Mika 7 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Mika 7:1-20

Taabu Ya Israeli

17:1 Yer 2:3; Hos 9:10; Wim 2:13Taabu gani hii niliyo nayo!

Nimefanana na yule akusanyaye

matunda ya kiangazi,

aokotaye masazo baada ya kuvunwa

shamba la mizabibu;

hakuna kishada chenye matunda ya kula,

hakuna hata ile tini ya mwanzoni ninayoitamani.

27:2 Za 10:8; 12:1; 57:6; Yer 2:29; 8:6; 5:26; Mit 6:17; 1Sam 24:11; Hab 1:15; Mik 3:10; Isa 3:5Wanaomcha Mungu wameondolewa kutoka nchi;

hakuna mtu mnyofu hata mmoja aliyebaki.

Watu wote wanavizia kumwaga damu,

kila mmoja anamwinda ndugu yake kwa wavu.

37:3 Mit 4:16; Kut 23:8; Hos 4:18; Isa 1:23; Eze 22:12Mikono yote miwili ni hodari katika kufanya ubaya,

mtawala anadai zawadi,

hakimu anapokea rushwa,

wenye nguvu wanaamuru wanachotaka:

wote wanafanya shauri baya pamoja.

47:4 Hes 33:55; Eze 2:6; Ay 31:14; 2Sam 23:6; Isa 22:5; Hos 9:7Aliye mwema kupita wote kati yao

ni kama mchongoma,

anayeonekana mnyofu zaidi miongoni mwao

ni mbaya kuliko uzio wa miiba.

Siku ya walinzi wako imewadia,

siku atakayokutembelea Mungu.

Sasa ni wakati wao

wa kuchanganyikiwa.

5Usimtumaini jirani;

usiweke matumaini kwa rafiki.

Hata kwa yule alalaye kifuani mwako

uwe mwangalifu kwa maneno yako.

67:6 Eze 22:7; Mwa 9:22-24; Mt 10:21, 35-36; Mk 13:12Kwa kuwa mwana humdharau baba yake,

naye binti huinuka dhidi ya mama yake,

mkwe kuwa kinyume na mama mkwe wake:

adui wa mtu ni wale wa nyumbani mwake hasa.

77:7 Isa 21:8; 25:9; Za 4:3; 130:5Lakini mimi, namtazama Bwana kwa matumaini,

namngoja Mungu Mwokozi wangu;

Mungu wangu atanisikia mimi.

Israeli Atainuka

87:8 Za 20:8; 22:17; 37:24; 37:5, 6; Mit 24:17; Mik 4:11; Mao 4:21; 2Sam 22:29; Isa 9:2Usifurahie msiba wangu, ee adui yangu!

Ingawa nimeanguka, nitainuka.

Japo ninaketi gizani,

Bwana atakuwa nuru yangu.

97:9 Mao 3:39-40; Za 107:10; 119:154; Isa 46:13Kwa sababu nimetenda dhambi dhidi yake,

nitabeba ghadhabu ya Bwana,

mpaka atakaponitetea shauri langu

na kuithibitisha haki yangu.

Atanileta nje kwenye mwanga,

nami nitaiona haki yake.

107:10 Za 35:26; 42:3; Isa 5:5; 51:23; Ay 40:12; Zek 10:5; 2Sam 22:43Kisha adui yangu ataliona

naye atafunikwa na aibu,

yule aliyeniambia,

“Yu wapi Bwana Mungu wako?”

Macho yangu yataona kuanguka kwake,

hata sasa atakanyagwa chini ya mguu

kama tope barabarani.

117:11 Amo 9:11; Isa 54:11Siku ya kujenga kuta zako itawadia,

siku ya kupanua mipaka yako.

127:12 Isa 19:23-25; 11:11; 60:4Siku hiyo watu watakuja kwako

kutoka Ashuru na miji ya Misri,

hata kutoka Misri hadi Frati

na kutoka bahari hadi bahari

na kutoka mlima hadi mlima.

