ምሳሌ 27 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ምሳሌ 27:1-27

1ነገ በሚሆነው አትመካ፤

ቀን የሚያመጣውን አታውቅምና።

2ሌላው ያመስግንህ እንጂ የገዛ አፍህ አይደለም፤

ሌላ ሰው ያወድስህ እንጂ የገዛ ከንፈርህ አይሁን።

3ድንጋይ ይከብዳል፤ አሸዋም ሸክም ነው፤

የተላላ ሰው ጕነጣ ግን ከሁለቱም ይከብዳል።

4ንዴት ጨካኝ፣ ቍጣም ጐርፍ ነው፤

በቅናት ፊት ግን ማን መቆም ይችላል?

5የተገለጠ ዘለፋ፣

ከተደበቀ ፍቅር ይሻላል።

6ከጠላት ደጋግሞ መሳም ይልቅ፣

የወዳጅ ማቍሰል ይታመናል።

7ለጠገበ ማር አይጥመውም፤

ለተራበ ግን እሬት እንኳ ይጣፍጠዋል።

8ከቤቱ ወጥቶ የሚባዝን ሰው፣

ጎጆዋን ለቅቃ እንደምትባዝን ወፍ ነው።

9ሽቱና ዕጣን ልብን ደስ ያሰኛሉ፤

የወዳጅ ማስደሰትም ከቅን ምክሩ ይመነጫል።

10የራስህንም ሆነ የአባትህን ወዳጅ አትተው፤

መከራ በሚያጋጥምህ ጊዜ ወደ ወንድምህ ቤት አትሂድ፤

ሩቅ ካለ ወንድም ቅርብ ያለ ጎረቤት ይሻላል።

11ልጄ ሆይ፤ ጠቢብ ሁን፤ ልቤን ደስ አሰኘው፤

ለሚንቁኝ ሁሉ መልስ መስጠት እችል ዘንድ።

12ጥንቁቅ አደጋን አይቶ ይሸሸጋል፤

ማስተዋል የጐደለው ግን ወደዚያው ይሄዳል፤ ይጐዳልም።

13ለማይታወቅ ሰው የተዋሰን ልብሱን ግፈፈው፤

ለዘልዛላ ሴት ከተዋሰማ ዐግተው።

14ሰው ድምፁን ከፍ አድርጎ ባልንጀራውን በማለዳ ቢመርቅ፣

እንደ ርግማን ይቈጠራል።

15ጨቅጫቃ ሚስት፣

በዝናብ ቀን እንደሚወርድ የማያቋርጥ ጠፈጠፍ ናት፤

16እርሷን ለመግታት መሞከር፣ ነፋስን እንደ መግታት ወይም ዘይትን

በእጅ እንደ መጨበጥ ነው።

17ብረት ብረትን እንደሚስል፣

ሰውም ሌላውን ሰው እንደዚሁ ይስለዋል።

18በለስን የሚንከባከብ ፍሬዋን ይበላል፤

ጌታውን የሚያገለግልም ክብርን ይጐናጸፋል።

19ውሃ ፊትን እንደሚያሳይ፣

የሰውም ልብ ማንነቱን ገልጦ ያሳያል።

20ሲኦልና የሙታን ዓለም27፥20 ወይም ሞትና ጥፋት እንደማይጠግቡ ሁሉ፣

የሰውም ዐይን አይረካም።

21ብር በማቅለጫ፣ ወርቅ በከውር እንደሚፈተን፣

ሰውም በሚቀበለው ምስጋና ይፈተናል።

22ጅልን በሙቀጫ ብትወቅጠው፣

እንደ እህልም በዘነዘና ብታደቅቀው፣

ጅልነቱን ልታስወግድለት አትችልም።

23በጎችህ በምን ሁኔታ እንዳሉ ደኅና አድርገህ ዕወቅ፤

መንጋህንም ተንከባከብ፤

24ሀብት ለዘላለም አይኖርምና፤

ዘውድም ከትውልድ ወደ ትውልድ ጸንቶ አይኖርም።

25ደረቁ ሣር ተወግዶ፣ አዲሱ ብቅ ሲል፣

በየኰረብታው ላይ ያለው ሣር ተሰብስቦ ሲገባ፣

26ከበግ ጠቦቶች ልብስ ታገኛለህ፤

ፍየሎችም የዕርሻ መሬት መግዣ ይሆኑሃል።

27አንተንና ቤተ ሰብህን፣

ገረዶችህንም ጭምር ለመመገብ፣

የተትረፈረፈ የፍየል ወተት ይኖርሃል።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 27:1-27

1Má ṣe yangàn nítorí ọ̀la

nítorí o kò mọ ohun tí ọjọ́ kan le è mú wáyé.

