አሞጽ 9 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

አሞጽ 9:1-15

እስራኤል ትጠፋለች

1ጌታን በመሠዊያው አጠገብ ቆሞ አየሁት፤ እርሱም እንዲህ አለ፤

“መድረኮቹ እንዲናወጡ፣

ጕልላቶቹን ምታ፤

በሕዝቡም ሁሉ ራስ ላይ ሰባብራቸው፤

የቀሩትን በሰይፍ እገድላቸዋለሁ፤

ከእነርሱ አንድም ሰው አይሸሽም፤

ቢሸሽም የሚያመልጥ የለም።

2መቃብር9፥2 ዕብራይስጡ ሲዖል ይለዋል። በጥልቀት ቈፍረው ቢወርዱም፣

እጄ ከዚያ ታወጣቸዋለች፤

ወደ ሰማይ ቢወጡም፣

ከዚያ አወርዳቸዋለሁ።

3በቀርሜሎስ ጫፍ ላይ ቢሸሸጉም፣

ዐድኜ፣ ፈልጌ ከዚያ አወርዳቸዋለሁ፤

እይዛቸዋለሁም።

በጥልቅ ባሕር ውስጥ ከእኔ ቢሸሸጉም፣

በዚያ እባቡ እንዲነድፋቸው አዝዘዋለሁ፤

4በጠላቶቻቸው ተነድተው ለምርኮ ቢወሰዱም፣

በዚያ እንዲገድላቸው ሰይፍን አዝዛለሁ፤

“ለመልካም ሳይሆን ለክፉ፣

ዐይኔን በእነርሱ ላይ አደርጋለሁ።”

5ጌታ፣ እግዚአብሔር ጸባኦት፣

ምድርን ይዳስሳል፤

እርሷም ትቀልጣለች፤

በውስጧ የሚኖሩ ሁሉ ያለቅሳሉ፤

የምድር ሁለመና እንደ አባይ ወንዝ ይነሣል፤

እንደ ግብፅ ወንዝም ይወርዳል።

6መኖሪያውን9፥6 ዕብራይስጡ ለዚህ ሐረግ የሰጠው ትርጕም ምን እንደ ሆነ አይታወቅም። በሰማይ የሚሠራ፣

መሠረቱንም9፥6 ዕብራይስጡ ለዚህ ሐረግ የሰጠው ትርጕም ምን እንደ ሆነ አይታወቅም። በምድር የሚያደርግ፣

የባሕርን ውሃ የሚጠራ፣

በምድርም ገጽ ላይ የሚያፈስስ፣

እርሱ ስሙ እግዚአብሔር ነው።

7“እናንት እስራኤላውያን፣

ለእኔ እንደ ኢትዮጵያውያን አይደላችሁምን?”

ይላል እግዚአብሔር

“እስራኤልን ከግብፅ፣

ፍልስጥኤማውያንን ከከፍቶር9፥7 በላይኛው አባይ አካባቢ ያለ ሕዝብ ነው።

ሶርያውያንንም ከቂር አላወጣሁምን?

8“እነሆ፤ የጌታ እግዚአብሔር ዐይኖች፣

በኀጢአተኛ መንግሥት ላይ ናቸው፤

ከምድር ገጽ፣ ፈጽሜ አጠፋዋለሁ፤

የያዕቆብን ቤት ግን፣ ሙሉ በሙሉ

አልደመስስም፤”

ይላል እግዚአብሔር

9“እነሆ፤ ትእዛዝ እሰጣለሁ፤

እህል በወንፊት እንደሚነፋ፣

የእስራኤልን ቤት፣

በሕዝብ ሁሉ መካከል እንዲሁ አደርጋለሁ፤

ነገር ግን አንዲት ቅንጣት በምድር ላይ አትወድቅም።

10በሕዝቤ መካከል ያሉ፣

‘ክፉ ነገር አያገኘንም ወይም አይደርስብንም’ የሚሉ፣

ኀጢአተኞች ሁሉ፣

በሰይፍ ይሞታሉ።

የእስራኤል መመለስ

11“በዚያ ቀን፣

“የወደቀውን የዳዊትን ድንኳን አነሣለሁ፤

የተሰበረውን እጠግናለሁ፤

የፈረሰውን ዐድሳለሁ፤

ቀድሞ እንደ ነበረም አድርጌ እሠራዋለሁ፤

12ስለዚህ የኤዶምን ትሩፍ፣

በስሜ9፥12 ዕብራይስጡ እንደ ሰብዓ ሊቃናቱ ትርጕም የሕዝቡ ትሩፋንና ስሜን የሚሸከሙ ሁሉ፣ እኔን ይፈልጋሉ የተጠሩትንም ሕዝቦች ሁሉ ይወርሳሉ፤”

