Yeremia 12 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Yeremia 12:1-17

Lalamiko La Yeremia

112:1 Ay 8:3; 12:6; Dan 9:14; Ay 21:7, 13; Ezr 9:15; Ay 5:8; Eze 18:25; Yer 5:27-28Wewe daima u mwenye haki, Ee Bwana,

niletapo mashtaka mbele yako.

Hata hivyo nitazungumza nawe kuhusu hukumu yako:

Kwa nini njia ya waovu inafanikiwa?

Kwa nini wasio waaminifu

wote wanaishi kwa raha?

212:2 Isa 29:13; Eze 22:27; Yer 11:17; Mk 7:6; Ay 5:3; Yer 3:10; Mt 15:8; Tit 1:16Umewapanda, nao wameota,

wanakua na kuzaa matunda.

Daima u midomoni mwao,

lakini mbali na mioyo yao.

312:3 Yer 17:18; Za 7:9; 11:5; Yer 20:11; 16:18Hata hivyo unanijua mimi, Ee Bwana;

unaniona na kuyachunguza mawazo yangu kukuhusu wewe.

Wakokote kama kondoo wanaokwenda kuchinjwa!

Watenge kwa ajili ya siku ya kuchinjwa!

412:4 Yer 4:25-28; Yoe 1:10-12; Kum 28:15-18; Za 107:34; Yer 4:26; 9:10Je, nchi itakaa katika hali ya kuomboleza mpaka lini,

na majani katika kila shamba kunyauka?

Kwa sababu wale waishio ndani yake ni waovu,

wanyama na ndege wameangamia.

Zaidi ya hayo, watu wanasema,

Bwana hataona yatakayotupata sisi.”

Jibu La Mungu

512:5 Yer 49:19; 50:44“Ikiwa umeshindana mbio na watu kwa mguu na wakakushinda,

unawezaje kushindana na farasi?

Ikiwa unajikwaa kwenye nchi ambayo ni salama,

utawezaje kwenye vichaka kando ya Yordani?

612:6 Mit 26:24-25; Yer 9:4; Za 12:2Ndugu zako, watu wa jamaa yako mwenyewe:

hata wao wamekusaliti;

wameinua kilio kikubwa dhidi yako.

Usiwaamini, ingawa wanazungumza

mema juu yako.

7“Nitaiacha nyumba yangu,

nitupe urithi wangu;

nitamtia yeye nimpendaye

mikononi mwa adui zake.

812:8 Amo 6:8; 2Nya 36:16; Za 17:12; Hos 9:15Urithi wangu umekuwa kwangu

kama simba wa msituni.

Huningurumia mimi,

kwa hiyo ninamchukia.

912:9 Kum 28:26; Isa 56:9; Yer 15:3; Eze 23:25; 39:17-20Je, urithi wangu haukuwa

kama ndege wa mawindo wa madoadoa

ambaye ndege wengine wawindao

humzunguka na kumshambulia?

Nenda ukawakusanye pamoja wanyama wote wa mwituni;

walete ili wale.

1012:10 Yer 25:34; Eze 33:2; Isa 5:1-7; Yer 9:10; 25:11Wachungaji wengi wataliharibu shamba langu la mizabibu

na kulikanyaga shamba langu;

watalifanya shamba langu zuri

kuwa jangwa la ukiwa.

1112:11 Isa 42:25; Yer 23:10; Isa 5:6; 24:4; Yer 9:12; 14:4Litafanywa kuwa jangwa,

lililokauka na kuachwa ukiwa mbele zangu;

nchi yote itafanywa jangwa

kwa sababu hakuna hata mmoja anayejali.

1212:12 Kum 32:41; Eze 33:2; Yer 3:2; Eze 21:3-4; Isa 31:8; Yer 46:10; Eze 14:17Juu ya miinuko yote ilivyo kama jangwani

mharabu atajaa,

kwa maana upanga wa Bwana utawala,

kuanzia ncha moja ya nchi hadi nyingine;

hakuna hata mmoja atakayekuwa salama.

1312:13 Mik 6:15; Kut 15:7; Yer 4:26; Law 26:16-20; Kum 28:38Watapanda ngano lakini watavuna miiba;

watajitaabisha lakini hawatafaidi chochote.

Kwa hiyo beba aibu ya mavuno yako

kwa sababu ya hasira kali ya Bwana Mungu.”

1412:14 Zek 2:7-9; Sef 2:8-10; Yer 32:37; 2Nya 7:20; Za 9:6; Kum 29:28Hili ndilo asemalo Bwana: “Kwa habari ya majirani zangu wote wabaya wanaonyangʼanya urithi ambao ninawapa watu wangu Israeli, nitawangʼoa kutoka nchi zao, nami nitaingʼoa nyumba ya Yuda kutoka katikati yao. 1512:15 Kum 30:3; Amo 9:14-15; Eze 28:25; Za 6:2Lakini baada ya kuwangʼoa, nitawahurumia tena na kumrudisha kila mmoja wao kwenye urithi wake mwenyewe na kwenye nchi yake mwenyewe. 1612:16 Yer 4:2; Yos 23:7; Efe 2:20; Isa 26:18; 49:6; Yer 18:8; 3:17Ikiwa watajifunza vyema njia za watu wangu na kuapa kwa Jina langu, wakisema, ‘Hakika kama Bwana aishivyo,’ hata kama wakati fulani walifundisha watu wangu kuapa kwa Baali, ndipo watakapofanywa imara katikati ya watu wangu. 1712:17 Mwa 27:29; Isa 60:12; Za 2:8-9Lakini kama taifa lolote halitasikiliza na kutii, nitalingʼoa kabisa na kuliangamiza,” asema Bwana.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 12:1-17

Ọ̀rọ̀ Jeremiah

1Olúwa, olódodo ni ọ́ nígbàkúgbà,

nígbà tí mo mú ẹjọ́ kan tọ̀ ọ́ wá.

