አሞጽ 6 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

አሞጽ 6:1-14

ተዘልላ ላለችው እስራኤል የተሰጠ ማስጠንቀቂያ

1በጽዮን ተዘልላችሁ የምትቀመጡ፣

በሰማርያ ተራራ ያለ ሥጋት የምትኖሩ፣

የእስራኤልም ሕዝብ ለርዳታ ወደ እናንተ የሚመጡባችሁ፣

እናንት የአሕዛብ አለቆች ሆይ፤ ወዮላችሁ!

2ወደ ካልኔ ሂዱ፤ እርሱንም ተመልከቱ፤

ከዚያም ወደ ታላቂቱ ሐማት ሂዱ፤

ወደ ፍልስጥኤም ከተማ ወደ ጌትም ውረዱ፤

እነዚህ ከሁለቱ መንግሥታታችሁ ይሻላሉን?

የምድራቸውስ ስፋት ከእናንተ ይበልጣልን?

3ክፉውን ቀን ለምታርቁ፣

የግፍንም ወንበር ለምታቀርቡ ወዮላችሁ!

4በዝኆን ጥርስ ባጌጠ ዐልጋ ላይ ለምትተኙ፤

በድንክ ዐልጋችሁ ላይ ለምትዝናኑ፣

ከበጎች መንጋ ጠቦትን፣

ከጋጣም ጥጃን ለምትበሉ፤

5ባልተቃኘ በገና ለምትዘፍኑ፣

በሙዚቃ መሣሪያ ለመጫወት ለምትሹ፣

6በፋጋ የወይን ጠጅ ለምትጠጡ፣

ምርጥ ሽቱም ለምትቀቡ፣

ስለ ዮሴፍ መከራ ግን ለማታዝኑ ወዮላችሁ!

7ስለዚህ እናንተ በመጀመሪያ በምርኮ ከሚወሰዱት መካከል ናችሁ፤

መፈንጠዛችሁና መዝናናታችሁም ያበቃል።

እግዚአብሔር የእስራኤልን ትዕቢት ይጸየፋል

8ጌታ እግዚአብሔር

“የያዕቆብን ትዕቢት ተጸይፌአለሁ፤

ምሽጎቹንም ጠልቻለሁ፤

ከተማዪቱንና በውስጧ ያለውን ሁሉ፣

አሳልፌ እሰጣለሁ”

ሲል በራሱ ምሏል፤ ይላል የሰራዊት አምላክ እግዚአብሔር

9በአንድ ቤት ውስጥ ዐሥር ሰዎች ቢቀሩ እነርሱም ይሞታሉ። 10በድኖቹንም ከቤት አውጥቶ ማቃጠል ያለበት አንድ ዘመድ መጥቶ ተደብቆ ያለውን ሰው፣ “ከአንተ ጋር የቀረ ሌላ ሰው አለን?” ሲለው፣ እርሱም “የለም” ይለዋል፤ ከዚያም በኋላ፣ “ዝም በል፤ የእግዚአብሔርን ስም መጥራት አይገባንም” ይለዋል።

11እነሆ፤ እግዚአብሔር ትእዛዝ ሰጥቷልና፤

ታላላቅ ቤቶችን ያወድማቸዋል፤

ትንንሾቹንም ያደቅቃቸዋል።

12ፈረሶች በጭንጫ ላይ ይሮጣሉን?

ሰውስ እዚያ ላይ በበሬ ያርሳልን?

እናንተ ግን ፍትሕን ወደ መርዝነት፣

የጽድቅንም ፍሬ ወደ መራራነት ለወጣችሁ።

13እናንተ ሎዶባርን6፥13 ትርጕሙ ምንም ማለት ነው። በማሸነፋችሁ ደስ ያላችሁ፣

“ቃርናይምን6፥13 ቃርናይም ትርጕሙ ቀንዶች ማለት ነው፤ ቀንድ የጥንካሬ ምልክት ነው። በራሳችን ብርታት ይዘናል” የምትሉ።

14ሁሉን የሚገዛ አምላክ እግዚአብሔር እንዲህ ይላልና፣

“የእስራኤል ሕዝብ ሆይ፤ እነሆ፤ እኔ ከሐማት መግቢያ6፥14 ወይም ከመግቢያው ጀምሮ እስከ ዓረባ ሸለቆ ድረስ፣

የሚያስጨንቃችሁን ሕዝብ፣ በእናንተ

ላይ አስነሣለሁ።”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 6:1-14

Ègbé ni fún àwọn tí ara rọ̀

1Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Sioni

àti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaria

àti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdè

tí ẹ̀yin ènìyàn Israẹli máa ń tọ̀ ọ́ wá

2Ẹ lọ Kalne kí ẹ lọ wò ó

kí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Hamati ìlú ńlá a nì.

Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gati ní ilẹ̀ Filistini

Ǹjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ?

Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju tiyín lọ bí?

3Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú,

ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòsí

4Ẹ̀yin sùn lé ibùsùn tí a fi eyín erin ṣe

ẹ sì tẹ́ ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùn

ẹyin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yín jẹ

ẹ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrín agbo wọn jẹ

5Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i Dafidi

ẹ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ àwọn ohun èlò orin

6Ẹ̀yin mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kan

àti ìkunra tí o dára jùlọ

ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò káàánú ilé Josẹfu tí ó di ahoro

7Nítorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùn

pẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùn

àsè àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò.

Olúwa Kórìíra Ìgbéraga Ọmọ Israẹli

8Olúwa Olódùmarè ti búra fúnrarẹ̀, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì ti wí pé:

“Mo kórìíra ìgbéraga Jakọbu

n kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀

Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́

àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”

9Bí Ọkùnrin mẹ́wàá bá ṣẹ́kù nínú ilé kan, àwọn náà yóò kú 10Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béèrè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó fi ara pamọ́ níbẹ̀, “Ǹjẹ́ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”

11Nítorí Olúwa tí pa àṣẹ náà,

Òun yóò sì wó ilé ńlá náà lulẹ̀ túútúú

Àti àwọn ilé kéékèèkéé sí wẹ́wẹ́.

12Ǹjẹ́ ẹṣin a máa sáré lórí àpáta bí?

Ǹjẹ́ ènìyàn a máa fi akọ màlúù kọ ilẹ̀ níbẹ̀?

Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yí òtítọ́ padà sí májèlé

ẹ sì ti sọ èso òdodo di ìkorò.

13Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí Lo-Debari

Ẹ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í ṣe agbára wa ni àwa fi gba Karnaimu?”

14Nítorí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí pé,

“Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Israẹli,

wọn yóò pọ́n yín lójú ní gbogbo ọ̀nà,

láti Lebo-Hamati, títí dé pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah.”