ሚክያስ 1 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ሚክያስ 1:1-16

1በይሁዳ ነገሥታት በኢዮአታም፣ በአካዝና በሕዝቅያስ ዘመን ወደ ሞሬታዊው ወደ ሚክያስ የመጣው የእግዚአብሔር ቃል፣ ስለ ሰማርያና ስለ ኢየሩሳሌም ያየው ራእይ ይህ ነው፤

2እናንተ አሕዛብ ሆይ፤ ሁላችሁም ስሙ፤

ምድር ሆይ፤ በውስጧም የምትኖሩ ሁሉ አድምጡ፤

ጌታ ከቅዱስ መቅደሱ፣

ልዑል እግዚአብሔር በእናንተ ላይ ይመሰክርባችኋል።

በሰማርያና በኢየሩሳሌም ላይ የተላለፈ ፍርድ

3እነሆ፤ እግዚአብሔር ከመኖሪያ ስፍራው ይመጣል፤

ወርዶም በምድር ከፍታዎች ላይ ይራመዳል።

4ተራሮች ከሥሩ ይቀልጣሉ፤

ሸለቆዎችም ይሰነጠቃሉ፤

በእሳት ፊት እንዳለ ሰም፣

በገደል ላይ እንደሚወርድ ፈሳሽ ይሆናሉ።

5ይህ ሁሉ የሚሆነው ስለ ያዕቆብ በደል፣

ስለ እስራኤልም ቤት ኀጢአት ነው።

የያዕቆብ በደል ምንድን ነው?

ሰማርያ አይደለችምን?

የይሁዳስ የኰረብታ መስገጃ ምንድን ነው?

ኢየሩሳሌም አይደለችምን?

6“ስለዚህ ሰማርያን የፍርስራሽ ክምር፣

ወይን የሚተከልባትም ስፍራ አደርጋታለሁ፤

ድንጋዮቿን ወደ ሸለቆ አወርዳለሁ፤

መሠረቷንም ባዶ አደርጋለሁ።

7ጣዖቶቿ ሁሉ ይሰባበራሉ፤

ለቤተ መቅደሷ የቀረበው ገጸ በረከት በእሳት ይቃጠላል፤

ምስሎቿን ሁሉ እደመስሳለሁ፤

ገጸ በረከቷን በዝሙት ዐዳሪነት እንደ ሰበሰበች ሁሉ፣

አሁንም ገጸ በረከቷ የዝሙት ዐዳሪነት ዋጋ መቀበያ ይሆናል።”

ልቅሶና ሐዘን

8በዚህ ምክንያት አለቅሳለሁ፤ ዋይ ዋይም እላለሁ፤

ባዶ እግሬንና ዕርቃኔን እሄዳለሁ፤

እንደ ቀበሮ አላዝናለሁ፤

እንደ ጕጕትም አቃስታለሁ።

9ቍስሏ የማይሽር ነውና፤

ለይሁዳ ተርፏል፤

እስከ ሕዝቤ መግቢያ በር፣

እስከ ኢየሩሳሌም እንኳ ደርሷል።

10በጌት1፥10 ጌት የሚለው ቃል በዕብራይስጡ አውራ ከሚለው ጋር ተመሳሳይ አነባበብ አለው። አታውሩት፤

ከቶም አታልቅሱ1፥10 ዕብራይስጡ ከዚህ ጋር ሲስማማ፣ የሰብዓ ሊቃናት ትርጕም ግን በአኮ ላይ አታልቅሱ ይላል። በአኮ የሚለው የዕብራይስጡ ቃል አለቀሰ ከሚለው የዕብራይስጡ ቃል ጋር ተመሳሳይ አነባበብ አለው።

በቤትዓፍራ1፥10 ቤትዓፍራ ትርጕሙ የትቢያ ቤት ማለት ነው።

በትቢያ ላይ ተንከባለሉ።

11እናንት በሻፊር1፥11 ሻፊር ትርጕሙ አስደሳች ማለት ነው። የምትኖሩ፣

ዕርቃናችሁን ሆናችሁ በኀፍረት ዕለፉ፤

በጸዓናን1፥11 ጸዓናን የሚለው ቃል በዕብራይስጡ ውጣ ከሚለው ጋር ተመሳሳይ አነባበብ አለው። የሚኖሩ

ከዚያ አይወጡም፤

ቤትዔጼል በሐዘን ላይ ናት፤

ለእናንተም መጠጊያ ልትሆን አትችልም።

12ከመከራው መገላገልን በመሻት፣

በማሮት1፥12 ማሮት የሚለው ቃል በዕብራይስጡ መራራ ከሚለው ጋር ተመሳሳይ አነባበብ አለው። የሚኖሩ በሥቃይ

ይወራጫሉ፤

እስከ ኢየሩሳሌም በር ሳይቀር፣

ክፉ ነገር ከእግዚአብሔር ዘንድ መጥቷልና።

13እናንት በለኪሶ1፥13 ለኪሶ የሚለው ቃል በዕብራይስጡ ቡድን ከሚለው ጋር ተመሳሳይ አነባበብ አለው። የምትኖሩ፣

ፈረሶችን ከሠረገላው ጋር አያይዙ፤

ለጽዮን ሴት ልጅ፣

የኀጢአት መጀመሪያ እናንት ነበራችሁ፤

የእስራኤል በደል

በእናንተ ዘንድ ተገኝቷልና።

14ስለዚህ እናንተ ለሞሬሼትጌት፣

ማጫ ትሰጣላችሁ፤

የአክዚብ1፥14 አክዚብ ትርጕሙ አታላይ ወይም ማታለል ማለት ነው። ከተማ፣

ለእስራኤል ነገሥታት መታለያ ትሆናለች።

15እናንት በመሪሳ1፥15 መሪሳ የሚለው ቃል በዕብራይስጡ ድል አድራጊ ከሚለው ጋር ተመሳሳይ አነባበብ አለው። የምትኖሩ

ድል አድራጊ አመጣባችኋለሁ፤

ያ የእስራኤል ክብር የሆነው

ወደ ዓዶላም ይመጣል።

16ደስ ለምትሰኙባቸው ልጆቻችሁ፣

በሐዘን ራሳችሁን ተላጩ፤

ራሳችሁን እንደ አሞራ ራስ ተመለጡት፤

ከእናንተ በምርኮ ይወሰዳሉና።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 1:1-16

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.

2Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,

fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,

Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,

1.2: 1Ọb 22.28.Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.

Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu

3Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;

yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.

4Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,

àwọn Àfonífojì yóò sì pínyà,

bí idà níwájú iná,

bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.

5Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,

àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.

Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?

Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?

Kí ni àwọn ibi gíga Juda?

Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?

6“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,

bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.

Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.

Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.

7Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́

gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun:

Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.

Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,

gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”

Ẹkún òun ọfọ̀

8Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,

èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:

èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò

Èmi yóò ké bí akátá,

èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.

9Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;

ó sì ti wá sí Juda.

Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,

àní sí Jerusalẹmu.

10Ẹ má ṣe sọ ní Gati

ẹ má ṣe sọkún rárá.

Ní ilẹ̀ Beti-Ofra

mo yí ara mi nínú eruku.

11Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,

ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.

Àwọn tí ó ń gbé ni Ṣaanani

kì yóò sì jáde wá.

Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;

A ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.

12Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,

Ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.

13Ìwọ olùgbé Lakiṣi,

dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.

Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀

sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,

nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.

14Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀

fún Moreṣeti Gati.

Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.

15Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.

Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli

yóò sì wá sí Adullamu.

16Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀

nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,

sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,

nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.