አሞጽ 8 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

አሞጽ 8:1-14

የጐመራ ፍሬ የሞላበት ቅርጫት

1ጌታ እግዚአብሔር ይህን አሳየኝ፤ እነሆ፤ የጐመራ ፍሬ የሞላበት ቅርጫት ነበረ። 2እርሱም፣ “አሞጽ ሆይ፤ ምን ታያለህ?” አለኝ። እኔም፣ “የጐመራ ፍሬ የሞላበት ቅርጫት አያለሁ” አልሁ። ከዚያም በኋላ እግዚአብሔር እንዲህ አለኝ፤ “በሕዝቤ በእስራኤል ላይ ፍጻሜ መጥቷል፤ ከእንግዲህም አልምራቸውም።”

3ጌታ እግዚአብሔር፣ “በዚያ ቀን የቤተ መቅደሱ ዝማሬ ወደ ዋይታ8፥3 የቤተ መቅደሱ ዘማርያን ዋይታ ያሰማሉ የሚሉ አሉ። ይለወጣል፤ እጅግ ብዙ የሆነ የሰው ሬሳ ወድቆ ይገኛል፤ ዝምታም ይሰፍናል” ይላል።

4እናንት ችግረኞችን የምትረግጡ፣

የምድሪቱንም ድኾች የምታጠፉ ይህን ስሙ፤

5እንዲህም ትላላችሁ፤

“መስፈሪያውን በማሳነስ፣

ዋጋውን ከፍ በማድረግ፣

በሐሰተኛ ሚዛን በማጭበርበር፣

እህል እንድንሸጥ፣

የወር መባቻ መቼ ያበቃል?

ስንዴም ለገበያ እንድናቀርብ፣

ሰንበት መቼ ያልፋል?”

6ድኻውን በብር፣

ችግረኛውንም በጥንድ ጫማ እንገዛለን፤

ግርዱን እንኳ በስንዴ ዋጋ እንሸጣለን።

7እግዚአብሔር በያዕቆብ ክብር እንዲህ ሲል ምሏል፤ “እነርሱ ያደረጉትን ሁሉ ከቶ አልረሳም።

8“በዚህ ነገር ምድር አትናወጥምን?

በውስጧ የሚኖሩትስ ሁሉ አያለቅሱምን?

የምድር ሁለመና እንደ አባይ ወንዝ ይነሣል፤

እንደ ግብፅ ወንዝም ወደ ላይ ይፈናጠራል፤

ተመልሶም ይወርዳል።”

9ጌታ እግዚአብሔር እንዲህ ይላል፤

“በዚያ ቀን፣ ፀሓይ በቀትር እንድትጠልቅ አደርጋለሁ፤

ምድርንም ደማቅ ብርሃን ሳለ በቀን አጨልማታለሁ።

10ዓመት በዓላችሁን ወደ ልቅሶ፣

ዝማሬአችሁንም ሁሉ ወደ ዋይታ እለውጣለሁ፤

ሁላችሁም ማቅ እንድትለብሱ፣

ጠጕራችሁንም እንድትላጩ አደርጋለሁ፤

ያን ጊዜ ለአንድያ ልጅ ሞት እንደሚለቀስበት፣

ፍጻሜውንም እንደ መራራ ቀን አደርገዋለሁ።”

11ጌታ እግዚአብሔር እንዲህ ይላል፤

“በምድር ላይ ራብን የምሰድድበት ዘመን ይመጣል፤

ይኸውም የእግዚአብሔርን ቃል የመስማት ራብ እንጂ፣

እንጀራን የመራብ ወይም ውሃን የመጠማት አይደለም።

12ሰዎች እግዚአብሔርን ለመሻት፣

ከባሕር ወደ ባሕር፣

ከሰሜን ወደ ምሥራቅ ይንከራተታሉ፤

ነገር ግን አያገኙትም።

13“በዚያ ቀን፣

“ቈነጃጅት ሴቶችና ብርቱዎች ጕልማሶች፣

ከውሃ ጥም የተነሣ ይዝላሉ።

14በሰማርያ ኀፍረት8፥14 ወይም በአሼማ ወይም በጣኦት አማልክት የሚምሉ፣

ወይም፣ ‘ዳን ሆይ፤ ሕያው አምላክህን’ የሚሉ፣

ወይም ‘ሕያው የቤርሳቤህ አምላክን8፥14 ወይም መንገዱን’ ብለው የሚምሉ፣

ዳግመኛ ላይነሡ፣ ለዘላለም ይወድቃሉ።”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 8:1-14

Agbọ̀n èso pípọ́n

1Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n. 2Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.”

Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.”

Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”

3Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”

4Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba,

tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.

5Tí ẹ ń wí pé,

“Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí

kí àwa bá à lè ta ọkà

kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin

kí àwa bá à le ta jéró?”

Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù

kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á

kí a sì fi òṣùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ

6Kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà

kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní

kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.

7Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé: “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.

8“Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí?

Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀?

Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili,

yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi

a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.

9“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí,

“Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán,

Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.

10Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀,

gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún.

Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀,

kí a sì fá orí yín.

Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin

kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.

11“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí,

“nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà,

kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi.

Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.

12Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun

wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá,

wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa

ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.

13“Ní ọjọ́ náà

“àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin

yóò dákú fún òǹgbẹ omi.

14Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra,

tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’

Bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba

Wọ́n yóò ṣubú,

Wọn kì yóò si tún dìde mọ.”