መዝሙር 89 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 89:1-52

መዝሙር 89

መዝሙርና ለእግዚአብሔር ታማኝነት የቀረበ ጸሎት

የይዝራኤላዊው የኤታን ትምህርት።

1ስለ እግዚአብሔር ምሕረት ለዘለላለም እዘምራለሁ፤

በአፌም ታማኝነትህን ከትውልድ እስከ ትውልድ እገልጻለሁ።

2ምሕረትህን ለዘላለም እንደምትመሠርት፣

ታማኝነትህንም በሰማይ እንደምታጸና እናገራለሁ።

3አንተም እንዲህ ብለሃል፤ “ከመረጥሁት ጋር ኪዳን ገብቻለሁ፤

ለባሪያዬ ለዳዊት ምያለሁ፤

4‘ዘርህን ለዘላለም እተክላለሁ፤

ዙፋንህንም ከትውልድ እስከ ትውልድ አጸናለሁ።’ ” ሴላ

5እግዚአብሔር ሆይ፤ ሰማያት ድንቅ ሥራህን፣

ታማኝነትህንም በቅዱሳን ጉባኤ መካከል ያወድሳሉ፤

6በላይ በሰማያት ከእግዚአብሔር ጋር ማን ሊስተካከል ይችላል?

ከሰማያውያን ፍጥረታትስ መካከል ማን እግዚአብሔርን ይመስለዋል?

7እግዚአብሔር በቅዱሳን ጉባኤ መካከል በጣም የሚፈራ፣

በዙሪያውም ካሉት ሁሉ በላይ እጅግ የሚከበር ነው።

8የሰራዊት አምላክ እግዚአብሔር ሆይ፤ እንደ አንተ ያለ ማን ነው?

