Isaya 37 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Isaya 37:1-38

Kuokolewa Kwa Yerusalemu Kunatabiriwa

(2 Wafalme 19:1-7)

137:1 2Nya 34:19; Mwa 37:34; 1Fal 8:33; Mt 21:13Mfalme Hezekia aliposikia haya, akararua nguo zake na kuvaa nguo ya gunia, naye akaenda katika Hekalu la Bwana. 237:2 2Fal 22:14; Isa 13:1; 36:3; 2Fal 18:18Akawatuma Eliakimu msimamizi wa nyumba ya mfalme, Shebna mwandishi, na viongozi wa makuhani, wote wakiwa wamevaa nguo za magunia, waende kwa nabii Isaya mwana wa Amozi. 337:3 Isa 66:9; Hos 13:13; 2Fal 19:3; Amu 6:2; Isa 5:30; 26:18Wakamwambia, “Hili ndilo asemalo Hezekia: Siku hii ni siku ya dhiki, ya kukaripiwa na ya aibu, kama wakati watoto wanapofikia karibu kuzaliwa na kumbe hakuna nguvu ya kuwazaa. 437:4 Yak 5:14-15; Isa 36:13, 18-20; Amo 7:2; 2Nya 32:17; Yos 3:10; 1Sam 7:8Yamkini Bwana, Mungu wako atayasikia maneno ya jemadari wa jeshi, ambaye bwana wake, mfalme wa Ashuru, amemtuma kumdhihaki Mungu aliye hai, tena kwamba atamkemea kwa maneno ambayo Bwana, Mungu wako ameyasikia. Kwa hiyo omba kwa ajili ya mabaki ambao bado wako.”

5Maafisa wa Mfalme Hezekia walipofika kwa Isaya, 637:6 Yos 1:9; Isa 7:4; Hes 15:30Isaya akawaambia, “Mwambieni bwana wenu, ‘Hili ndilo asemalo Bwana: Usiogope kwa hayo uliyoyasikia, yale maneno ambayo watumishi wa mfalme wa Ashuru wamenitukana nayo. 737:7 Isa 31:8; 1Nya 5:26Sikiliza! Nitatia roho fulani ndani yake ili kwamba atakaposikia taarifa fulani, atarudi nchi yake mwenyewe, nami huko nitafanya auawe kwa upanga.’ ”

837:8 Hes 33:20; Neh 11:30; Yer 34:7; Yos 10:3Jemadari wa jeshi aliposikia kwamba mfalme wa Ashuru ameondoka Lakishi, alirudi, akamkuta mfalme akipigana na Libna.

937:9 2Nya 32:11; Isa 20:3Basi Senakeribu akapata taarifa kwamba Tirhaka, Mkushi mfalme wa Misri, alikuwa anaenda kupigana naye. Aliposikia jambo hili akatuma wajumbe kwa Hezekia na neno hili: 1037:10 2Nya 32:11, 15; Isa 36:15“Mwambieni Hezekia mfalme wa Yuda: Usikubali huyo Mungu unayemtumainia akudanganye wakati anaposema, ‘Yerusalemu haitatiwa mkononi mwa mfalme wa Ashuru.’ 1137:11 Isa 36:18-20Hakika umesikia yale ambayo wafalme wa Ashuru wametenda kwa nchi zote, wakiwaangamiza kabisa. Je, wewe utaokolewa? 1237:12 Mwa 12:1-4; Mdo 7:2; 2Fal 18:11Je, miungu ya mataifa ambayo yaliangamizwa na baba zangu iliweza kuwaokoa? Yaani miungu ya Gozani, Harani, Resefu, na ya watu wa Edeni waliokuwa Telasari? 1337:13 Isa 10:9; 2Fal 17:24; Isa 36:20Yuko wapi mfalme wa Hamathi, mfalme wa Arpadi, mfalme wa mji wa Sefarvaimu, au wa Hena au wa Iva?”

