ዘዳግም 32 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ዘዳግም 32:1-52

1ሰማያት ሆይ፤ አድምጡ፤ እኔም እናገራለሁ፤

ምድር ሆይ፤ አንቺም የአፌን ቃል ስሚ።

2ትምህርቴ እንደ ዝናብ ትውረድ፤

ቃሌም እንደ ጤዛ ይንጠባጠብ፤

በቡቃያ ሣር ላይ እንደ ካፊያ፣

ለጋ ተክልም ላይ እንደ ከባድ ዝናብ ይውረድ።

3እኔ የእግዚአብሔርን (ያህዌ) ስም ዐውጃለሁ፤

የአምላካችንን (ኤሎሂም) ታላቅነት አወድሱ!

4እርሱ ዐለት፣ ሥራውም ፍጹም ነው፤

መንገዱም ሁሉ ትክክል ነው፤

የማይሳሳት ታማኝ አምላክ፣

ቀጥተኛና ጻድቅ አምላክም እርሱ ነው።

5በእርሱ ላይ ክፋት ፈጽመዋል፤ ከነውራቸው የተነሣ ከእንግዲህ ልጆቹ አይደሉም፤

ወልጋዳና ጠማማ ትውልዶች ናቸው32፥5 ወይም የተጣመሙት እነርሱ እንጂ የእርሱ ልጆች አይደሉም

6አንተ ተላላና ጥበብ የጐደለህ ሕዝብ፣

ለእግዚአብሔር (ለያህዌ) የምትመልስለት በዚህ መንገድ ነውን?

አባትህ ፈጣሪህ32፥6 ወይም ያወጣህ አባትህ።

የሠራህና ያበጀህ እርሱ አይደለምን?

7የጥንቱን ዘመን አስታውስ፤

አባትህን ጠይቅ፤ ይነግርሃልም፤

ሽማግሌዎችህንም ጠይቅ፤ ያስረዱሃል።

8ልዑል ለአሕዛብ ርስታቸውን በሰጠ ጊዜ፣

የሰውንም ዘር በለያየ ጊዜ፣

በእስራኤል ልጆች32፥8 የማሶሬቱ ቅጅ፣ የሙት ባሕር ጥቅልል እንዲሁም የሰብዓ ሊቃናት ትርጕም፣ የእግዚአብሔር ልጆች ይላሉ። ቍጥር ልክ፣

