Ayubu 31 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Ayubu 31:1-40

131:1 Kum 5:18; Mt 5:18“Nimefanya agano na macho yangu

yasimtazame msichana kwa kumtamani.

231:2 Ay 16:19; 20:29Kwa kuwa fungu la mwanadamu ni gani kutoka kwa Mungu juu,

urithi wake kutoka kwa Mungu Mwenye Nguvu Aliye juu?

331:3 Ay 21:30; 34:22; Rum 2:9Je, si uharibifu kwa watu waovu,

maangamizi kwa wale watendao mabaya?

431:4 2Nya 16:9; Mit 5:21; Yer 32:19; Dan 4:37Je, yeye hazioni njia zangu

na kuihesabu kila hatua yangu?

531:5 Ay 15:31; Mik 2:11“Kama nimeishi katika uongo

au mguu wangu umekimbilia udanganyifu,

631:6 Law 19:36; Ay 6:2Mungu na anipime katika mizani za uaminifu,

naye atajua kwamba sina hatia:

731:7 Ay 9:30; Hes 15:39; Eze 6:9; Mt 5:29; Mhu 11:9kama hatua zangu zimepotoka kutoka kwenye njia,

kama moyo wangu umeongozwa na macho yangu,

au kama mikono yangu imetiwa unajisi,

831:8 Law 26:16; Yn 4:37; Mik 6:15basi wengine na wale nilichokipanda,

nayo yale yote niliyootesha na yangʼolewe.

931:9 Kum 11:16; Yak 1:14“Kama moyo wangu umeshawishiwa na mwanamke,

au kama nimevizia mlangoni mwa jirani yangu,

1031:10 Kum 28:30; Yer 8:16; Mit 14:31basi mke wangu na asage nafaka ya mwanaume mwingine,

nao wanaume wengine walale naye.

1131:11 Law 20:10; Yn 8:4-5Kwa kuwa hilo lingekuwa aibu,

naam, dhambi ya kuhukumiwa.

1231:12 Ay 15:30; 26:6Ni moto uwakao kwa Uharibifu;31:12 Kwa Kiebrania ni Abadon (Ay 26:6; Mit 15:11).

ungekuwa umengʼoa mavuno yangu.

1331:13 Kut 21:2-11; Law 25:39-46“Kama ningewanyima haki watumishi wangu wanaume au vijakazi wangu,

walipokuwa na manungʼuniko dhidi yangu,

1431:14 Ay 33:5; Hos 9:7; Za 10:13, 15; Isa 10:3; Yer 5:31nitafanya nini Mungu atakaponikabili?

Nitamjibu nini nitakapoitwa kutoa hesabu?

1531:15 Ay 10:3; Efe 6:9Je, yeye aliyeniumba tumboni mwa mama yangu,

si ndiye aliwaumba?

Je, si ni yeye huyo mmoja aliyetuumba sote

ndani ya mama zetu?

1631:16 Law 25:17; Ay 20:19; Yak 1:27“Ikiwa nimewanyima maskini haja zao,

au kuyaacha macho ya wajane yadhoofike,

1731:17 Ay 6:27; 29:12kama nimekula chakula changu mwenyewe,

bila kuwashirikisha yatima;

1831:18 Isa 51:18lakini tangu ujana wangu nimemlea yatima kama ambavyo baba angefanya,

nami tangu kuzaliwa kwangu nimewaongoza wajane:

1931:19 Ay 22:6; 24:4; Isa 58:7kama nilimwona yeyote akiteseka kwa kukosa nguo,

au mtu mhitaji asiye na mavazi

2031:20 Ay 29:13; Amu 6:37ambaye wala moyo wake haukunibariki

kwa kumpatia joto kwa mavazi ya manyoya ya kondoo zangu,

2131:21 Ay 22:7-9; Yak 1:27na kama nimeinua mkono wangu dhidi ya yatima,

nikijua kuwa nina ushawishi mahakamani,

2231:22 Hes 15:30; Za 10:15basi mkono wangu na unyofoke toka begani mwangu,

nao na uvunjike kutoka kiungio chake.

2331:23 Ay 10:3; 13:11; Mwa 20:11Kwa kuwa niliogopa uharibifu kutoka kwa Mungu,

nami kwa kuuogopa utukufu wake sikuweza kufanya mambo kama hayo.

2431:24 Ay 22:25; Mk 10:24; Lk 12:15“Kama nimeweka tumaini langu kwenye dhahabu,

au kuiambia dhahabu safi, ‘Wewe ndiwe salama yangu,’

2531:25 Mwa 12:16; Isa 10:14kama nimefurahia wingi wa utajiri wangu,

ustawi ambao mikono yangu ilikuwa imepata,

2631:26 Hes 11:20; Kum 4:19; Eze 8:16kama nimelitazama jua katika kungʼaa kwake

au mwezi ukienda kwa fahari yake,

2731:27 Ay 24:15; Yak 1:14; Yer 8:2; 16:11hivyo moyo wangu kushawishiwa kwa siri,

au kubusu mkono wangu kwa kuviheshimu,

2831:28 Mwa 38:24; Kum 17:2-7; Yos 24:23-27; Mit 30:9basi hiyo pia ingekuwa dhambi ya kuhukumiwa,

kwa kuwa ningekuwa si mwaminifu kwa Mungu aishiye juu sana.

