መዝሙር 79 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 79:1-13

መዝሙር 79

ብሔራዊ ሰቈቃ

የአሳፍ መዝሙር።

1አምላክ ሆይ፤ ሕዝቦች ርስትህን ወረሩ፤

የተቀደሰውን ቤተ መቅደስህን አረከሱ፤

ኢየሩሳሌምንም አፈራርሰው ጣሏት።

2የባሪያዎችህን ሬሳ ለሰማይ ወፎች፣

የቅዱሳንህንም ሥጋ ለምድር አራዊት፣

ምግብ አድርገው ሰጡ።

3ደማቸውንም በኢየሩሳሌም ዙሪያ፣

እንደ ውሃ አፈሰሱ፤

የሚቀብራቸውም አልተገኘም።

4እኛም ለጎረቤቶቻችን መዘባበቻ፣

በዙሪያችንም ላሉት መሣቂያ መሣለቂያ ሆንን።

5እግዚአብሔር ሆይ፤ ይህ እስከ መቼ ነው?

የምትቈጣውስ ለዘላለም ነውን?

ቅናትህስ እንደ እሳት ሲነድድ ይኖራልን?

6በማያውቁህ ሕዝቦች ላይ፣

ስምህን በማይጠሩ፣

መንግሥታት ላይ፣

መዓትህን አፍስስ፤

7ያዕቆብን በልተውታልና፤

መኖሪያ ቦታውንም ባድማ አድርገዋል።

8የአባቶቻችንን ኀጢአት በእኛ ላይ አትቍጠርብን፤

ምሕረትህ ፈጥና ወደ እኛ ትምጣ፤

በጭንቅ ላይ እንገኛለንና።

9አዳኛችን የሆንህ አምላክ ሆይ፤

ስለ ስምህ ክብር ብለህ ርዳን፤

ስለ ስምህ ስትል፣

ታደገን፤ ኀጢአታችንንም ይቅር በል።

10ሕዝቦች፣ “አምላካቸው የት አለ?”

ለምን ይበሉ?

የፈሰሰውን የአገልጋዮችህን ደም በቀል፣

ዐይናችን እያየ ሕዝቦች ይወቁት።

11የእስረኞች ሰቈቃ በፊትህ ይድረስ፤

በክንድህም ብርታት፣

ሞት የተፈረደባቸውን አድን።

12ጌታ ሆይ፤ ጎረቤቶቻችን በአንተ ላይ የተዘባበቱትን መዘባበት፣

ሰባት ዕጥፍ አድርገህ አስታቅፋቸው።

13እኛ ሕዝብህ፣ የማሰማሪያህ በጎችህ፣

ለዘላለም ምስጋና እናቀርብልሃለን፤

ከትውልድ እስከ ትውልድም፣

ውለታህን እንናገራለን።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 79:1-13

Saamu 79

Saamu ti Asafu.

1Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ;

wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́,

wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.

2Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ

fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ,

ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.

3Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi

yí Jerusalẹmu ká,

kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.

4Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká,

àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.

5Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé?

Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?

6Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè

tí kò ní ìmọ̀ rẹ,

lórí àwọn ìjọba

tí kò pe orúkọ rẹ;

7Nítorí wọ́n ti run Jakọbu

wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.

8Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn

jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa,

nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.

9Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa,

fún ògo orúkọ rẹ;

gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì

nítorí orúkọ rẹ.

10Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé,

“Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?”

Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè

kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.

11Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ,

gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ

ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.

12San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje

nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.

13Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ,

àti àgùntàn pápá rẹ,

yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé;

láti ìran dé ìran

ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.