ምሳሌ 28 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ምሳሌ 28:1-28

1ክፉ ሰው ማንም ሳያሳድደው ይሸሻል፤

ጻድቅ ግን እንደ አንበሳ ልበ ሙሉ ነው።

2አገር ስታምፅ፣ ገዦቿ ይበዛሉ፤

አስተዋይና ዐዋቂ ሰው ግን ሥርዐትን ያሰፍናል።

3ድኾችን የሚያስጨንቅ ሰው፣28፥3 ወይም ድኻ

ሰብል እንደሚያጠፋ ኀይለኛ ዝናብ ነው።

4ሕግን የሚተዉ ክፉዎችን ያወድሳሉ፤

ሕግን የሚጠብቁ ግን ይቋቋሟቸዋል።

5ክፉዎች ፍትሕን አያስተውሉም፤

እግዚአብሔርን የሚሹ ግን ሙሉ በሙሉ ያውቁታል።

6በአካሄዱ ነውር የሌለበት ድኻ፣

መንገዱ ጠማማ ከሆነ ባለጠጋ ይሻላል።

7ሕግን የሚጠብቅ አስተዋይ ልጅ ነው፤

ከሆዳሞች ጋር ጓደኛ የሚሆን ግን አባቱን ያዋርዳል።

8በከፍተኛ ወለድ ሀብቱን የሚያካብት፣

ለድኻ ለሚራራ፣ ለሌላው ሰው ያከማችለታል።

9ሕግን ላለመስማት ጆሮውን የሚደፍን፣

ጸሎቱ እንኳ አስጸያፊ ነው።

10ቅኖችን በክፉ መንገድ የሚመራ፣

በቈፈረው ጕድጓድ ይገባል፤

ንጹሓን ግን መልካም ነገርን ይወርሳሉ።

11ባለጠጋ ራሱን ጠቢብ አድርጎ ይቈጥር ይሆናል፤

አስተዋይ የሆነ ድኻ ግን መርምሮ ያውቀዋል።

12ጻድቃን ድል ሲነሡ ታላቅ ደስታ ይሆናል፤

ክፉዎች ሥልጣን ሲይዙ ግን ሕዝብ ይሸሸጋል።

13ኀጢአቱን የሚሰውር አይለማም፤

የሚናዘዝና የሚተወው ግን ምሕረትን ያገኛል።

14እግዚአብሔርን ዘወትር የሚፈራ ሰው ቡሩክ ነው፤

ልቡን የሚያደነድን ግን መከራ ላይ ይወድቃል።

15ታዳጊ በሌለው ሕዝብ ላይ የተሾመ ጨካኝ ገዥ፣

እንደሚያገሣ አንበሳ ወይም ተንደርድሮ እንደሚይዝ ድብ ነው።

16ጨካኝ ገዥ ማመዛዘን ይጐድለዋል፤

አለአግባብ የሚገኝን ጥቅም የሚጸየፍ ግን ዕድሜው ይረዝማል።

17የሰው ደም ያለበት ሰው፣

ዕድሜ ልኩን ሲቅበዘበዝ ይኖራል፤

ማንም ሰው አይርዳው።

18አካሄዱ ነቀፋ የሌለበት ሰው ክፉ አያገኘውም፤

መንገዱ ጠማማ የሆነ ግን ድንገት ይወድቃል።

19መሬቱን የሚያርስ የተትረፈረፈ ምግብ ያገኛል፤

ከንቱ ተስፋን ይዞ የሚጓዝ ግን ድኽነትን ይወርሳል።

20ታማኝ ሰው እጅግ ይባረካል፤

ሀብት ለማግኘት የሚጣደፍ ግን ከቅጣት አያመልጥም።

21አድልዎ ማድረግ መልካም አይደለም፤

ሰው ግን ለቍራሽ እንጀራ ሲል በደል ይፈጽማል።

22ስስታም ሀብት ለማከማቸት ይስገበገባል፤

ድኽነት እንደሚጠብቀውም አያውቅም።

23ሸንጋይ አንደበት ካለው ይልቅ፣

ሰውን የሚገሥጽ ውሎ ዐድሮ ይወደዳል።

24ከአባት ከእናቱ ሰርቆ፣

“ይህ ጥፋት አይደለም” የሚል የአጥፊ ተባባሪ ነው።

25ሥሥታም ሰው ጠብን ያነሣሣል፤

በእግዚአብሔር የሚታመን ግን ይባረካል።

26በራሱ የሚታመን ተላላ ነው፤

በጥበብ የሚመላለስ ግን ክፉ አያገኘውም።

27ለድኾች የሚሰጥ አይቸገርም፤

አይቷቸው እንዳላየ የሚሆን ግን ብዙ ርግማን ይደርስበታል።

28ክፉዎች ሥልጣን በሚይዙ ጊዜ ሕዝብ ይሸሸጋል፤

ክፉዎች በሚጠፉበት ጊዜ ግን ጻድቃን ይበዛሉ።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 28:1-28

1Ènìyàn búburú ń sá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹnìkan kò lé e

ṣùgbọ́n olódodo láyà bí i kìnnìún.

