ኢሳይያስ 24 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢሳይያስ 24:1-23

እግዚአብሔር ምድርን ፈጽሞ ያጠፋታል

1እነሆ፤ እግዚአብሔር ምድርን ባድማ ያደርጋታል፤

ፈጽሞ ያጠፋታል፤

የፍርስራሽ ክምር ያደርጋታል፤

ነዋሪዎቿንም ይበትናል።

2ነገሩ ሁሉ አንድ ዐይነት ይሆናል፤

በሕዝቡ ላይ የሚሆነው በካህኑ፣

በአገልጋዩ ላይ የሚሆነው በጌታው፣

በአገልጋይዋ ላይ የሚሆነው በእመቤቷ፣

በገዥው ላይ የሚሆነው በሻጩ፣

በተበዳሪው ላይ የሚሆነው በአበዳሪው፣

በብድር ከፋይ ላይ የሚሆነው በብድር ሰጪው ይሆናል።

3ምድር ፈጽሞ ባድማ ትሆናለች፤

ጨርሶም ትበዘበዛለች፤

እግዚአብሔር ይህን ቃል ተናግሯልና።

4ምድር ትደርቃለች፤ ትረግፋለች፤

ዓለም ትዝላለች፤ ትረግፋለች፤

የምድርም መሳፍንት ይዝላሉ።

5ምድር በሕዝቧ ትረክሳለች፤

ሕግን ጥሰዋል፤

ሥርዐትን ተላልፈዋል፤

ዘላለማዊውንም ኪዳን አፍርሰዋል።

6ስለዚህ ርግማን ምድርን ትበላለች፤

ሕዝቦቿም ስለ በደላቸው ይቀጣሉ፤

ስለዚህ የምድር ነዋሪዎች ተቃጥለዋል፤

በጣም ጥቂት የሆኑት ቀርተዋል።

7አዲሱ የወይን ጠጅ ዐለቀ፤ የወይኑም ተክል ደረቀ፤

ደስተኞችም ሁሉ አቃሰቱ።

8የከበሮ ደስታ ጸጥ አለ፤

የጨፋሪዎች ጩኸት አበቃ፤

ደስ የሚያሰኘውም በገና እረጭ አለ።

9ከእንግዲህ እየዘፈኑ የወይን ጠጅ አይጠጡም፤

መጠጡም ለሚጠጡት ይመርራል።

10የፈራረሰችው ከተማ ባድማ ሆነች፤

የየቤቱም መግቢያ ተዘጋ።

11በየአደባባዩ የወይን ጠጅ ያለህ እያሉ ይጮኻሉ፤

ደስታው ሁሉ ወደ ሐዘን ይለወጣል፤

ሐሤቱም ሁሉ ከምድር ገጽ ጠፍቷል።

12ከተማዪቱ ፈጽማ ፈርሳለች፤

በሮቿም ደቅቀው ወድቀዋል።

13የወይራ ዛፍ ሲመታ፣

የወይንም ዘለላ ሲቈረጥ ቃርሚያ እንደሚቀር ሁሉ፣

በምድሪቱ ላይ፣

በሕዝቦችም ላይ እንዲሁ ይሆናል።

14ድምፃቸውን ከፍ ያደርጋሉ፤ በደስታም ይጮኻሉ፤

ከምዕራብም የእግዚአብሔርን ክብር ያስተጋባሉ።

15ስለዚህ በምሥራቅ ለእግዚአብሔር ክብር ስጡ፤

ከባሕር ደሴቶችም፣

የእስራኤልን አምላክ፣ የእግዚአብሔርን ስም ከፍ ከፍ አድርጉ።

16“ለጻድቁ ክብር ይሁን” የሚል ዝማሬ፣

ከምድር ዳርቻ ሰማን፤

እኔ ግን፣ “ከሳሁ፤ መነመንሁ፤

ወዮልኝ!

ከዳተኞች አሳልፈው ሰጡ፤

ከዳተኞች በክሕደታቸው አሳልፈው ሰጡ” አልሁ።

17በምድር የምትኖር ሕዝብ ሆይ፤

ሽብር፣ ጕድጓድና ወጥመድ ይጠብቁሃል።

18ከሽብር ድምፅ የሚሸሽ፣

ወደ ጕድጓድ ይገባል፤

ከጕድጓድ የወጣም፣

በወጥመድ ይያዛል።

የሰማይ መስኮቶች ተከፍተዋልና፤

የምድርም መሠረት ተናወጠ።

19ምድር ተከፈለች፤

ምድር ተሰነጠቀች፤

ምድር ፈጽማ ተናወጠች።

20ምድር እንደ ሰካራም ዞረባት፤

ነፋስ እንደሚወዘውዘውም ጐጆ ሆነች፣

የዐመፅዋ ሸክም ከባድ ስለሆነ ትወድቃለች፤

እንደ ገናም አትነሣም።

21በዚያ ቀን እግዚአብሔር

በላይ በሰማያት ያሉትን ኀይሎች፣

በታችም በምድር ያሉትን ነገሥታት ይቀጣቸዋል።

22በጕድጓድ ውስጥ እንዳሉ እስረኞች፣

በአንድ ላይ ይታጐራሉ፤

በእስር ቤት ይዘጋባቸዋል24፥22 ወይም፣ ይላቀቃሉ

ከብዙ ቀንም በኋላ ለፍርድ ይቀርባሉ።

23የሰራዊት ጌታ እግዚአብሔር

በጽዮን ተራራና በኢየሩሳሌም፣

በሽማግሌዎቹም ፊት በክብሩ ይነግሣል፤

ጨረቃ ትሸማቀቃለች፤ ፀሓይም ታፍራለች።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 24:1-23

