaa,

kwa sababu mimi ndimi baba wa Israeli,

naye Efraimu ni mzaliwa wangu wa kwanza.

1031:10 Isa 66:19; Kum 30:4; Isa 11:12; 40:11; Eze 34:12; Yer 25:22; Law 26:33“Sikieni neno la Bwana, enyi mataifa,

litangazeni katika nchi za pwani ya mbali:

‘Yeye aliyewatawanya Israeli atawakusanya

na atalichunga kundi lake la kondoo kama mchungaji.’

1131:11 Kut 6:6; Isa 44:23; Za 142:6; 9:16Kwa kuwa Bwana atamlipia fidia Yakobo

na kuwakomboa mkononi mwa walio na nguvu kuliko wao.

1231:12 Eze 40:2; Mik 4:1; Yoe 3:18; Hes 18:12; Hos 2:21-22; Wim 4:15; Yn 16:22; Isa 58:11; Wim 4:15; Isa 30:19Watakuja na kupiga kelele kwa furaha katika miinuko ya Sayuni;

watashangilia ukarimu wa Bwana:

nafaka, divai mpya na mafuta,

wana-kondoo wachanga

na ndama wa makundi ya ngʼombe nitakaowapa.

Watakuwa kama bustani iliyonyeshewa vizuri,

wala hawatahuzunika tena.

1331:13 Isa 61:3; Za 30:11; Isa 51:11Kisha wanawali watacheza na kufurahi,

vijana waume na wazee pia.

Nitageuza maombolezo yao kuwa furaha,

nitawapa faraja na furaha badala ya huzuni.

1431:14 Law 7:35-36; Za 36:8; Isa 30:23Nitawashibisha makuhani kwa wingi,

nao watu wangu watajazwa kwa ukarimu wangu,”

asema Bwana.

1531:15 Yos 18:25; Mwa 37:35; Yer 10:20; Mt 2:17-18; Ay 7:21Hili ndilo asemalo Bwana:

“Sauti imesikika huko Rama,

maombolezo na kilio kikubwa,

Raheli akiwalilia watoto wake

na anakataa kufarijiwa,

kwa sababu watoto wake hawako tena.”

1631:16 Za 30:5; Isa 25:8; Rut 2:12; Eze 11:17-18; 2Nya 15:7; Yer 30:3; Isa 30:19Hili ndilo asemalo Bwana:

“Izuie sauti yako kulia,

na macho yako yasitoe machozi,

kwa kuwa kazi yako itapata thawabu,”

asema Bwana.

“Watarudi kutoka nchi ya adui.

17Kwa hiyo kuna tumaini kwa siku zijazo,”

asema Bwana.

“Watoto wako watarudi nchi yao yenyewe.

1831:18 Ay 5:17; Hos 4:16; 10:11; Za 80:3-4; Mao 5:21; Yer 50:11“Hakika nimeyasikia maombolezo ya Efraimu:

‘Ulinirudi kama ndama mkaidi,

nami nimekubali kutii.

Unirudishe, nami nitarudi,

kwa sababu wewe ndiwe Bwana, Mungu wangu.

1931:19 Za 95:10; Eze 36:31; 21:12; Lk 18:13; Yer 8:4; Ezr 9:6; Za 25:7Baada ya kupotea, nilitubu;

baada ya kuelewa, nilijipiga kifua.

Niliaibika na kuona haya

kwa sababu niliibeba aibu ya ujana wangu.’

2031:20 Isa 44:21; Hos 4:4; Mik 7:18; 1Fal 3:26; Mao 3:33; Isa 55:7Je, Efraimu si mwanangu mpendwa,

mtoto ninayependezwa naye?

Ingawa mara kwa mara ninanena dhidi yake,

bado ninamkumbuka.

Kwa hiyo moyo wangu unamwonea shauku,

nina huruma kubwa kwa ajili yake,”

asema Bwana.

2131:21 Isa 35:8; Yer 50:5; Isa 52:11; Yer 3:12; Eze 21:19“Weka alama za barabara,

weka vibao vya kuelekeza.

Zingatia vyema njia kuu,

barabara ile unayoipita.

Rudi, ee Bikira Israeli,

rudi kwenye miji yako.

2231:22 Yer 2:23; Hos 4:16; Isa 43:19; Kum 32:10Utatangatanga hata lini,

ee binti usiye mwaminifu?

Bwana ameumba kitu kipya duniani:

mwanamke atamlinda mwanaume.”

2331:23 Yer 30:18; Isa 1:26; Zek 8:3; Mwa 28:3; Hes 6:24; Isa 2:2; Za 48:1Hili ndilo Bwana Mwenye Nguvu Zote, Mungu wa Israeli, asemalo, “Nitakapowarudisha toka nchi ya kutekwa kwenu, watu walio katika nchi ya Yuda na miji yake kwa mara nyingine tena watatumia maneno haya: ‘Bwana akubariki, ee makao ya haki, ee mlima mtakatifu.’ 2431:24 Yer 33:12, 18; Zek 8:4-8; Yer 30:18Watu wataishi pamoja katika Yuda na miji yake yote, wakulima na wote wanaohamahama na mifugo yao. 2531:25 Yn 4:14; Isa 40:29Nitawaburudisha waliochoka na kuwatuliza walio na huzuni.”

26Kwa jambo hili niliamka na kuangalia pande zote. Usingizi wangu ulikuwa mtamu kwangu.

2731:27 Eze 36:9-11; Hos 2:23; Yer 16:14Bwana asema, “Siku zinakuja, nitakapoongeza idadi ya watu, na kuzidisha hesabu ya mifugo katika nyumba ya Israeli na nyumba ya Yuda. 2831:28 Yer 18:8; 44:27; Kum 30; 9; Amo 9:14; Ay 29:2; Eze 36:10-11; Yer 1:10Kama vile nilivyowaangalia ili kungʼoa na kubomoa, kuharibu, kuangamiza na kuleta maafa juu yao, vivyo hivyo nitawaangalia ili kujenga na kupanda,” asema Bwana. 2931:29 Mwa 9:25; Kum 24:16; Eze 18:2; Mao 5:7“Katika siku hizo, watu hawatasema tena,

“ ‘Baba wamekula zabibu chachu,

nayo meno ya watoto yakatiwa ganzi.’

3031:30 2Fal 14:6; Gal 6:7; Isa 3:11Badala yake, kila mmoja atakufa kwa ajili ya dhambi zake mwenyewe; yeyote alaye zabibu chachu, meno yake mwenyewe yatatiwa ganzi.

3131:31 Kum 29:14; Ebr 8:8-12; Yer 33:14; Lk 22:20; Isa 42:6; 54:10; Ebr 10:16-17“Siku zinakuja,” asema Bwana,

“nitakapofanya agano jipya

na nyumba ya Israeli

na nyumba ya Yuda.

3231:32 Kut 24:8; Kum 5:3; 1:31; Yer 11:4; Isa 54:5Halitafanana na agano

nililofanya na baba zao

wakati nilipowashika mkono

kuwaongoza watoke Misri,

kwa sababu walivunja agano langu,

ijapokuwa nilikuwa mume kwao,”

asema Bwana.

3331:33 Kum 6:6; 2Kor 3:3; Yer 24:7; Ebr 10:16; Za 40:8; Kut 4:15“Hili ndilo agano nitakalofanya na nyumba ya Israeli

baada ya siku zile,” asema Bwana.

“Nitaweka sheria yangu katika nia zao,

na kuiandika mioyoni mwao.

Nitakuwa Mungu wao,

nao watakuwa watu wangu.

3431:34 1Yn 2:27; Yn 6:45; Isa 54:13; Za 85:2; Mik 7:19; Rum 11:27; Isa 11:9Mtu hatamfundisha tena jirani yake,

wala mtu kumfundisha ndugu yake akisema, ‘Mjue Bwana Mungu,’

kwa sababu wote watanijua mimi,

tangu aliye mdogo kabisa kwao, hadi aliye mkuu sana,”

asema Bwana.

“Kwa sababu nitasamehe uovu wao,

wala sitazikumbuka dhambi zao tena.”

3531:35 Za 136:7-9; Mwa 1; 16; Yer 10:16; Kut 14:21; Za 93:3Hili ndilo asemalo Bwana,

yeye aliyeweka jua

liwake mchana,

yeye anayeamuru mwezi na nyota

kungʼaa usiku,

yeye aichafuaye bahari

ili mawimbi yake yangurume;

Bwana Mwenye Nguvu Zote ndilo jina lake:

3631:36 Ay 38:33; Isa 54:9-10; Za 89:36-37; Yer 33:20-26“Ikiwa amri hizi zitaondoka machoni pangu,”

asema Bwana,

“ndipo wazao wa Israeli watakoma

kuwa taifa mbele yangu daima.”

3731:37 Ay 38:5; Yer 33:22, 24, 26; Rum 11:1-5Hili ndilo asemalo Bwana:

“Ikiwa mbingu zilizo juu zitaweza kupimika

na misingi ya dunia chini

ikaweza kuchunguzwa,

ndipo nitakapowakataa wazao wote wa Israeli

kwa sababu ya yote waliyoyatenda,”

asema Bwana.

3831:38 Yer 30:18; Neh 3:1; 2Nya 25:23; Zek 14:10; Yer 24:6; 2Fal 14:13“Siku zinakuja,” asema Bwana, “wakati mji huu utajengwa upya kwa ajili yangu, kuanzia mnara wa Hananeli hadi Lango la Pembeni. 3931:39 1Fal 7:23Kamba ya kupimia itaanzia hapo kuendelea hadi kwenye kilima cha Garebu, na kisha kugeuka kuelekea Goa. 4031:40 Yer 2:23; 7:31-32; 1Sam 15:23; Yn 18:1; 2Fal 11:16; Yoe 3:17; Zek 14:21Bonde lote watupwapo maiti na majivu pia na matuta yote kutoka Bonde la Kidroni upande wa mashariki hadi pembe ya Lango la Farasi, itakuwa takatifu kwa Bwana. Kamwe mji huu hautangʼolewa tena wala kubomolewa.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 31:1-40

1“Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.

2Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà

yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀,

Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”

3Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé:

“Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin;

mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,

4Èmi yóò tún gbé e yín sókè,

àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli.

Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé,

ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.

5Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà

ní orí òkè Samaria;

àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa

gbádùn èso oko wọn.

6Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde

lórí òkè Efraimu wí pé,

‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni,

ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’ ”

7Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé:

“Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu;

ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo.

Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé,

Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là;

àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’

8Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá;

èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé.

Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ,

aboyún àti obìnrin tí ń rọbí,

ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.

9Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún,

wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà.

Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi;

ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú,

nítorí èmi ni baba Israẹli,

Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.

10“Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè

ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn;

‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ,

yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’

11Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà

ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ

12Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni;

wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa.

Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró

ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran.

Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin,

ìkorò kò ní bá wọn mọ́.

13Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀,

bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin.

Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀,

dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú.

Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.

14Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀;

àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,”

ni Olúwa wí.

1531.15: Mt 2.18.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“A gbọ́ ohùn kan ní Rama

tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò.

Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀;

kò gbà kí wọ́n tu òun nínú,

nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”

16Báyìí ni Olúwa wí:

“Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún

àti ojú rẹ nínú omijé;

nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,”

ni Olúwa wí.

“Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.

17Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,”

ni Olúwa wí.

“Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.

18“Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé,

‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́

èmi sì ti gbọ́ ìbáwí.

Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà,

nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.

19Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà,

mo ronúpìwàdà,

lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀,

èmi lu àyà mi.

Ojú tì mí, mo sì dààmú;

nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’

20Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára

tí inú mi dùn sí bí?

Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó,

síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀.

Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un,

èmi káàánú gidigidi fún un,”

ni Olúwa wí.

21“Gbé ààmì ojú ọ̀nà dìde,

ṣe atọ́nà ààmì,

kíyèsi òpópó ọ̀nà geere

ojú ọ̀nà tí ó ń gbà.

Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli,

padà sí àwọn ìlú rẹ.

22Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó,

ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin;

Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀,

ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”

23Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’ 24Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká. 25Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”

26Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.

27“Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko. 28Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí. 29“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé:

“ ‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n

àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’

30Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.

3131.31: Lk 22.20; 1Kọ 11.25.31.31-34: Jr 32.38-40; Hb 8.8-12; 10.16-17.“Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí,

“tí Èmi yóò bá ilé Israẹli

àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.

32Kò ní dàbí májẹ̀mú

tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá,

nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́,

tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti

nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi.

Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,”

ni Olúwa wí.

33“Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá

lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé:

“Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn,

èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn.

Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn;

àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.

34Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀

tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’

nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí

láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,”

ni Olúwa wí.

“Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì,

èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”

35Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

ẹni tí ó mú oòrùn

tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán,

tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀

ràn ní òru;

tí ó rú omi Òkun sókè

tó bẹ́ẹ̀ tí Ìjì rẹ̀ fi ń hó

Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

36“Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,”

ni Olúwa wí.

“Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun

láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”

37Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè

tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀,

ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli

nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,”

ni Olúwa wí.

38“Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè. 39Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa. 40Gbogbo Àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo Àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”