መዝሙር 73 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 73:1-28

ሦስተኛ መጽሐፍ

ከመዝሙር 73–89

መዝሙር 73

የፍትሕ አሸናፊነት

የአሳፍ መዝሙር።

1እግዚአብሔር ልባቸው ንጹሕ ለሆነ፣

ለእስራኤል እንዴት ቸር ነው!

2እኔ ግን እግሬ ሊሰናከል፣

አዳልጦኝም ልወድቅ ጥቂት ቀረኝ።

3ክፉዎች ሲሳካላቸው አይቼ፣

በዐመፀኞች ቀንቼ ነበርና።

4አንዳች ጣር የለባቸውም፤

ሰውነታቸውም ጤናማና የተደላደለ ነው።

5በሰዎች የሚደርሰው ጣጣ አይደርስባቸውም፤

እንደ ማንኛውም ሰው መከራ አያገኛቸውም።

6ስለዚህ ትዕቢት የዐንገት ጌጣቸው ነው፤

ዐመፅንም እንደ ልብስ ተጐናጽፈዋል።

7የሠባ ዐይናቸው ይጕረጠረጣል፤73፥7 የዕብራይስጡ ከዚህ ጋር ይስማማል፤ የሱርስቱና የሰብዓ ሊቃናት ትርጕም ግን፣ ከደነደነው ልባቸው በደል ይወጣል ይላል።

ልባቸውም በከንቱ ሐሳብ ተሞልቶ ይፈስሳል።

8በፌዝና በክፋት ይናገራሉ፤

ቀና ቀና ብለውም በዐመፅ ይዝታሉ።

9አፋቸውን በሰማይ ላይ ያላቅቃሉ፤

አንደበታቸውም ምድርን ያካልላል።

10ስለዚህ ሕዝቡ ወደ እነርሱ ይነጕዳል፤

ውሃቸውንም በገፍ73፥10 በዕብራይስጡ የዚህ ሐረግ ትርጕም በትክክል አይታወቅም። ይጠጣሉ።

11“ለመሆኑ እግዚአብሔር እንዴት ያውቃል?

በልዑልስ ዘንድ ዕውቀት አለ?” ይላሉ።

12እንግዲህ፣ ክፉዎች ይህን ይመስላሉ፤

ሁልጊዜ ግድ የለሽና ሀብት በሀብት ናቸው።

13ለካ ልቤን ንጹሕ ያደረግሁት በከንቱ ነው፤

እጄንም በየዋህነት የታጠብሁት በከንቱ ኖሯል!

14ቀኑን ሙሉ ተቀሠፍሁ፤

ጧት ጧትም ተቀጣሁ።

15“እኔ እንደዚህ እናገራለሁ” ብልማ ኖሮ፣

የልጆችህን ትውልድ በከዳሁ ነበር።

16ይህን ነገር ለመረዳት በሞከርሁ ጊዜ፣

አድካሚ ተግባር መስሎ ታየኝ።

17ይኸውም ወደ አምላክ መቅደስ እስክገባ፣

መጨረሻቸውንም እስካይ ድረስ ነበር።

18በርግጥ በሚያዳልጥ ስፍራ አስቀመጥሃቸው፤

ወደ ጥፋትም አወረድሃቸው።

19እንዴት ፈጥነው በቅጽበት ጠፉ!

በድንጋጤ ፈጽመው ወደሙ።

20ሰው ከሕልሙ ሲነቃ እንደሚሆነው፣

ጌታ ሆይ፤ አንተም በምትነሣበት ጊዜ፣

እንደ ቅዠት ከንቱ ታደርጋቸዋለህ።

21ነፍሴ በተማረረች ጊዜ፣

ልቤም በተቀሠፈ ጊዜ፣

22ስሜት የሌለውና አላዋቂ ሆንሁ፤

በፊትህም እንደ እንስሳ ሆንሁ።

23ይህም ሆኖ ዘወትር ከአንተ ጋር ነኝ፤

አንተም ቀኝ እጄን ይዘኸኛል።

24በምክርህ መራኸኝ፤

ኋላም ወደ ክብር ታስገባኛለህ።

25በሰማይ ከአንተ በቀር ማን አለኝ?

በምድርም ከአንተ ሌላ የምሻው የለኝም።

26ሥጋዬና ልቤ ሊደክሙ ይችላሉ፤

እግዚአብሔር ግን የልቤ ብርታት፣

የዘላለም ዕድል ፈንታዬ ነው።

27እነሆ፤ ከአንተ የሚርቁ ይጠፋሉና፤

አንተ ታማኞች ያልሆኑልህን ሁሉ ታጠፋቸዋለህ።

28ለእኔ ግን ወደ እግዚአብሔር መቅረብ ይሻለኛል፤

ጌታ እግዚአብሔርን መጠጊያዬ አድርጌዋለሁ፤

ስለ ሥራህም ሁሉ እናገር ዘንድ።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 73:1-28

ÌWÉ KẸTA

Saamu 73–89

Saamu 73

Saamu ti Asafu.

1Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli,

fún àwọn ọlọ́kàn funfun.

2Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán;

ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.

3Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé

nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.

4Wọn kò ṣe wàhálà;

ara wọn mókun wọn sì lágbára.

5Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn;

a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.

6Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn;

ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.

7Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá;

ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n

8Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti

ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.

9Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run

ahọ́n wọn gba ipò ayé.

10Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn

wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

11Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀?

Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”

12Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí

ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.

13Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́;

nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.

14Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu;

a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.

15Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,”

Èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.

16Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí,

Ó jẹ́ ìnilára fún mi.

17Títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run;

Nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.

18Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́

ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.

19Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí

bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan!

Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!

20Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí,

bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa,

ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.

21Nígbà tí inú mi bàjẹ́

àti ọkàn mi ṣì korò,

22Mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye;

mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.

23Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo;

ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.

24Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi

ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo

25Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ?

Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.

26Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà

ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi

àti ìpín mi títí láé.

27Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé

ìwọ ti pa gbogbo wọn run;

tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ

28Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run

Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi;

Kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.