የአሕዛብን ርስት ድንበር ለየ፤

9የእግዚአብሔር (ያህዌ) ድርሻ የገዛ ሕዝቡ፣

ያዕቆብ የተለየ ርስቱ ነውና።

10እርሱን በምድረ በዳ፣

ባዶና ጭው ባለ በረሓ ውስጥ አገኘው፤

ጋሻ ሆነው፤ ተጠነቀቀለትም፤

እንደ ዐይኑ ብሌን ጠበቀው።

11ንስር ጐጆዋን በትና፣

በጫጩቶቿም ላይ እንደምትረብብ፣

እነርሱን ለመያዝ ክንፎቿን እንደምትዘረጋ፣

በክንፎቿም እንደምትሸከማቸው፣

12እግዚአብሔር (ያህዌ) ብቻ መራው፤

ምንም ባዕድ አምላክ አብሮት አልነበረም።

13በምድር ከፍታ ላይ አወጣው፤

የዕርሻንም ፍሬ መገበው፤

ከዐለት ድንጋይ ማር አበላው፤

ከባልጩትም ድንጋይ ዘይት መገበው።

14የላሙንና የበጉን መንጋ ቅቤና ወተት፣

የሰቡትን በጎችና ፍየሎች፣

የባሳንን ምርጥ አውራ በግ፣

መልካም የሆነውንም ስንዴ፣

ማለፊያውንም የወይን ጠጅ።

15ይሹሩን32፥15 ይሹሩን ማለት ቅን ወይም ትክክለኛ ማለት ሲሆን፣ ይኸውም እስራኤልን የሚያሳይ ነው። ወፈረ፤ ረገጠ፤

ጠገበ፤ ሰውነቱ ደነደነ፤ ለሰለሰ፤

የፈጠረውንም አምላክ (ኤሎሂም) ተወ፤

መጠጊያ ዐለት የሆነውን አዳኙንም ናቀ።

16በባዕዳን አማልክታቸው አስቀኑት፤

በአጸያፊ ጣዖቶቻቸውም አስቈጡት።

17አምላክ ላልሆኑ አጋንንት፦

ላላወቋቸው አማልክት፣

ከጊዜ በኋላ ለተነሡ አማልክት፣

አባቶቻችሁ ላልፈሯቸው አማልክት ሠዉ።

18አባት የሆነህን ዐለት ከዳኸው፤

የወለደህን አምላክ ረሳኸው።

19እግዚአብሔር (ያህዌ) ይህን አይቶ ናቃቸው፤

በወንድና በሴት ልጆቹ ተቈጥቷልና።

20እርሱም፣ “ፊቴን ከእነርሱ እሰውራለሁ፤

መጨረሻቸው ምን እንደሚሆንም አያለሁ” አለ፤

ጠማማ ትውልድ፣

የማይታመኑም ልጆች ናቸውና።

21አምላክ ባልሆነው አስቀኑኝ፤

በከንቱ ጣዖቶቻቸው አስቈጡኝ።

እኔም ሕዝብ ባልሆነው አስቀናቸዋለሁ።

በማያስተውልም ሕዝብ አስቈጣቸዋለሁ።

22በቍጣዬ እሳት ተቀጣጥሏልና፤

እርሱ እስከ ሲኦል ዘልቆ ይነድዳል።

ምድርን እስከ ሰብሏ ይበላል፤

የተራሮችንም መሠረት ያቀጣጥላል።

23“በመዓት ላይ መዓት አመጣባቸዋለሁ።

ፍላጻዬንም በእነርሱ ላይ እጨርሳለሁ።

24የሚያጠፋ ራብ፣ በልቶ የሚጨርስ ቸነፈርና ከባድ

መቅሠፍት እሰድድባቸዋለሁ፤

የአራዊትን ሹል ጥርስ፣ በምድር የሚሳብ የእባብ መርዝም

እሰድድባቸዋለሁ።

25ሰይፍ መንገድ ላይ ያስቀራቸዋል፤

ቤታቸውም ውስጥ ድንጋጤ ይነግሣል፤

ጕልማሳውና ልጃገረዷ፣

ሕፃኑና ሽማግሌው ይጠፋሉ።

26እበትናቸዋለሁ፤ ከሰዎችም መካከል መታሰቢያቸውን

አጠፋለሁ አልሁ፤

27ነገር ግን ጠላቶቻቸው እንዳይታበዩ፣

‘ድል ያደረገችው እጃችን እንጂ፣

እግዚአብሔር (ያህዌ) ይህን ሁሉ አላደረገም’ እንዳይሉ፣

የጠላትን መነሣሣት ሠጋሁ።”

28አእምሮ የጐደላቸው፣

ማስተዋልም የሌላቸው ናቸው።

29አስተዋዮች ቢሆኑ ኖሮ ይህን በተገነዘቡ፣

መጨረሻቸውም ምን እንደሚሆን ባስተዋሉ ነበር።

30መጠጊያ ዐለታቸው ካልሸጣቸው፣

እግዚአብሔር (ያህዌ) ካልተዋቸው በቀር፣

አንድ ሰው እንዴት ሺሑን ያሳድዳል?

ሁለቱስ እንዴት ዐሥር ሺሑን እንዲሸሹ ያደርጋሉ?

31የእነርሱ መጠጊያ ዐለት እንደ እኛ መጠጊያ

ዐለት አይደለምና፤ ጠላቶቻችንም እንኳ ይህን አይክዱም።

32ወይናቸው ከሰዶም ወይን፣

ከገሞራም ዕርሻ ይመጣል፤

የወይናቸው ፍሬ በመርዝ፣

ዘለላቸውም በምሬት የተሞላ ነው።

33ወይናቸው የእባብ መርዝ፣

የመራዥ እባብም መርዝ ነው።

34“ይህ በእኔ ዘንድ ተጠብቆ ያለ፣

በመዝገቤስ የታተመ አይደለምን?

35በቀል የእኔ ነው፤ እኔ ብድራትን እመልሳለሁ፤

ጊዜው ሲደርስ እግራቸው ይሰናከላል፤

የመጥፊያቸው ቀን ቀርቧል፤

የሚመጣባቸውም ፍርድ ፈጥኖባቸዋል።”

36ኀይላቸው መድከሙን፣

ባሪያም ሆነ ነጻ ሰው አለመቅረቱን በሚያይበት ጊዜ፣

እግዚአብሔር (ያህዌ) ለሕዝቡ ይፈርዳል፤

ለአገልጋዮቹም ይራራል።

37እንዲህም ይላል፤ “መጠጊያ ዐለት የሆኗቸው፣

እነዚያ አማልክታቸው የት አሉ?

38የመሥዋዕታቸውን ሥብ የበሉ፣

የመጠጥ ቍርባናቸውንም የወይን ጠጅ የጠጡ አማልክት ወዴት ናቸው?

እስቲ ይነሡና ይርዷችሁ!

እስቲ መጠለያ ይስጧችሁ!

39“እኔ ራሴ እርሱ እንደ ሆንሁ እዩ፤

ከእኔም በቀር ሌላ አምላክ የለም፤

እገድላለሁ፤ አድናለሁም፤

አቈስላለሁ፤ እፈውሳለሁም፤

ከእጄም የሚያስጥል ማንም የለም።

40እጄን ወደ ሰማይ አነሣለሁ፤

ለዘላለምም ሕያው እንደ ሆንሁ እናገራለሁ፤

41የሚያብረቀርቅ ሰይፌን ስዬ፣

እጄ ለፍርድ ስትይዘው፣

ባላጋራዎቼን እበቀላቸዋለሁ፤

የሚጠሉኝንም እንደ ሥራቸው እከፍላቸዋለሁ።

42ሰይፌ ሥጋ በሚበላበት ጊዜ፣

ፍላጾቼ በደም እንዲሰክሩ አደርጋለሁ፤

ደሙ የታረዱትና የምርኮኞች፣

የጠላት አለቆችም ራስ ደም ነው።”

43አሕዛብ ሆይ፤ ከሕዝቡ ጋር ደስ ይበላችሁ32፥43 ወይም፣ ሕዝቦች ሆይ፤ ደስ ይበላችሁ።32፥43 የማሶሬቱ ቅጅ፣ የሙት ባሕር ጥቅልል እንዲሁም የሰብዓ ሊቃናት ትርጕም፣ ሕዝቦች ሆይ፤ መላእክት ሁሉ ለእርሱ ይስገዱ ይላሉ።

እርሱ የአገልጋዮቹን ደም ይመልሳል፤

ጠላቶቹንም ይበቀላል።

ምድሪቱንና ሕዝቡን ይቤዣቸዋልና።

44ሙሴም ከነዌ ልጅ ከኢያሱ ጋር መጥቶ የዚህን መዝሙር ቃሎች በሕዝቡ ጆሮ ተናገረ። 45ሙሴም እነዚህን ቃሎች ሁሉ ለመላው እስራኤል ተናግሮ ከጨረሰ በኋላ፣ 46እንዲህ አላቸው፤ የዚህን ሕግ ቃሎች ሁሉ በጥንቃቄ ይጠብቁ ዘንድ ልጆቻችሁን እንድታዝዟቸው፣ እኔ ዛሬ በግልጥ የምነግራችሁን ቃሎች ሁሉ በልባችሁ አኑሩ። 47ቃሎቹ ለእናንተ ሕይወታችሁ እንጂ እንዲሁ ባዶ ቃሎች አይደሉም፤ በእነርሱ ዮርዳኖስን ተሻግራችሁ፣ በምትወርሷትም ምድር ረዥም ዘመን ትኖራላችሁ።