137:13 Isa 3:10-11; Eze 12:19; 33:28-29Dunia itakuwa ukiwa kwa sababu ya wakazi wake,

kwa sababu ya matunda ya matendo yao.

Sala Na Sifa

147:14 Za 23:4; 28:9; 95:7; Mik 5:4; 7:14; Hes 23:9; Kum 33:28; Wim 4:1; Isa 33:9; Yer 50:19; Eze 36:11Wachunge watu wako kwa fimbo yako,

kundi la urithi wako,

ambalo linaishi peke yake msituni,

katika nchi ya malisho yenye rutuba.

Waache walishe katika Bashani na Gileadi

kama ilivyokuwa siku za kale.

157:15 Kut 3:20; Za 78:12“Kama siku zile mlipotoka Misri,

nitawaonyesha maajabu yangu.”

167:16 Isa 26:11; Amu 18:19Mataifa yataona na kuaibika,

waliondolewa nguvu zao zote.

Wataweka mikono yao kwenye vinywa vyao

na masikio yao yatakuwa na uziwi.

177:17 Mwa 3:14; 2Sam 22:46; Isa 25:3; 59:19Wataramba mavumbi kama nyoka,

kama viumbe vitambaavyo juu ya ardhi.

Watatoka nje ya mapango yao wakitetemeka;

watamgeukia Bwana Mungu wetu kwa hofu

nao watakuogopa.

187:18 Kut 10:8; 1Sam 2:2; Isa 43:25; 54:9; 57:16; Zek 3:4; Yer 31:20; 50:20; Kut 15:11; 34:6, 7, 9; Za 89:6-8; 103:9; 2Nya 6:21; 30:9; Za 103:8-13; Yoe 2:32; Amo 5:15; Mik 2:12Ni nani Mungu kama wewe,

ambaye anaachilia dhambi

na kusamehe makosa

ya mabaki ya urithi wake?

Wewe huwi na hasira milele,

bali unafurahia kuonyesha rehema.

197:19 Isa 43:25; Rum 6:6; Yer 31:34Utatuhurumia tena,

utazikanyaga dhambi zetu

chini ya nyayo zako,

na kutupa maovu yetu yote

katika vilindi vya bahari.

207:20 Gal 3:16; Kum 11:29; 7:8; Lk 1:72; Za 108:4Utakuwa wa kweli kwa Yakobo,

nawe utamwonyesha Abrahamu rehema,

kama ulivyowaahidi kwa kiapo baba zetu

siku za kale.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 7:1-20

Ìrora Israẹli

1Ègbé ni fún mi!

Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ,

ìpèsè ọgbà àjàrà;

kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ,

kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.

2Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà,

kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́;

gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀,

olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.

3Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú;

àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn,

àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀

alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́,

gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.

4Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún,

ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ.

Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé,

àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò.

Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.

5Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́;

ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan.

Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni

tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.

67.6: Mt 10.21,35,36; Mk 13.12; Lk 12.53.Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀,

ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀,

aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀,

ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.

7Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí Olúwa,

Èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi;

Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.

Israẹli yóò dìde

8Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi;

Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde.

Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn

Olúwa yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.

9Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i,

Èmi yóò faradà ìbínú Olúwa,

títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò,

tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi.

Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀;

èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.

10Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i

ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé,

“Níbo ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wà?”

Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀;

nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀

bí ẹrẹ̀ òpópó.

11Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé,

ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.

12Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ

láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti

àní láti Ejibiti dé Eufurate

láti Òkun dé Òkun

àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.

13Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀,

nítorí èso ìwà wọn.

Àdúrà àti ìyìn

14Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ,

èyí tí ó ń dágbé nínú igbó

ní àárín Karmeli;

Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi

bí ọjọ́ ìgbàanì.

15“Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá,

ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”

16Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n,

nínú gbogbo agbára wọn.

Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn,

etí wọn yóò sì di.

17Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò,

wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló.

Wọn yóò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa,

wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.

18Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀,

ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì,

tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀?

Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé

nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.

19Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa;

òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀,

yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.

207.20: Lk 1.55.Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu

ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu,

bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa

láti ọjọ́ ìgbàanì.