2931:29 Za 35:15; Mt 5:44; Mit 17:5; 24:17-18“Kama nimeshangilia msiba wa adui yangu,

au kutazama kwa furaha taabu iliyomjia,

30lakini sikuruhusu kinywa changu kufanya dhambi

kwa kuomba laana dhidi ya maisha yake;

31kama watu wa nyumbani mwangu kamwe hawakusema,

‘Ni nani ambaye hajashibishwa na nyama ya Ayubu?’

3231:32 Amu 19:20; Mt 25:35; Ebr 13:2; 1Pet 4:9Lakini hakuna mgeni aliyelala njiani,

kwa maana mlango wangu ulikuwa wazi kwa msafiri;

3331:33 Za 32:5; Mit 28:13; Mwa 3:8kama nimeifunika dhambi yangu kama wanadamu wengine wafanyavyo,

kwa kuficha hatia yangu moyoni mwangu,

3431:34 Kut 23:2; Mit 29:25kwa sababu ya kuogopa umati wa watu,

na hivyo kuwa na hofu ya kudharauliwa na jamaa,

nikanyamaza kimya nisitoke nje ya mlango:

35(“Laiti kama angekuwepo mtu wa kunisikia!

Tazama sasa ninatia sahihi kwenye utetezi wangu:

Mwenyezi na anijibu;

mshtaki wangu na aweke mashtaka yake kwenye maandishi.

36Hakika ningeyavaa begani mwangu,

ningeyavaa kama taji.

3731:37 Ay 1:3; 21:28Ningempa hesabu ya kila hatua yangu,

ningemwendea kama mwana wa mfalme.)

3831:38 Mwa 4:10“Kama nchi yangu inalia dhidi yangu,

na mifereji yake yote imelowana kwa machozi,

3931:39 1Fal 21:19; Law 19:13; Yak 5:4kama nimekula mazao yake bila malipo,

au kuvunja mioyo ya wapangaji wake,

4031:40 Mwa 3:18; Mit 13:7basi miiba na iote badala ya ngano,

na magugu badala ya shayiri.”

Mwisho wa maneno ya Ayubu.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 31:1-40

Àwíjàre Jobu

1“Mo ti bá ojú mi dá májẹ̀mú,

èmi yó ha ṣe tẹjúmọ́ wúńdíá?

2Nítorí pé kí ni ìpín Ọlọ́run láti ọ̀run wá?

Tàbí kí ni ogún Olódùmarè láti òkè ọ̀run wá.

3Kò ṣe pé àwọn ènìyàn búburú ni ìparun wà fún,

àti àjàkálẹ̀-ààrùn fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀?

4Òun kò ha ri ipa ọ̀nà mi,

òun kò ha sì ka gbogbo ìṣísẹ̀ mi?

5“Bí ó bá ṣe pé èmi bá fi àìṣòótọ́ rìn,

tàbí tí ẹsẹ̀ mi sì yára sí ẹ̀tàn;

6(Jẹ́ kí Ọlọ́run wọ́n mí nínú ìwọ̀n òdodo,

kí Ọlọ́run le mọ ìdúró ṣinṣin mi.)

7Bí ẹsẹ̀ mí bá yà kúrò lójú ọ̀nà,

tí àyà mí sì tẹ̀lé ipa ojú mi,

tàbí bí àbàwọ́n kan bá sì lẹ̀ mọ́ mi ní ọwọ́,

8Ǹjẹ́ kí èmi kí ó gbìn kí ẹlòmíràn kí ó sì mújẹ,

àní kí a fa irú-ọmọ mi tu.

9“Bí àyà mi bá di fífà sí ipasẹ̀ obìnrin kan,

tàbí bí mo bá lọ í ba de ènìyàn ní ẹnu-ọ̀nà ilé aládùúgbò mi,

10Kí àyà mi kí ó lọ ọlọ fún ẹlòmíràn,

kí àwọn ẹlòmíràn kí ó tẹ̀ ara wọn ní ara rẹ̀.

11Nítorí pé yóò jẹ́ ohun ìtìjú

àní, ẹ̀ṣẹ̀ tí a ó ṣe onídàájọ́ rẹ̀

12Nítorí pé iná ní èyí tí ó jó dé ibi ìparun,

tí ìbá sì fa gbòǹgbò ohun ìbísí mi gbogbo tu.

13“Tí mo bá sì ṣe àìka ọ̀ràn ìránṣẹ́kùnrin mi

tàbí ìránṣẹ́bìnrin mi sí,

nígbà tí wọ́n bá ń bá mi jà;

14Kí ni èmi ó ha ṣe nígbà tí Ọlọ́run bá dìde?