ይላል ይህን የሚያደርግ እግዚአብሔር

13እግዚአብሔር እንዲህ ይላል፤

“እነሆ፤ ዐጫጁ ዐጭዶ ሳይጨርስ፣

ዐራሹ በላዩ የሚደርስበት፣

ችግኝ ተካዩም ገና ተክሎ ሳይጨርስ፣

ወይን ጨማቂው የሚደርስበት ጊዜ ይመጣል፤

አዲስ የወይን ጠጅ ከተራሮች ይንጠባጠባል፤

ከኰረብቶችም ሁሉ ይፈስሳል።

14የተሰደደውን9፥14 ወይም ዕጣ ፈንታቸውን አድሳለሁ ሕዝቤን እስራኤልን እመልሳለሁ።

“እነርሱም የፈራረሱትን ከተሞች መልሰው ሠርተው በውስጣቸው ይኖራሉ።

የወይን ተክል ተክለው፣ ጠጁን ይጠጣሉ፤

አትክልት ተክለው ፍሬውን ይበላሉ።

15እስራኤልን በገዛ ምድራቸው እተክላቸዋለሁ፤

ከሰጠኋቸውም ምድር፣

ዳግመኛ አይነቀሉም፤”

ይላል አምላክህ እግዚአብሔር

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 9:1-15

A o pa Israẹli run

1Mo rí Olúwa, ó dúró ní ẹ̀bá pẹpẹ, ó sì wí pé:

“Lu orí àwọn àtẹ́rígbà ìlẹ̀kùn

kí àwọn òpó kí ó lè mì

fọ́ wọn sí orí àwọn gbogbo ènìyàn

àwọn tí ó ṣẹ́kù ni èmi yóò fi idà pa,

Ẹni tí ó sálọ nínú wọn kí yóò sá gbé

Ẹni ti ó sá àsálà nínú wọn kí yóò gbàlà.

2Bí wọ́n tilẹ̀ wa ilẹ̀ lọ sí ipò òkú

Láti ibẹ̀ ni ọwọ́ mi yóò ti tẹ̀ wọ́n

Bí wọ́n tilẹ̀ gun òkè ọ̀run lọ,

láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú wọn sọ̀kalẹ̀.

3Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Karmeli,

èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀.

Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìsàlẹ̀ Òkun,

láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.

4Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọn

láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa.

“Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí,

kì í sì í ṣe fún rere.”

5Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,

ẹni ti ó fi ọwọ́ kan ilẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì ṣọ̀fọ̀;

gbogbo orílẹ̀-èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Naili

tiwọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Ejibiti.

6Òun ni ẹni tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run

ti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayé

Ẹni ti ó pe àwọn omi Òkun

ti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé

Olúwa ni orúkọ rẹ̀.

7“Àbá ẹ̀yin ọmọ Israẹli

kò ha dàbí àwọn ọmọ Kuṣi sí mi?”

ni Olúwa wí.

“Èmi kò ha ti mú Israẹli gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá

àti àwọn Filistini láti ilẹ̀ Kafitori

àti àwọn ará Aramu láti Kiri?

8“Dájúdájú, ojú Olúwa Olódùmarè

ń bẹ̀ lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀.

Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀

Síbẹ̀ Èmi kò nípa ilé Jakọbu run pátápátá,”

ni Olúwa wí.

9“Nítorí Èmi yóò pàṣẹ,

Èmi yóò sì mi ilé Israẹli

ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè

bí a ti ń jọ nǹkan nínú ajọ̀

tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.

10Gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn mi

ni yóò ti ipa idà kú

gbogbo àwọn ti ń wí pé,

‘Aburú kì yóò lé wa bá, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́.’

Ìmúpadàbọ̀ Israẹli

119.11-12: Ap 15.16-17.“Ní ọjọ́ náà ní

Èmi yóò gbé àgọ́ Dafidi tí ó wó ró,

Èmi yóò dí odi rẹ̀ tí ó ya,

Èmi yóò sì gbé ahoro rẹ̀ sókè,

Èmi yóò sì kọ bí ti ọjọ́ ìgbàanì,

12kí wọn le jogún ìyókù Edomu

àti gbogbo àwọn kèfèrí, ti a ń pè nípa orúkọ mi,”

ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.

139.13: Jl 3.18.“Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí,

“tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè bá

Tí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn bá

Àwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀

Tí yóò sì sàn láti ara àwọn òkè kéékèèkéé.

14Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Israẹli ènìyàn mi padà bọ̀.

“Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọn

Wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọn

wọn yóò sì ṣe ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn

15Èmi yóò gbin Israẹli sí orí ilẹ̀ rẹ̀.

A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláé

kúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,”

ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.