Maombi Ya Hezekia

1437:14 2Nya 32:17; 1Fal 8:33Hezekia akapokea barua kutoka kwa wale wajumbe naye akaisoma. Kisha akapanda katika Hekalu la Bwana, akaikunjua mbele za Bwana. 1537:15 2Nya 32:20Naye Hezekia akamwomba Bwana akisema: 1637:16 Kum 10:17; Za 46:10; Kut 25:22; Mwa 3:24; Za 86:10; Dan 4:34; Mdo 4:24“Ee Bwana Mwenye Nguvu Zote, Mungu wa Israeli, uketiye juu ya kiti cha enzi kati ya makerubi, wewe peke yako ndiwe Mungu juu ya falme zote za dunia. Wewe umeumba mbingu na nchi. 1737:17 Dan 9:18; Yer 25:29; 2Nya 6:40; 1Fal 8:29; 2Nya 32:17Tega sikio, Ee Bwana, usikie; fungua macho yako, Ee Bwana, uone; sikiliza maneno yote ambayo Senakeribu ametuma kumtukana Mungu aliye hai.

1837:18 2Fal 15:29; Nah 2:11-12“Ni kweli, Ee Bwana, kwamba wafalme wa Ashuru wameyaangamiza mataifa haya yote pamoja na nchi zao. 1937:19 Isa 36:20; Yer 2:11; Gal 4:8; Yos 7:15; Isa 26:14; 2Nya 13:9; Isa 40:18-20; 44:9-11Wameitupa miungu yao kwenye moto na kuiangamiza, kwa kuwa haikuwa miungu, bali miti na mawe tu, iliyotengenezwa kwa mikono ya wanadamu. 2037:20 1Sam 17:46; Za 46:10; Mit 20:22; Yos 4:24Sasa basi, Ee Bwana Mungu wetu, tuokoe kutoka mkononi mwake, ili kwamba falme zote duniani zipate kujua kwamba wewe peke yako, Ee Bwana, ndiwe Mungu.”

Kuanguka Kwa Senakeribu

(2 Wafalme 19:20-37)

2137:21 Isa 37:2Kisha Isaya mwana wa Amozi akapeleka ujumbe kwa Hezekia, akasema: “Hili ndilo asemalo Bwana, Mungu wa Israeli: Kwa sababu umeniomba kuhusu Senakeribu mfalme wa Ashuru, 2237:22 Isa 23:12; 10:32; Ay 16:4hili ndilo neno ambalo Bwana amelisema dhidi yake:

“Bikira binti Sayuni anakudharau na kukudhihaki.

Binti Yerusalemu anatikisa kichwa chake unapokimbia.

2337:23 Hes 15:30; Dan 7:25; Isa 2:11; 52:5; Eze 36:20-23; Ay 15:25; Isa 12:6Ni nani uliyemtukana na kumkufuru?

Ni nani uliyeinua sauti yako dhidi yake,

na kumwinulia macho yako kwa kiburi?

Ni dhidi ya yule Aliye Mtakatifu wa Israeli!

2437:24 Isa 14:8; 36:9; 1Fal 5:8-10; Isa 14:5, 13; 41:19; Hos 14:8Kupitia kwa wajumbe wako

umelundika matukano juu ya Bwana.

Nawe umesema,

‘Kwa magari yangu mengi ya vita,

nimepanda juu ya vilele vya milima,

vilele vya juu sana katika Lebanoni.

Nami nimeiangusha mierezi yake mirefu,

misunobari yake iliyo bora sana.

Nimefikia sehemu zake zilizoinuka juu sana,

misitu yake iliyo mizuri sana.

2537:25 Kum 11:10; Dan 4:30; Isa 19:6; 44:27; 10:14Nimechimba visima katika nchi za kigeni

na kunywa maji yake.

Kwa nyayo za miguu yangu

nimekausha vijito vyote vya Misri.’

2637:26 Mdo 4:27-28; 1Pet 2:8; Isa 25:1-2; Kum 13:16; Mdo 2:23; Isa 10:6“Je, hujasikia?

Zamani sana niliamuru hili.

Siku za kale nilipanga hili;

sasa nimelifanya litokee,

kwamba umegeuza miji yenye ngome

kuwa malundo ya mawe.

2737:27 Isa 15:6; Za 129:6Watu wa miji hiyo wameishiwa nguvu,

wanavunjika mioyo na kuaibishwa.

Wao ni kama mimea katika shamba,

kama machipukizi mororo ya kijani,

kama majani yachipuayo juu ya paa la nyumba,

ambayo hukauka kabla ya kukua.

2837:28 Za 139:1-3; 2:1“Lakini ninajua mahali ukaapo,

kutoka kwako na kuingia kwako,

na jinsi unavyoghadhibika dhidi yangu.