2Jẹ́ kí ẹlòmíràn yìn ọ́ dípò ẹnu ara rẹ

àní àlejò, kí ó má sì ṣe ètè ìwọ fúnrarẹ̀.

3Òkúta wúwo, erùpẹ̀ sì wúwo

ṣùgbọ́n ìbínú aṣiwèrè wúwo ju méjèèjì lọ.

4Ìbínú ni ìkà, ìrunú sì burú púpọ̀

ṣùgbọ́n ta ni ó le è dúró níwájú owú?

5Ìbániwí gbangba sàn

ju ìfẹ́ ìkọ̀kọ̀ lọ.

6Òtítọ́ ni ọgbẹ́ ọ̀rẹ́,

ṣùgbọ́n ìfẹnukonu ọ̀tá ni ẹ̀tàn.

7Kódà oyin kò dùn lẹ́nu ẹni tí ó ti yó

ṣùgbọ́n òróǹró gan an dùn lẹ́nu ẹni tí ebi ń pa.

8Bí ẹyẹ tí ó ṣáko lọ kúrò níbi ìtẹ́ rẹ̀

ni ènìyàn tí ó ṣáko lọ kúrò ní ilé rẹ̀.

9Ìpara olóòórùn dídùn àti tùràrí ń mú ayọ̀ wá sínú ọkàn

bẹ́ẹ̀ ni inú dídùn láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ ń wá láti inú ìmọ̀ràn tí ó ṣàkóso.

10Má ṣe kọ ọ̀rẹ́ rẹ àti ọ̀rẹ́ baba rẹ sílẹ̀,

má sì ṣe lọ sílé arákùnrin rẹ nígbà tí ìdààmú dé bá ọ

ó sàn kí o jẹ́ aládùúgbò tí ó súnmọ́ ni ju arákùnrin tí ó jìnnà sí ni.

11Gbọ́n, ọmọ mi, kí o sì mú ayọ̀ wá sínú ọkàn mi

nígbà náà ni mo le dá gbogbo ẹni tí ó bá kẹ́gàn mi.

12Ọlọ́gbọ́n rí ewu, ó sì fi ara pamọ́

ṣùgbọ́n aláìgbọ́n rí, kàkà kí ó dúró ó tẹ̀síwájú, ó sì jìyà rẹ̀.

13Gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àjèjì

fi ṣe ẹ̀rí ìdúró bí o bá ṣe onídùúró fún obìnrin oníṣekúṣe.

14Bí ènìyàn kan ń kígbe súre fún aládùúgbò rẹ ní òwúrọ̀

a ó kà á sí bí èpè.

15Àyà tí ó máa ń jà dàbí

ọ̀wààrà òjò ní ọjọ́ tí òjò ń rọ̀;

16dídá a lẹ́kun dàbí ìgbà tí ènìyàn ń dá afẹ́fẹ́ lẹ́kun

tàbí bí ẹni tí ó gbá òróró.

17Bí irin tí ń pọ́n irin mú

bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn kan ń pọ́n ẹlòmíràn mú.

18Ẹni tí ó tọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ yóò jẹ èso rẹ̀

ẹni tí ó sì fojú tó ọ̀gá rẹ̀ yóò gba ọlá.

19Bí omi tí ń ṣe àfihàn ojú, nígbà tí a bá wò ó

bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ènìyàn ń ṣe àfihàn ènìyàn.

20Kò tẹ́ ikú àti ìparun lọ́rùn rí

bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni ojú ènìyàn kò rí ìtẹ́lọ́rùn rí.

21Iná fún fàdákà iná ìléru fún wúrà,

ṣùgbọ́n a ń dán ènìyàn wò nípa ìyìn tí ó ń gbà.

22Bí a tilẹ̀ gún aláìgbọ́n nínú odó,

fi ọmọ odó gún un bí èlùbọ́

ìwọ kì yóò le è yọ ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ kúrò ní inú rẹ̀.

23Rí i dájú pé o mọ ipò tí àwọn agbo àgùntàn rẹ wà

bojútó àwọn agbo màlúù rẹ dáradára;

24Nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títí

adé kì í sì í wà lórí títí láéláé.

25Nígbà tí a bá kó koríko, ewéko tuntun yóò sì hù jáde, a ó sì kó koríko àwọn orí òkè wọlé

26àwọn àgùntàn yóò pèsè aṣọ fún ọ,

àti ewúrẹ́ yóò pèsè owó oko.

27Ìwọ yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà ewúrẹ́

láti bọ́ ọ àti ìdílé rẹ

àti láti tọ́jú àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ.