ኢዮብ 15 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢዮብ 15:1-35

ኤልፋዝ

1ቴማናዊው ኤልፋዝ እንዲህ ሲል መለሰ፤

2“ጠቢብ ሰው በከንቱ ንግግር መልስ ይሰጣልን?

ወይስ በምሥራቅ ነፋስ ሆዱን ይሞላል?

3በማይረባ ቃል፣

ፍሬ ቢስ በሆነም ንግግር ይከራከራልን?

4አንተ ግን እግዚአብሔርን መፍራት ታጣጥላለህ፤

አምልኮተ እግዚአብሔርን ትከለክላለህ።

5ኀጢአትህ አፍህን ታስተምረዋለች፤

የተንኰለኞችንም አነጋገር መርጠህ ትይዛለህ።

6የሚፈርድብህ አንደበትህ እንጂ እኔ አይደለሁም፣

የሚመሰክርብህም እኔ ሳልሆን የገዛ ከንፈርህ ነው።

7“ለመሆኑ ከሰው ሁሉ ቀድመህ የተወለድህ አንተ ነህን?

ወይስ ከኰረብቶች በፊት ተገኝተሃል?

8በእግዚአብሔር የመማክርት ጉባኤ ላይ ነበርህን?

ጥበብስ የተሰጠው ለአንተ ብቻ ነው?

9እኛ የማናውቀው አንተ ግን የምታውቀው ምን ነገር አለ?

እኛስ የሌለን አንተ ያለህ ማስተዋል የቱ ነው?

10በዕድሜ ከአባትህ የሚበልጡ፣

የሸበቱ ሽማግሌዎች ከእኛ ጋር አሉ።

11የእግዚአብሔር ማጽናናት፣

በርጋታ የተነገረህ ቃል አነሰህን?

12ልብህ ለምን ይሸፍታል?

ዐይንህንስ ምን ያጕረጠርጠዋል?

13በእግዚአብሔር ላይ እንድትቈጣ፣

እንደዚህ ያለ ቃል ከአፍህ እንዲወጣ ያደረገህ ምንድን ነው?

14“ንጹሕ ይሆን ዘንድ ሰው ምንድን ነው?

ጻድቅስ ይሆን ዘንድ፣ ከሴት የተወለደ ምንድን ነው?

15እነሆ፤ እግዚአብሔር በቅዱሳኑ እንኳ አይታመንም፤

ሰማያትም በእርሱ ፊት ንጹሓን አይደሉም።

16ታዲያ፣ ክፋትን እንደ ውሃ የሚጠጣ፣

አስጸያፊና ርኩስ ሰውማ እንዴት ይታመን!

17“አድምጠኝ፤ በግልጽ አስረዳሃለሁ፤

ያየሁትንም እነግርሃለሁ፤

18ጠቢባን ከአባቶቻቸው የተቀበሉትን፤

ሳይሸሽጉ የተናገሩትን አስረዳሃለሁ፤

19ምድሪቱ ለአባቶቻቸው ተሰጠች፤

በመካከላቸውም ባዕድ አልተቀመጠም፤

20ክፉ ሰው ዕድሜውን ሙሉ፣

ጨካኙም በተመደበለት ዘመን ሁሉ ይሠቃያል።

21የሚያስደነግጥ ድምፅ በጆሮው ላይ ይጮኻል፤

በሰላም ጊዜ ቀማኞች አደጋ ያደርሱበታል።

22ከጨለማ ወጥቶ ማምለጥ ይፈራል፤

ለሰይፍም የተመደበ ነው።

23የአሞራ እራት15፥23 ወይም ለአሞራ እራት ለመፈለግ ለመሆን ይቅበዘበዛል፤

የጨለማ ቀን መቅረቡን ያውቃል።

24ጭንቀትና ሐዘን ያስፈራሩታል፤

ለማጥቃት እንደ ተዘጋጀ ንጉሥም ያይሉበታል፤

25እጁን በእግዚአብሔር ላይ አንሥቷልና፤

ሁሉን የሚችለውን አምላክም ደፍሯል፤

26ወፍራምና ጠንካራ ጋሻ አንግቦ፣

ሊቋቋመው ወጥቷል።

27“ፊቱ በስብ ቢሸፈን፣

ሽንጡ በሥጋ ቢደነድንም፣

28መኖሪያው በፈራረሱ ከተሞች፣

የፍርስራሽ ክምር ለመሆን በተቃረቡ፣

ሰው በማይኖርባቸው ወና ቤቶች ውስጥ ይሆናል።

29ከእንግዲህ ባለጠጋ አይሆንም፤ ሀብቱም አይቈይም፤

ይዞታውም በምድር ላይ አይሰፋም።

30ከጨለማ አያመልጥም፤

ቅርንጫፎቹን ነበልባል ያደርቃቸዋል፤

በእግዚአብሔርም እስትንፋስ ይወሰዳል።

31በአጸፋው አንዳች አያገኝምና፤

ከንቱን ነገር በመታመን ራሱን አያታልል።

32ጊዜው ሳይደርስ ይጠወልጋል፤

ቅርንጫፉም አይለመልምም።

33ፍሬው በጮርቃነት እንደ ተለቀመበት የወይን ተክል፣

አበባውም እንደ ረገፈበት የወይራ ዛፍ ይሆናል።

34የዐመፀኞች ጉባኤ ትመክናለች፤

የጉቦ ሱሰኞችም ድንኳን በእሳት ትበላለች።

35መከራን ይፀንሳሉ፤ ክፋትንም ይወልዳሉ፤

በሆዳቸውም ተንኰል ይጠነስሳሉ።”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 15:1-35

Elifasi tako ọrọ̀ Jobu

1Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé:

2“Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán, kí

ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?

3Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní

èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?

4Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì,

ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.

5Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀

rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.

6Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi;

àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.

7“Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí?

Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?

8Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí, tàbí

ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?

9Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀?

Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?

10Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa,

tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.

11Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ?

Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?

12Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri,

kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.

13Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run,

tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?

14“Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́,

àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?

15Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀,

àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,

16mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí,

tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.

17“Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi;

Èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,

18ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti

ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́,

19Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan,

ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.

20Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá,

pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo,

àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.

21Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀;

nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.

22Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn;

a sì ṣà á sápá kan fún idà.

23Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà?

Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.

24Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un

bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.

25Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì

sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,

26Ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga,

àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.

27“Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀

lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.

28Òun sì gbé inú ahoro ìlú,

àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé

mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.

29Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò

lè dúró pẹ́; Bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.

30Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn;

ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀,

àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.

31Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ.

Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.

32A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀,

ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.

33Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù,

yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.

34Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè

yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.

35Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀,

ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”