2Nígbà tí orílẹ̀-èdè bá ní orí kunkun, àwọn ọba rẹ̀ a máa pọ̀,

ṣùgbọ́n olóye àti onímọ̀ a máa pa òfin mọ́.

3Ọba tí ó ni àwọn tálákà lára

dàbí àgbàrá òjò tí ó ń gbá gbogbo ọ̀gbìn lọ.

4Àwọn tí ó kọ òfin sílẹ̀ a máa gbóríyìn fún ènìyàn búburú

ṣùgbọ́n àwọn tí ó pa òfin mọ́ kọjú ìjà sí ènìyàn búburú.

5Òye ìdájọ́ òdodo kò yé àwọn ẹni ibi

ṣùgbọ́n ó yé àwọn tí ń wá Olúwa dáradára.

6Ó sàn láti jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ jẹ́ aláìlábùkù

ju ọlọ́rọ̀ tí ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla.

7Ẹni tí ó pa òfin mọ́ jẹ́ olóye ọmọ

ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ẹ́ jẹgúdújẹrá kẹ́gbẹ́ dójútì baba rẹ̀.

8Ẹni tí ó mú ọrọ̀ rẹ̀ di púpọ̀ nípa èrè àjẹjù

ń kó jọ fún ẹlòmíràn, tí yóò ní àánú àwọn tálákà.

9Bí ẹnikẹ́ni bá kọ etí ikún sí òfin,

kódà àdúrà rẹ̀ jẹ́ ìríra.

10Ẹni tí ó mú olódodo rìn ọ̀nà búburú

yóò bọ́ sínú pàkúté ara rẹ̀

ṣùgbọ́n aláìlẹ́gàn yóò gba ogún rere.

11Ọlọ́rọ̀ ènìyàn le è gbọ́n lójú ara rẹ̀

ṣùgbọ́n tálákà tí ó ní òye rí ìdí, rẹ̀.

12Nígbà tí olódodo ń lékè ariwo ayọ̀ ta;

ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú gorí òye, àwọn ènìyàn a na pápá bora.

13Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kì yóò ṣe rere,

ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jẹ́wọ́ tí ó sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀ máa ń rí àánú gbà.

14Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run nígbà gbogbo

ṣùgbọ́n ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le bọ́ sínú wàhálà.

15Bí kìnnìún tí ń ké tàbí Beari tí ń halẹ̀

ni ènìyàn búburú tí ń jẹ ọba lórí àwọn aláìlágbára.

16Ọmọ-aládé tí ó ṣe aláìmòye púpọ̀ ní ń ṣe ìwà ìkà púpọ̀ pẹ̀lú,

ṣùgbọ́n èyí tí ó kórìíra ojúkòkòrò yóò mún ọjọ́ rẹ̀ pẹ́.

17Ẹni tí ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ìpànìyàn

yóò máa joró rẹ̀ títí ikú

má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ràn án lọ́wọ́.

18Ẹni tí ń rìn déédéé ní yóò là,

ṣùgbọ́n ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà ni yóò ṣubú lójijì.

19Ẹni tí ó bá ro ilẹ̀ rẹ̀ yóò ní oúnjẹ lọ́pọ̀lọpọ̀

ṣùgbọ́n ẹni tí ń lé ohun asán yóò kún fún òsì.

20Olóòtítọ́ ènìyàn yóò rí ìbùkún gbà gan an

ṣùgbọ́n ẹni tí ojú ń kán láti di ọlọ́rọ̀ kì yóò lọ láìjìyà.

21Ojúsàájú ṣíṣe kò dára,

síbẹ̀ ènìyàn kan ń ṣẹ̀ nítorí òkèlè oúnjẹ kan.

22Ahun ń sáré àti là

kò sì funra pé òsì dúró de òun.

23Ẹni tí ó bá ènìyàn kan wí yóò rí ojúrere ni nígbẹ̀yìn

ju ẹni tí ó ní ètè ẹ̀tàn lọ.

24Ẹni tí ó ja baba tàbí ìyá rẹ̀ lólè

tí ó sì wí pé “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀”

irú kan ni òun àti ẹni tí ń pa ni run.

25Ọ̀kánjúwà ènìyàn a máa dá ìjà sílẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò gbilẹ̀.

26Ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀ jẹ́ aláìgbọ́n

ṣùgbọ́n ẹni tí ń rìn nínú ọgbọ́n wà láìléwu.

27Ẹni tí ó ń fi fún tálákà kì yóò ṣe aláìní ohunkóhun,

ṣùgbọ́n ẹni tí ó di ojú rẹ̀ sí wọn gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ègún.

28Nígbà tí ènìyàn búburú bá dórí ìjọba, àwọn ènìyàn a na pápá bora;

ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú bá ṣègbé,

àwọn olódodo ń gbilẹ̀ sí i.