ሙሴ በናባው ተራራ ላይ መሞቱ

48በዚያችም ዕለት እግዚአብሔር (ያህዌ) ሙሴን እንዲህ አለው፤ 49“ከኢያሪኮ ማዶ ባለው የሞዓብ ምድር፣ ከዓባሪም ተራሮች አንዱ ወደ ሆነው ወደ ናባው ተራራ ወጥተህ ለእስራኤላውያን ርስት አድርጌ የምሰጣትን የከነዓንን ምድር አሻግረህ ተመልከት። 50ወንድምህ አሮን በሖር ተራራ ላይ እንደ ሞተና ወደ ወገኖቹ እንደ ተሰበሰበ ሁሉ፣ አንተም በወጣህበት በዚያ ተራራ ላይ ሙት፤ ወደ ወገኖችህም ተሰብሰብ። 51ይህ የሚሆንበት ምክንያት ሁለታችሁም በጺን ምድረ በዳ፣ በቃዴስ በመሪባ ውሃ አጠገብ በእኔ ላይ መታመናችሁን በእስራኤላውያን ፊት ስላጐደላችሁና ቅድስናዬንም በእስራኤላውያን መካከል ስላላከበራችሁ ነው። 52ስለዚህ ምድሪቱን ከሩቅ ሆነህ ታያታለህ እንጂ፣ ለእስራኤል ሕዝብ ወደምሰጣት ምድር አትገባም።”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Deuteronomi 32:1-52

1Fetísílẹ̀, Ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀;

ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.

2Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò,

kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì,

bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun,

bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.

3Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa,

Háà, ẹ yin títóbi Ọlọ́run wa!

4Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé,

gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo.

Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan,

Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.

532.5: Fp 2.15.Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀;

fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́,

ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.

6Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa,

Háà, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn?

Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín,

tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?

7Rántí ìgbà láéláé;

wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá.

Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ,

àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.

8Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn,

nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn,

ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn

gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.

9Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀,

Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.

10Ní aginjù ni ó ti rí i,

ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí.

Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀,

ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.

11Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń

rábàbà sórí ọmọ rẹ̀,

tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì

gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.

12Olúwa ṣamọ̀nà;

kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.

13Ó mú gun ibi gíga ayé

ó sì fi èso oko bọ́ ọ.

Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá,

àti òróró láti inú akọ òkúta wá,

14Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn

àti ti àgbò ẹran

àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́,

pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani

tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.

15Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá;

ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán.

O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ

o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.

16Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú,

ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.

17Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run,

ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí,

ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́,

ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.

18Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ;

o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.

19Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n,

nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.

20Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn,

èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí;

nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí,

àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.

2132.21: Ro 10.19; 11.11; 1Kọ 10.22.Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run,

wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú.

Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn;

èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.

22Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi,

yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀.

Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀

yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá.

23“Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí

èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.

24Èmi yóò mú wọn gbẹ,

ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n.

Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.

25Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù,

ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá.

Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.

26Mo ní èmi yóò tú wọn ká

èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,

27nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá,

kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má

ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni;

kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’ ”

28Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀,

bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.

29Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn

kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!

30Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún,

tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbàárùn-ún sá,

bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n,

bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?

31Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa,

àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.

32Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu

àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra.

Èso àjàrà wọn kún fún oró,

Ìdì wọn korò.

33Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni,

àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.

34“Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́

èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?

35Ti èmi ni láti gbẹ̀san; Èmi yóò san án fún wọn

ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ;

ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé

ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”

36Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀

yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀

nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán

tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.

37Yóò wí pé: “Òrìṣà wọn dà báyìí,

àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,

38ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn

tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn?

Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n!

Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!

39“Wò ó báyìí pé: èmi fúnra à mi, èmi ni!

Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi.

Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè,

Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná,

kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.

40Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé:

Èmi ti wà láààyè títí láé,

41nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi

àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́,

Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi

Èmi kò sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.

42Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀,

nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran:

ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn,

láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”

4332.43: Ro 15.10; Hb 1.6 (Septuagint); If 6.10; 19.2.Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀

nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀;

yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀

yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.

44Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni. 45Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli. 46Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí. 47Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”

Ikú Mose lórí òkè Nebo

48Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé, 49“Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn. 50Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀. 51Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli. 52Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”