እግዚአብሔር ሆይ፤ አንተ ኀያል ነህ፤ ታማኝነትህም ከብቦሃል።

9የባሕርን ቍጣ ትቈጣጠራለህ፤

ሞገዱም ሲነሣ ጸጥ ታደርገዋለህ።

10አንተ ረዓብን የተሰየፈ ያህል አደቀቅኸው፤

በብርቱ ክንድህም ጠላቶችህን በተንሃቸው።

11ሰማያት የአንተ ናቸው፤ ምድርም የአንተ ናት፤

ዓለምንና በውስጧ ያለውን ሁሉ አንተ መሠረትህ።

12ሰሜንንና ደቡብን የፈጠርህ አንተ ነህ፤

ታቦርና አርሞንዔም በስምህ ሐሤት ያደርጋሉ።

13አንተ ክንደ ብርቱ ነህ፤

እጅህ ኀያል ናት፤ ቀኝ እጅህም ከፍ ከፍ ያለች ናት።

14ጽድቅና ፍትሕ የዙፋንህ መሠረቶች ናቸው፤

ምሕረትና ታማኝነት በፊትህ ይሄዳሉ።

15እግዚአብሔር ሆይ፤ እልልታን የሚያውቅ፣

በፊትህም ብርሃን የሚሄድ ሕዝብ ምስጉን ነው።

16ቀኑን ሙሉ በስምህ ደስ ይላቸዋል፤

በጽድቅህም ሐሤት ያደርጋሉ፤

17አንተ የብርታታቸው ክብር ነህና፤

በሞገስህም ቀንዳችንን89፥17 የጥንካሬ ምልክት ነው። ከፍ ከፍ አደረግህ።

18ጋሻችን89፥18 ወይም ልዑል ማለት ነው። የእግዚአብሔር ነውና፤

ንጉሣችንም የራሱ የእስራኤል ቅዱስ ነው።

19በዚያን ጊዜ በራእይ ተናገርህ፤

ታማኝ ሕዝብህንም እንዲህ አልህ፤

“ኀያሉን ሰው ሥልጣን አጐናጸፍሁት፤

ከሕዝብ መካከል የተመረጠውንም ከፍ ከፍ አደረግሁት።

20ባሪያዬን ዳዊትን አገኘሁት፤

በተቀደሰው ዘይቴም ቀባሁት።

21እጄ ይደግፈዋል፤

ክንዴም ያበረታዋል።

22በጠላት አይበለጥም፤

ክፉ ሰውም አይበግረውም።

23ባላንጣዎቹን በፊቱ አደቅቃቸዋለሁ፤

ጠላቶቹንም እቀጠቅጣለሁ።

24ታማኝነቴና ምሕረቴ ከእርሱ ጋር ይሆናል፤

በስሜም ቀንዱ ከፍ ከፍ ይላል።

25እጁን በባሕር ላይ፣

ቀኝ እጁንም በወንዞች ላይ አኖራለሁ።

26እርሱም፣ ‘አንተ አባቴ ነህ፤

አምላኬና መዳኛ ዐለቴም ነህ’ ብሎ ይጠራኛል።

27እኔም ደግሞ በኵሬ አደርገዋለሁ፤

ከምድር ነገሥታትም በላይ ከፍ ይላል።

28ምሕረቴንም ለዘላለም ለእርሱ እጠብቃለሁ፤

ከእርሱ ጋር የገባሁት ኪዳንም ጸንቶ ይኖራል።

29የዘር ሐረጉን ለዘላለም፣

ዙፋኑንም በሰማያት ዕድሜ ልክ አጸናለሁ።

30“ልጆቹ ሕጌን ቢተዉ፣

ደንቤን ባይጠብቁ፣

31ሥርዐቴን ቢጥሱ፣

ትእዛዜንም ባያከብሩ፣

32ኀጢአታቸውን በበትር፣

በደላቸውን በጅራፍ እቀጣለሁ።

33ምሕረቴን ግን ከእርሱ አላርቅም፤

ታማኝነቴንም አላጓድልበትም።

34ኪዳኔን አላፈርስም፤

ከአፌ የወጣውንም አላጥፍም።

35አንድ ጊዜ በቅድስናዬ ምያለሁና፣

ዳዊትን አልዋሸውም።

36የዘር ሐረጉ ለዘላለም፣

ዙፋኑም በፊቴ እንደ ፀሓይ ጸንቶ ይኖራል፤

37በሰማይ ታማኝ ምስክር ሆና እንደምትኖረው፣

እንደ ጨረቃ እርሱ ለዘላለም ይመሠረታል።” ሴላ

38አሁን ግን ናቅኸው፤ ጣልኸውም፤

የቀባኸውንም እጅግ ተቈጣኸው።

39ከባሪያህ ጋር የገባኸውን ኪዳን አፈረስህ፤

የክብር ዘውዱን ትቢያ ላይ ጥለህ አቃለልኸው።

40ቅጥሩን ሁሉ አፈራረስህ፤

ምሽጉንም ደመሰስህ።

41ዐላፊ አግዳሚው ሁሉ ዘረፈው፤

ለጎረቤቶቹ መዘባበቻ ሆነ።

42የጠላቶቹን ቀኝ እጅ ከፍ ከፍ አደረግህ፤

ባላንጣዎቹም ሁሉ ደስ አላቸው።

43የሰይፉን ስለት አጠፍህ፤

በጦርነትም ጊዜ አልረዳኸውም።

44ግርማዊነቱን አጠፋህበት፤

ዙፋኑንም ከዐፈር ደባለቅኸው።

45የወጣትነት ዘመኑን አሳጠርኸው፤

ዕፍረትንም አከናነብኸው። ሴላ

46እግዚአብሔር ሆይ፤ ይህ እስከ መቼ ይሆናል? ራስህንስ ለዘላለም ትሰውራለህን?

ቍጣህስ እንደ እሳት የሚነድደው እስከ መቼ ነው?

47ዘመኔ ምን ያህል ዐጭር እንደ ሆነች ዐስብ፤

የሰውን ልጆች እንዲያው ለከንቱ ፈጠርሃቸው!

48ሞትን ሳያይ ሕያው ሆኖ የሚቀር

ሰው አለን?

ራሱን ከሲኦል እጅ ማዳን የሚችል ማን ነው? ሴላ

49ጌታ ሆይ፤ ለዳዊት በታማኝነትህ የማልህለት፣

የቀድሞው ምሕረትህ የት አለ?

50ጌታ ሆይ፤ ባሪያህ89፥50 ባሮችህ የሚሉ አሉ። እንዴት እንደ ተፌዘበት፣

የብዙ ሰዎችንም ነቀፋ እንደ ታቀፍሁ ዐስብ።

51እግዚአብሔር ሆይ፤ ጠላቶችህ የተሣለቁበትን፣

የቀባኸውን ሰው ርምጃ የነቀፉበትን ሁኔታ ዐስብ።

52እግዚአብሔር ለዘላለም ይባረክ፤

አሜን፤ አሜን።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 89:1-52

Saamu 89

Maskili ti Etani ará Esra.

1Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé;

pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.

2Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé,

pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnrarẹ̀.

389.3-4: Sm 132.11; Ap 2.30.Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi

mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.

4‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé

èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’ ”

5Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa,

òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.

6Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa?

Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?

7Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi;

ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.

8Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ

ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.

9Ìwọ ń darí ríru omi Òkun;

nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.

10Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ

bí ẹni tí a pa;

ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ

tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.

11Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ:

ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀:

ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.

12Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn;

Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.

13Ìwọ ní apá agbára;

agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

14Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ:

ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.

15Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì,

Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.

16Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́,

wọn ń yin òdodo rẹ.

17Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn;

nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.

18Nítorí ti Olúwa ni asà wa,

ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.

19Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé:

“Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára,

èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.

2089.20: Ap 13.22.Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi;

pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án;

21Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀

apá mí yóò sì fi agbára fún un.

22Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀,

àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀

23Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ

èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀

24Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ

àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.

25Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí Òkun

àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá

26Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’

2789.27: If 1.5.Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi,

Ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.

28Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un,

àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.

29Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé,

àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.

30“Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀

tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.

31Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́

tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,

32Nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò;

àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán:

33Ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.

34Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.

35Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra;

èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.

36Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé,

àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.

3789.37: If 1.5; 3.14.A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá,

àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run”. Sela.

38Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra;

ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni ààmì òróró rẹ.

39Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo;

ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku

40Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀

ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.

41Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ;

ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.

42Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè;

ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.

43Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà,

ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.

44Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà,

ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.

45Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú;

ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.

46Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa?

Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé?

Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?

47Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó

nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!

48Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀?

Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú?

49Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà,

tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?

50Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ;

bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,

51Ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa,

tí wọn gan ipasẹ̀ Ẹni ààmì òróró rẹ.

52Olùbùkún ní Olúwa títí láé.

Àmín àti Àmín.