Ìparun Olúwa lórí ilẹ̀ ayé

1Kíyèsi i, Olúwa yóò sọ ohun

gbogbo dòfo ní ilẹ̀ ayé

yóò sì pa á run

òun yóò pa ojú u rẹ̀ rẹ́

yóò sì fọ́n àwọn olùgbé ibẹ̀ káàkiri—

2bákan náà ni yóò sì rí

fún àlùfáà àti àwọn ènìyàn,

fún ọ̀gá àti ọmọ ọ̀dọ̀,

fún ìyá-ilé àti ọmọbìnrin,

fún olùtà àti olùrà,

fún ayáni àti atọrọ

fún ayánilówó àti onígbèsè.

3Ilé ayé ni a ó sọ di ahoro pátápátá

a ó sì jẹ gbogbo rẹ̀ run.

Olúwa ni ó ti sọ ọ̀rọ̀ yìí.

4Ilẹ̀ ayé ti gbẹ ó sì sá,

ayé ń ṣòjòjò, àárẹ̀ mú un,

àwọn ẹni gíga ilẹ̀ ayé wà nínú ìpọ́njú

5àwọn ènìyàn ayé ti bà á jẹ́;

wọ́n ti pa àwọn òfin run

wọ́n ṣe lòdì sí àwọn ìlànà

wọ́n sì ti ba májẹ̀mú ayérayé jẹ́.

6Nítorí náà, ègún kan ti jẹ ayé run;

àwọn ènìyàn rẹ̀ ní láti ru ẹ̀bi wọn.

Nítorí náà, àwọn olùgbé ayé ti gbiná dànù,

àwọn ẹ̀tàhóró ló sì kù.

7Wáìnì tuntun ti gbẹ, àjàrà sì ti rọ,

gbogbo àwọn aláríyá sì kérora.

824.8: If 18.22.Àríyá ti ṣaworo ti dákẹ́

ariwo àwọn tí ń ṣàjọyọ̀ ti dáwọ́ dúró

ayọ̀ dùùrù ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.

9Kò ṣe é ṣe fún wọn láti máa mu wáìnì pẹ̀lú orin kíkọ mọ́

ọtí líle ti di ìkorò fún àwọn ọ̀mu.

10Ìlú tí a run ti dahoro,

ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé kọ̀ọ̀kan ni a dí pa.

11Ní òpópónà ni wọ́n ti ń kígbe fún wáìnì

gbogbo ayọ̀ ọ wọn ti di ìbànújẹ́,

gbogbo àríyá ni a lé kúrò lórí ilẹ̀ ayé.

12Ìlú ni a ti fi sílẹ̀ ní ahoro,

ìlẹ̀kùn rẹ̀ ni a sì tì pa bámú bámú.

13Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí ní orí ilẹ̀ ayé

àti láàrín àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú,

gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a lu igi olifi,

tàbí gẹ́gẹ́ bí i pàǹtí tí ó ṣẹ́kù lẹ́yìn

tí a kórè èso tán.

14Wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì hó fún ayọ̀;

láti ìwọ̀-oòrùn ni wọn yóò ti polongo

ọláńlá Olúwa.

15Nítorí náà ní ìlà-oòrùn ẹ fi ògo fún Olúwa;

gbé orúkọ Olúwa ga, àní

Ọlọ́run Israẹli,

ní àwọn erékùṣù ti inú Òkun,

16Láti òpin ayé wá ni a ti gbọ́ orin;

“Ògo ni fún olódodo n nì.”

Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Mo ṣègbé, mo ṣègbé!

“Ègbé ni fún mi!

Alárékérekè dalẹ̀!

Pẹ̀lú ìhàlẹ̀ ni àgàbàgebè fi dalẹ̀!”

17Ìpayà, isà òkú, àti ìdẹ̀kùn ń dúró dè ọ́,

ìwọ ènìyàn ilẹ̀ ayé.

18Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá nítorí ariwo ìpayà

yóò ṣubú sínú ihò,

ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yọ́ jáde nínú ihò

ni ìdẹ̀kùn yóò gbámú.

Ibodè ọ̀run ti wà ní ṣíṣí sílẹ̀

Ìpìlẹ̀ ayé mì tìtì.

19Ilẹ̀ ayé ti fọ́

ilẹ̀ ayé ti fọ́ dànù,

a ti mi ilẹ̀ ayé rìrìrìrì.

20Ilẹ̀ ayé yí gbiri bí ọ̀mùtí,

ó bì síwá sẹ́yìn bí ahéré nínú afẹ́fẹ́;

Ẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ rẹ̀ ń pa á lẹ́rù

tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣubú láìní lè dìde mọ́.

21Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò jẹ ẹ́ ní yà

gbogbo agbára tí ó wà lókè lọ́run

àti àwọn ọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé.

22A ó sì kó wọn jọ pọ̀,

gẹ́gẹ́ bí ará túbú jọ sínú ihò,

a ó tì wọ́n mọ́ inú túbú,

a ó sì bẹ̀ wọ́n wò lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.

23A ó rẹ òṣùpá sílẹ̀, ojú yóò sì ti oòrùn;

nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jẹ ọba

ní orí òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu,

àti níwájú àwọn àgbàgbà rẹ ní ògo.