Nígbà tí ó bá sì ṣe ìbẹ̀wò, ohùn kí ni èmi ó dá?

15Ẹni tí ó dá mi ní inú kọ́ ni ó dá a?

Ẹnìkan náà kí ó mọ wá ní inú ìyá wa?

16“Bí mo bá fa ọwọ́ sẹ́yìn fún ìfẹ́ inú tálákà,

tàbí bí mo bá sì mú kí ojú opó rẹ̀wẹ̀sì,

17Tàbí tí mo bá nìkan bu òkèlè mi jẹ,

tí aláìní baba kò jẹ nínú rẹ̀;

18nítorí pé láti ìgbà èwe mi wá ni a ti tọ́ ọ dàgbà pẹ̀lú mi bí ẹni pé baba,

èmi sì ń ṣe ìtọ́jú opó láti inú ìyá mi wá:

19Bí èmi bá rí olùpọ́njú láìní aṣọ,

tàbí tálákà kan láìní ìbora;

20Bí ọkàn rẹ̀ kò bá súre fún mi,

tàbí bí ara rẹ̀ kò sì gbóná nípasẹ̀ irun àgùntàn mi;

21Bí mo bá sì gbé ọwọ́ mi sókè sí aláìní baba,

nítorí pé mo rí ìrànlọ́wọ́ mi ní ẹnu ibodè,

22Ǹjẹ́, ní apá mi kí o wọ́n kúrò ní ihò èjìká rẹ̀,

kí apá mi kí ó sì ṣẹ́ láti egungun rẹ̀ wá.

23Nítorí pé ìparun láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ẹ̀rù ńlá fún mi,

àti nítorí ọláńlá rẹ̀ èmi kò le è dúró.

24“Bí ó bá ṣe pé mo fi wúrà ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé mi,

tàbí tí mo bá wí fún fàdákà dídára pé, ‘Ìwọ ni ààbò mi;’

25Bí mo bá yọ̀ nítorí ọrọ̀ mí pọ̀,

àti nítorí ọwọ́ mi dara lọ́pọ̀lọpọ̀;

26Bí mo bá bojú wo oòrùn nígbà tí ń ràn,

tàbí òṣùpá tí ń ràn nínú ìtànmọ́lẹ̀,

27Bí a bá tàn ọkàn mi jẹ: Láti fi

ẹnu mi kò ọwọ́ mi:

28Èyí pẹ̀lú ni ẹ̀ṣẹ̀ ti àwọn onídàájọ́ ní láti bẹ̀wò.

Nítorí pé èmí yóò jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run tí ó wà lókè.

29“Bí ó bá ṣe pé mo yọ̀ sì ìparun ẹni tí ó kórìíra mi.

Tàbí bí mo bá sì gbéraga sókè, nígbà tí ibi bá a.

30Bẹ́ẹ̀ èmi kò sì jẹ ki ẹnu mi ki ó ṣẹ̀

nípa fífẹ́ ègún sí ọkàn rẹ̀.

31Bí àwọn ènìyàn inú àgọ́ mi kò bá lè wí pé,

ta ni kò ì tí ì jẹ ẹran rẹ̀ ní àjẹyó?

32(Àlejò kò wọ̀ ni ìgboro rí;

èmí ṣí ìlẹ̀kùn mi sílẹ̀ fún èrò.)

33Bí mo bá bò ẹ̀ṣẹ̀ mi mọ́lẹ̀ bí Adamu ni pápá,

ẹ̀bi mi pamọ́ ni àyà mi.

34Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni mo ha bẹ̀rù bí?

Tàbí ẹ̀gàn àwọn ìdílé ní ń bà mí ní ẹ̀rù?

Tí mo fi pa ẹnu mọ́, tí èmí kò sì fi sọ̀rọ̀ jáde?

35(“Ìbá ṣe pé ẹnìkan le gbọ́ ti èmí!

Kíyèsi i, ààmì mi, kí Olódùmarè kí ó dá mi lóhùn!

Kí èmí kí ó sì rí ìwé náà tí olùfisùn mi ti kọ!

36Nítòótọ́ èmí ìbá gbé le èjìká mi,

èmi ìbá sì dé bí adé mọ́ orí mi.

37Èmi ìbá sì sọ iye ìṣísẹ̀ mi fún un,

bí ọmọ-aládé ni èmi ìbá súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀.)

38“Bí ilẹ̀ mi bá sì ké rara lòdì sí mi

tí a sì fi omijé kún gbogbo poro rẹ̀.

39Bí mo bá jẹ èso oko mi láìsan owó

tàbí tí mo sì mú ọkàn olúwa rẹ̀ fò lọ,

40kí ẹ̀gún òṣùṣú kí ó hù dípò alikama,

àti èpò búburú dípò ọkà barle.”

Ọ̀rọ̀ Jobu parí.