2937:29 Isa 10:12; Ay 41:2; 40:24; Eze 38:4; Amo 4:2; 2Nya 33:11Kwa sababu unaghadhibika na ufidhuli dhidi yangu,

na kwa sababu ufidhuli wako umefika masikioni mwangu,

nitaweka ndoana yangu puani mwako

na hatamu yangu kinywani mwako,

nami nitakufanya urudi kwa njia ile uliyoijia.

3037:30 Isa 20:3; 32:10; 16:14; Law 25:4; Yer 31:5; Za 107:37“Hii ndiyo itakuwa ishara kwako, ee Hezekia:

“Mwaka huu utakula kile kiotacho chenyewe,

na mwaka wa pili utakula kutoka machipukizi yake.

Lakini katika mwaka wa tatu panda na uvune,

panda mashamba ya mizabibu na ule matunda yake.

3137:31 Isa 27:6; 11:10Mara nyingine tena mabaki ya nyumba ya Yuda

wataeneza mizizi chini na kuzaa matunda juu.

3237:32 Isa 11:11; 1:9; 9:7Kwa kuwa kutoka Yerusalemu watakuja mabaki,

na kutoka Mlima Sayuni kundi la walionusurika.

Wivu wa Bwana Mwenye Nguvu Zote,

ndio utatimiza jambo hili.

3337:33 Isa 32:18; 2Sam 20:15“Kwa hiyo hili ndilo asemalo Bwana kuhusu mfalme wa Ashuru:

“Hataingia katika mji huu

wala hatapiga mshale hapa.

Hatakuja mbele yake na ngao

wala kupanga majeshi kuuzingira.

3437:34 Isa 37:29Kwa njia ile aliyoijia ndiyo atakayorudi;

hataingia katika mji huu,”

asema Bwana.

3537:35 Isa 31:5; 38:6; Eze 48:9-11; 36:21-22; 2Fal 20:6; 1Nya 17:19“Nitaulinda mji huu na kuuokoa,

kwa ajili yangu mwenyewe,

na kwa ajili ya Daudi mtumishi wangu!”

3637:36 Kut 12:12, 23; Isa 10:12Ndipo malaika wa Bwana akaenda, akawaua wanajeshi 185,000 katika kambi ya Waashuru. Wenzao walipoamka asubuhi yake, walikuta maiti kila mahali! 3737:37 Mwa 10:11; Nah 1:1; 2Nya 32:1Basi Senakeribu mfalme wa Ashuru akavunja kambi na kuondoka. Akarudi Ninawi na kukaa huko.

3837:38 Mwa 8:4; Yer 51:27; 2Fal 17:24; Isa 14:25; 9:4; 10:26Siku moja, alipokuwa akiabudu katika hekalu la mungu wake Nisroki, wanawe Adrameleki na Shareza wakamuua kwa upanga, nao wakakimbilia nchi ya Ararati. Naye Esar-Hadoni mwanawe akawa mfalme badala yake.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 37:1-38

A sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìdáǹdè Jerusalẹmu

1Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ. 2Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi. 3Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí: ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn. 4Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”

5Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah, 6Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí: Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi. 7Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’ ”

8Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.

9Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí: 10“Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘a kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’ 11Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí? 12Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari? 13Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”

Àdúrà Hesekiah

14Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa. 15Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa: 16Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé. 17Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.

18“Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán. 19Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe. 20Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”

Ìṣubú Sennakeribu

21Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé: Nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria, 22èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀:

“Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni

ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà.

Ọmọbìnrin Jerusalẹmu

ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.

23Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí?

Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè

tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga?

Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!

24Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ

Ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa.

Tì wọ sì wí pé,

‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi

ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá,

sí ibi gíga jùlọ Lebanoni.

Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀,

àti ààyò igi firi rẹ̀.

Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ,

igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.

25Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì

mo sì mu omi ní ibẹ̀,

pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi

Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’

26“Ṣé o kò tí ì gbọ́?

Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀.

Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀;

ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ,

pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di

àkójọpọ̀ àwọn òkúta

27Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù,

ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì.

Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá,

gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun,

gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé,

tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.

28“Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà

àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ

àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.

29Nítorí pé inú rẹ ru sí mi

àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti

dé etí ìgbọ́ mi,

Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú,

àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu,

èmi yóò sì jẹ́ kí o padà

láti ọ̀nà tí o gbà wá.

30“Èyí ni yóò ṣe ààmì fún ọ Ìwọ Hesekiah:

“Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnrarẹ̀,

àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ.

Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè,

ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.

31Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda

yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.

32Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá,

àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà.

Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.

33“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria:

“Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá

tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín

Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà

tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.

34Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ;

òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,”

ni Olúwa wí.

35“Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là,

nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”

36Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú! 37Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.

38Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.