ኢዮብ 32 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢዮብ 32:1-22

ኤሊሁ

1ኢዮብ በበኩሉ ራሱን እንደ ጻድቅ ቈጥሮ ስለ ነበር፣ እነዚህ ሦስት ሰዎች ለእርሱ መልስ መስጠታቸውን ተዉ። 2ከራም ወገን የሆነው፣ የቡዛዊው የባርክኤል ልጅ ኤሊሁ ግን ኢዮብ ከእግዚአብሔር ይልቅ ራሱን ጻድቅ ስላደረገ እጅግ ተቈጣው። 3ሦስቱ የኢዮብ ጓደኞች በኢዮብ ላይ መፍረድ32፥3 የማሶሬቱ ቅጅ ከዚህ ጋር ይስማማል፤ ጥንታዊው የዕብራውያን ጸሐፍት ትውፊት ግን ኢዮብንም ሆነ እግዚአብሔርን ኰነኑ ይላል። እንጂ፣ ነገሩን ሊያሳምኑት ስላልቻሉ፣ በእነርሱም ላይ ተቈጣ። 4ኤሊሁ፣ ሌሎቹ በዕድሜ ይበልጡት ስለ ነበር ከእነርሱ ቀድሞ ለኢዮብ ሳይናገር ቈየ። 5ነገር ግን እነዚህ ሦስቱ የሚሉትን ባጡ ጊዜ ቍጣው ነደደ።

6ስለዚህ የቡዛዊው የባርክኤል ልጅ ኤሊሁ እንዲህ አለ፤

“እኔ በዕድሜ ታናሽ ነኝ፤

እናንተ ግን አዛውንቶች ናችሁ፤

ከዚህም የተነሣ የማውቀውን ለመናገር አልደፈርሁም፤

ፈርቼ ዝም አልሁ።

7‘ዕድሜ ይናገራል፤

ረዥም ዘመን ጥበብን ያስተምራል’ ብዬ ነበር።

8ነገር ግን በሰው ያለው መንፈስ፣

ሁሉን የሚችል አምላክ እስትንፋስ፣

ማስተዋልን ይሰጣል።

9ጠቢባን የሚሆኑት በዕድሜ የገፉ32፥9 ወይም፣ ብዙ ወይም፣ ታላቅ ብቻ አይደሉም፤

የሚያስተውሉም ሽማግሌዎች ብቻ አይደሉም።

10“ስለዚህ፣ ‘ስሙኝ፣

እኔም የማውቀውን ልንገራችሁ’ እላለሁ።

11እናንተ በምትነጋገሩበት ጊዜ ታገሥሁ፤

ቃላት እየመረጣችሁ ስትናገሩ፣

በጥሞና ሰማኋችሁ፤

12በሙሉ ልብ አደመጥኋችሁ፤

ነገር ግን ከእናንተ የኢዮብን ቃል ያስተባበለ ማንም የለም፤

ለንግግሩም አጸፋ የመለሰ አልተገኘም።

13‘እኛ ጥበብ አግኝተናል፤

ሰው ሳይሆን እግዚአብሔር ይርታው’ አትበሉ።

14ኢዮብ ግን ቃሉን በእኔ ላይ አልሰነዘረም፤

እኔም እንደ እናንተ አነጋገር መልስ አልሰጠውም።

15“እነርሱ ተስፋ ቈርጠው የሚሉት የላቸውም፤

የሚናገሩትም ጠፍቷቸዋል።

16እንግዲህ እነርሱ መልስ ስላጡ፣

ጸጥ ብለውም ስለ ቆሙ፣ በትዕግሥት ልጠብቅን?

