ኢሳይያስ 62 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢሳይያስ 62:1-12

አዲሱ የጽዮን ስም

1ጽድቋ እንደ ማለዳ ወጋገን እስኪፈነጥቅ፣

ድነቷ እንደሚያንጸባርቅ ፋና እስኪታይ፣

ስለ ጽዮን ዝም አልልም፤

ስለ ኢየሩሳሌምም ጸጥ አልልም።

2መንግሥታት ጽድቅሽን፣

ነገሥታት ክብርሽን ያያሉ፤

የእግዚአብሔር አፍ በሚያወጣልሽ፣

በአዲስ ስም ትጠሪያለሽ።

3በእግዚአብሔር እጅ የክብር አክሊል፣

በአምላክሽም እጅ የመንግሥት ዘውድ ትሆኛለሽ።

4ከእንግዲህ፣ “የተተወች” ብለው አይጠሩሽም፤

ምድርሽም፣ “የተፈታች” አትባልም፤

ነገር ግን፣ “ደስታዬ በእርሷ” ትባያለሽ፤

ምድርሽም፣ “ባለ ባል” ትባላለች፤

እግዚአብሔር በአንቺ ደስ ይለዋል፤

ምድርሽም ባለ ባል ትሆናለች።

5ጕልማሳ ድንግሊቱን እንደሚያገባ፣

ልጆችሽ62፥5 ወይም፣ ግንበኞችሽ እንዲሁ ያገቡሻል፤

ሙሽራ በሙሽራዪቱ ደስ እንደሚለው፣

አምላክሽም በአንቺ ደስ ይለዋል።

6ኢየሩሳሌም ሆይ፤ ዘብ ጠባቂዎችን በቅጥሮችሽ ላይ አቁሜአለሁ፤

ቀንም ሆነ ሌሊት ፈጽሞ አይታክቱም።

እናንት ወደ እግዚአብሔር አቤት፣ አቤት የምትሉ፤

ፈጽሞ አትረፉ፤

7ኢየሩሳሌምን እስኪያጸናት፣

የምድርም ምስጋና እስኪያደርጋት ዕረፍት አትስጡት።

8እግዚአብሔር በቀኝ እጁ፣

በኀያል ክንዱም እንዲህ ሲል ምሏል፤

“ከእንግዲህ እህልሽን፣

ለጠላቶችሽ መብል እንዲሆን አልሰጥም፤

ከእንግዲህ የደከምሽበትን፣

አዲስ የወይን ጠጅ ባዕዳን አይጠጡትም።

9ነገር ግን መከሩን የሰበሰቡ ይበሉታል፤

እግዚአብሔርንም ያመሰግናሉ፤

የወይኑን ፍሬ የለቀሙም በመቅደሴ

አደባባዮች ይጠጡታል።”

10ዕለፉ፤ በበሮቹ በኩል ዕለፉ፤

ለሕዝቡ መንገድ አዘጋጁ፤

አስተካክሉ፤ ጐዳናውን አስተካክሉ፤

ድንጋዩን አስወግዱ፤

ለመንግሥታትም ምልክት አሳዩ።

11እግዚአብሔር እስከ ምድር ዳርቻ፣

እንዲህ ሲል ዐውጇል፤

“ለጽዮን ሴት ልጅ፣

‘እነሆ፤ አዳኝሽ መጥቷል፤

ዋጋሽ በእጁ አለ፤

ዕድል ፈንታሽም ከእርሱ ጋር ነው’ በሏት።”

12እነርሱም ቅዱስ ሕዝብ፣

እግዚአብሔር የተቤዣቸው ተብለው ይጠራሉ፤

አንቺም የምትፈለግ፣

ከእንግዲህም የማትተው ከተማ ትባያለሽ።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 62:1-12

Orúkọ Sioni tuntun

1Nítorí Sioni èmi kì yóò dákẹ́,

nítorí i Jerusalẹmu èmi kì yóò sinmi ẹnu,

títí tí òdodo rẹ̀ yóò fi tàn bí òwúrọ̀,

àti ìgbàlà rẹ̀ bí i fìtílà tí ń jó geere.

262.2: If 2.17.Àwọn orílẹ̀-èdè yóò rí òdodo rẹ,

àti gbogbo ọba ògo rẹ

a ó sì máa pè ọ́ ní orúkọ mìíràn

èyí tí ẹnu Olúwa yóò fi fún un.

3Ìwọ yóò sì jẹ́ adé dídán ní ọwọ́ Olúwa,

adé ọba ní ọwọ́ Ọlọ́run rẹ.

4Wọn kì yóò pè ọ́ ní ìkọ̀sílẹ̀ mọ́

tàbí kí wọ́n pe ilẹ̀ rẹ ní ahoro.

Ṣùgbọ́n a ó máa pè ọ́ ní Hẹfsiba,

àti ilẹ̀ rẹ ní Beula;

nítorí Olúwa yóò yọ́nú sí ọ

àti ilẹ̀ rẹ ni a ó gbé níyàwó.

5Gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́mọkùnrin tí í gbé ọ̀dọ́mọbìnrin níyàwó

bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin rẹ yóò gbé ọ níyàwó

Gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ṣe é yọ̀ lórí ìyàwó rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run rẹ yóò yọ̀ lórí rẹ.

6Èmi ti fi olùṣọ́ ránṣẹ́ sórí odi rẹ ìwọ Jerusalẹmu;

wọn kì yóò lè dákẹ́ tọ̀sán tòru.

Ẹ̀yin tí ń ké pe Olúwa,

ẹ má ṣe fúnrayín ní ìsinmi,

7àti kí ẹ má ṣe fún òun pẹ̀lú ní ìsinmi

títí tí yóò fi fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀

tí yóò sì fi ṣe ìyìn orí ilẹ̀ ayé.

8Olúwa ti búra pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀

àti nípa agbára apá rẹ:

“Èmi kì yóò jẹ́ kí ìyẹ̀fun rẹ

di oúnjẹ fún ọ̀tá rẹ

bẹ́ẹ̀ ni àwọn àjèjì kì yóò mu wáìnì

tuntun rẹ mọ́

èyí tí ìwọ ti ṣe làálàá fún;

9ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá kóórè rẹ̀ ni yóò jẹ ẹ́,

tí wọn ó sì yin Olúwa,

àti àwọn tí wọ́n bá kó àjàrà jọ ni wọn ó mú un,

nínú àgbàlá ilé mímọ́ mi.”

10Ẹ kọjá, ẹ kọjá ní ẹnu ibodè náà!

Ẹ tún ọ̀nà ṣe fún àwọn ènìyàn.

Ẹ mọ ọ́n sókè, ṣe ojú ọ̀nà òpópó!

Ẹ ṣa òkúta kúrò

Ẹ gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè.

11Olúwa ti ṣe ìkéde

títí dé òpin ilẹ̀ ayé:

“Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Sioni pé,

‘kíyèsi i, Olùgbàlà rẹ ń bọ̀!

Kíyèsi i, èrè ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀,

àti ẹ̀san rẹ̀ pẹ̀lú n tẹ̀lé e lẹ́yìn.’ ”

12A ó sì pè wọ́n ní Ènìyàn Mímọ́,

ẹni ìràpadà Olúwa;

a ó sì máa pè ọ́ ní ìwákiri,

Ìlú tí a kì yóò kọ̀sílẹ̀.