ሚክያስ 3 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ሚክያስ 3:1-12

መሪዎችና ነቢያት ተገሠጹ

1ከዚያም እኔ እንዲህ አልሁ፤

“እናንት የያዕቆብ መሪዎች፤

እናንት የእስራኤል ቤት ገዦች ስሙ፤

ፍትሕን ማወቅ አይገባችሁምን?

2መልካሙን ጠላችሁ፤ ክፉውንም ወደዳችሁ፤

የሕዝቤን ቈዳ ገፈፋችሁ፤

ሥጋቸውንም ከዐጥንቶቻቸው ለያችሁ፤

3የሕዝቤን ሥጋ በላችሁ፤

ቈዳቸውን ገፈፋችሁ፤

ዐጥንቶቻቸውንም ሰባበራችሁ፤

በመጥበሻ እንደሚጠበስ፣

በድስት እንደሚቀቀል ሥጋ ቈራረጣችኋቸው።”

4እነርሱም ወደ እግዚአብሔር ይጮኻሉ፤

እርሱ ግን አይመልስላቸውም፤

ካደረጉት ክፋት የተነሣ፣

በዚያ ጊዜ ፊቱን ከእነርሱ ይሰውራል።

5እግዚአብሔር እንዲህ ይላል፤

“ሕዝቤን የሚያስቱ ነቢያት፣

ሰው ሲያበላቸው፣ ‘ሰላም አለ’ ይላሉ፤

ሳያበላቸው ሲቀር ግን፣

ጦርነት ሊያውጁበት ይነሣሉ።

6ስለዚህ ሌሊቱ ያለ ራእይ፣

ጨለማውም ያለ ንግርት ይመጣባችኋል፤

በነቢያት ላይ ፀሓይ ትጠልቅባቸዋለች፤

ቀኑም ይጨልምባቸዋል።

7ባለ ራእዮች ያፍራሉ፤

ንግርተኞችም ይዋረዳሉ፤

ሁሉም ፊታቸውን ይሸፍናሉ፤

ከእግዚአብሔር መልስ የለምና።”

8እኔ ግን፣

ለያዕቆብ በደሉን፣

ለእስራኤልም ኀጢአቱን እነግር ዘንድ፣

ኀይልን በእግዚአብሔር መንፈስ፣

ፍትሕና ብርታትም ተሞልቻለሁ።

9እናንተ የያዕቆብ ቤት መሪዎች፣

እናንት የእስራኤል ቤት ገዦች፣

ፍትሕን የምትንቁ፣

ትክክለኛ የሆነውንም ነገር ሁሉ የምታጣምሙ፤ ስሙ፤

10ጽዮንን ደም በማፍሰስ፣

ኢየሩሳሌምን በክፋት የምትገነቡ፤ ስሙ።

11መሪዎቿ በጕቦ ይፈርዳሉ፤

ካህናቷ ለዋጋ ሲሉ ያስተምራሉ፤

ነቢያቷም ለገንዘብ ሲሉ ይናገራሉ።

ነገር ግን በእግዚአብሔር ላይ ተደግፈውም፣

እግዚአብሔር በመካከላችን አይደለምን?

ምንም ዐይነት ክፉ ነገር አይደርስብንም” ይላሉ።

12ስለዚህ በእናንተ ምክንያት፣

ጽዮን እንደ ዕርሻ ትታረሳለች፣

ኢየሩሳሌም የፍርስራሽ ክምር ትሆናለች፤

የቤተ መቅደሱም ኰረብታ ዐረም የበቀለበት ጕብታ ይሆናል።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 3:1-12

Bíbá àwọn olórí àti àwọn wòlíì wí

1Nígbà náà, ni mo wí pé,

“Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu,

ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli.

Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.

2Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi;

Ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn

àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;

3Àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi,

wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn.

Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́;

Wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò,

bí ẹran inú agbada?”

4Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa,

Ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn.

Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn,

nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.

5Báyìí ni Olúwa wí:

“Ní ti àwọn Wòlíì

tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà,

tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ,

wọn yóò kéde àlàáfíà;

Ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu,

wọn yóò múra ogun sí i.

6Nítorí náà òru yóò wá sórí yín,

tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan,

òkùnkùn yóò sì kùn fún yín,

tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀

Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì

ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.

7Ojú yóò sì ti àwọn Wòlíì

àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú.

Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn,

nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

8Ṣùgbọ́n ní tèmi,

èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa,

láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un,

àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.

9Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu,

àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli,

tí ó kórìíra òdodo

tí ó sì yí òtítọ́ padà;

10Tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀,

àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.

11Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀,

àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà

àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó.

Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé,

“Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa!

Ibi kan kì yóò bá wa.”

12Nítorí náà, nítorí tiyín,

ni a ó ṣe ro Sioni bí oko,

Jerusalẹmu yóò sì di ebè

àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.