17እኔም የምለው ይኖረኛል፤

የማውቀውንም እገልጣለሁ።

18የምናገረው ሞልቶኛልና፤

በውስጤ ያለውም መንፈስ ገፋፍቶኛል።

19ውስጤ እንደ ተከደነና መተንፈሻ እንዳጣ የወይን ጠጅ፣

ሊፈነዳ እንደ ተቃረበም አዲስ የወይን ጠጅ አቁማዳ ሆኗል።

20ተናግሬ መተንፈስ አለብኝ፤

አፌንም ከፍቼ መልስ መስጠት ይገባኛል።

21ለማንም አላደላም፤

ሰውንም አላቈላምጥም።

22ማቈላመጥን ባውቅበትማ ኖሮ፣

ፈጣሪዬ ፈጥኖ ባጠፋኝ ነበር።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 32:1-22

Ọ̀rọ̀ Elihu

1Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí dákẹ́ láti dá Jobu lóhùn, nítorí ó ṣe olódodo lójú ara rẹ̀. 2Nígbà náà ni inú bí Elihu ọmọ Barakeli ará Busi, láti ìbátan ìdílé Ramu; ó bínú si Jobu nítorí ti ó dá ara rẹ̀ láre kàkà ki ó dá Ọlọ́run láre. 3Inú sì bí i sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, nítorí tí wọn kò rí ọ̀nà láti dá Jobu lóhùn bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá Jobu lẹ́bi. 4Ǹjẹ́ Elihu ti dúró títí tí Jobu fi sọ̀rọ̀ tán nítorí tí àwọn wọ̀nyí dàgbà ju òun lọ ní ọjọ́ orí. 5Nígbà tí Elihu rí i pé ìdáhùn ọ̀rọ̀ kò sí ní ẹnu àwọn ọkùnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí nígbà náà ni ó bínú.

6Elihu, ọmọ Barakeli, ará Busi, dáhùn ó sì wí pé:

“Ọmọdé ni èmi,

àgbà sì ní ẹ̀yin;

ǹjẹ́ nítorí náà ní mo dúró,

mo sì ń bẹ̀rù láti fi ìmọ̀ mi hàn yin.

7Èmi wí pé ọjọ́ orí ni ìbá sọ̀rọ̀,

àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ní ìbá kọ́ ni ní ọgbọ́n.

8Ṣùgbọ́n ẹ̀mí kan ní ó wà nínú ènìyàn

àti ìmísí Olódùmarè ní ì sì máa fún wọn ní òye.

9Ènìyàn ńláńlá kì í ṣe ọlọ́gbọ́n,

Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbà ní òye ẹ̀tọ́ kò yé.

10“Nítorí náà ní èmí ṣe wí pé: Ẹ dẹtí sílẹ̀ sí mi;

èmí pẹ̀lú yóò fi ìmọ̀ mi hàn.

11Kíyèsi i, èmí ti dúró de ọ̀rọ̀ yín;

Èmi fetísí àròyé yín,

nígbà tí ẹ̀yin ń wá ọ̀rọ̀ ti ẹ̀yin yóò sọ;

12àní, mo fiyèsí yín tinútinú.

Sì kíyèsi i, kò sí ẹnìkan nínú yín tí ó le já Jobu ní irọ́;

tàbí tí ó lè dá a lóhùn àríyànjiyàn rẹ̀!

13Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe wí pé, ‘Àwa wá ọgbọ́n ní àwárí;

Ọlọ́run ni ó lè bì í ṣubú kì í ṣe ènìyàn.’

14Bí òun kò ti sọ̀rọ̀ sí mi,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi ọ̀rọ̀ yín dá a lóhùn.

15“Ẹnu sì yà wọ́n, wọn kò sì dáhùn mọ́,

wọ́n ṣíwọ́ ọ̀rọ̀ í sọ.

16Mo sì retí, nítorí wọn kò sì fọhùn, wọ́n dákẹ́ jẹ́ẹ́;

wọn kò sì dáhùn mọ́.

17Bẹ́ẹ̀ ni èmí ó sì dáhùn nípa ti èmi,

èmí pẹ̀lú yóò sì fi ìmọ̀ mi hàn.

18Nítorí pé èmi kún fún ọ̀rọ̀ sísọ,

ẹ̀mí ń rọ̀ mi ni inú mi.

19Kíyèsi i, ikùn mi dàbí ọtí wáìnì, tí kò ní ojú-ìhò;

ó múra tán láti bẹ́ bí ìgò-awọ tuntun.

20Èmí ó sọ, kí ara kí ó le rọ̀ mí,

èmí ó sí ètè mi, èmí ó sì dáhùn.

21Lóòtítọ́ èmi kì yóò ṣe ojúsàájú sí ẹnìkankan,

bẹ́ẹ̀ ni èmí kì yóò sì ṣe ìpọ́nni fún ẹnìkan.

22Nítorí pé èmí kò mọ̀ ọ̀rọ̀ ìpọ́nni í sọ ní ṣíṣe bẹ́ẹ̀,

Ẹlẹ́dàá mi yóò mú mi kúrò lọ́gán.