Síbẹ̀ èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀ nípa òdodo rẹ.

Èéṣe tí ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú fi ń ṣe déédé?

Èéṣe tí gbogbo àwọn aláìṣòdodo sì ń gbé ní ìrọ̀rùn?

2Ó ti gbìn wọ́n, wọ́n sì ti fi egbò múlẹ̀,

wọ́n dàgbà wọ́n sì so èso.

Gbogbo ìgbà ni ó wà ní ètè wọn,

o jìnnà sí ọkàn wọn.

3Síbẹ̀ o mọ̀ mí ní Olúwa,

o ti rí mi o sì ti dán èrò mi nípa rẹ wò.

Wọ, wọ́n lọ bí àgùntàn tí a fẹ́ pa.

Yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ pípa.

4Yóò ti pẹ́ tó tí ọ̀gbẹlẹ̀ yóò fi wà,

tí gbogbo ewéko igbó sì ń rọ?

Nítorí àwọn ènìyàn búburú ni ó ń gbé ibẹ̀.

Àwọn ẹranko àti àwọn ẹyẹ ti ṣègbé,

pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ènìyàn ń sọ pé,

“Kò lè rí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa.”

Ìdáhùn Ọlọ́run

5Bí ìwọ bá ń bá ẹlẹ́ṣẹ̀ sáré,

tí àárẹ̀ sì mú ọ,

báwo ni ìwọ yóò ṣe bá ẹṣin díje?

Bí ìwọ bá kọsẹ̀ ní ilẹ̀ àlàáfíà,

bí ìwọ bá ní ìgbẹ́kẹ̀lé,

kí ni ìwọ ó ṣe nínú ẹkùn odò Jordani?

6Àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn

ìdílé—

ti dà ọ́, kódà wọ́n ti kẹ̀yìn sí ọ

Wọ́n ti hó lé ọ lórí;

Má ṣe gbà wọ́n gbọ́

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń sọ̀rọ̀ rẹ dáradára.

7Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀,

èmi yóò fi ìní mi sílẹ̀.

Èmi yóò fi ẹni tí mo fẹ́

lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.

8Ogún mi ti rí sí mi

bí i kìnnìún nínú igbó.

Ó ń bú ramúramù mọ́ mi;

nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.

9Ogún mi kò ha ti rí sí mi

bí ẹyẹ kannakánná

tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dòyì ka, tí wọ́n sì kọjú ìjà sí i?

Ẹ lọ, kí ẹ sì kó gbogbo ẹranko igbó jọ,

ẹ mú wọn wá jẹ.

10Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́-àgùntàn ni yóò sì ba ọgbà àjàrà mi jẹ́,

tí wọn yóò sì tẹ oko mi mọ́lẹ̀;

Wọ́n ó sọ oko dídára mi di

ibi tí a ń da ìdọ̀tí sí.

11A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀

tí kò wúlò níwájú mi,

gbogbo ilẹ̀ ni yóò di ahoro

nítorí kò sí ẹnìkankan tí yóò náání.

12Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀

ni àwọn apanirun ti gorí,

nítorí idà Olúwa yóò pa

láti ìkangun kìn-ín-ní dé ìkangun èkejì ilẹ̀ náà;

kò sí àlàáfíà fún gbogbo alààyè.

13Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká,

wọn yóò fi ara wọn ṣe wàhálà, ṣùgbọ́n òfo ni èrè wọn.

Kí ojú kí ó tì yín nítorí èrè yín,

nítorí ìbínú gbígbóná Olúwa.

14Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ní ti gbogbo àwọn aládùúgbò mi búburú tí wọ́n gbẹ́sẹ̀ lé ogún tí mo fún àwọn ènìyàn Israẹli mi, Èmi yóò fà wọ́n tu kúrò lórí ilẹ̀ wọn, èmi yóò fa ìdílé Juda tu kúrò ní àárín wọn. 15Ṣùgbọ́n tí mo bá fà wọ́n tu tán, Èmi yóò padà yọ́nú sí wọn. Èmi yóò sì padà fún oníkálùkù ní ogún ìní rẹ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ ìní oníkálùkù. 16Bí wọ́n bá sì kọ ìwà àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì fi orúkọ mi búra wí pé, ‘níwọ̀n bí Olúwa ń bẹ láààyè,’ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ́ àwọn ènìyàn mi láti fi Baali búra, nígbà náà ni a ó gbé wọn ró láàrín àwọn ènìyàn mi. 17Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kan kò bá gbọ́, Èmi yóò fà á tu pátápátá, èmi yóò sì pa wọ́n run,” ni Olúwa wí.