መዝሙር 49 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 49:1-20

መዝሙር 49

የሀብት ከንቱነት

ለመዘምራን አለቃ፤ የቆሬ ልጆች መዝሙር።

1እናንተ ሕዝቦች ሁላችሁ፤ ይህን ስሙ፤

በዓለም የምትኖሩ ሁሉ፤ ይህን አድምጡ።

2ዝቅተኞችና ከፍተኞች፤

ባለጠጎችና ድኾች ይህን በአንድነት ስሙ።

3አፌ የጥበብን ቃል ይናገራል፤

የልቤም ሐሳብ ማስተዋልን ይሰጣል።

4ጆሮዬን ወደ ምሳሌ አዘነብላለሁ፤

እንቆቅልሼንም በበገና እፈታለሁ።

5የአጭበርባሪዎች ክፋት በከበበኝ ጊዜ፣

በክፉ ቀን ለምን እፈራለሁ?

6በሀብታቸው የሚመኩትን፣

በብልጽግናቸውም የሚታመኑትን ለምን እፈራለሁ?

7የሌላውን ሕይወት መቤዠት የሚችል ሰው፣

ወይም ለእግዚአብሔር ወጆ የሚከፍልለት ማንም የለም።

8የነፍስ ቤዛ ውድ ነውና፤

በቂ ዋጋም ከቶ ሊገኝለት አይችልም፤

9በዚህም ዘላለም ይኖራል፣

መበስበስንም አያይም።

10ጠቢባን ሟቾች መሆናቸው የሚታይ ነው፤

ቂልና ሞኝም በአንድነት ይጠፋሉ፤

ጥሪታቸውንም ለሌላው ጥለው ይሄዳሉ።

11መሬቶችን በስማቸው ቢሰይሙም፣

መቃብራቸው የዘላለም ቤታቸው፣

ከትውልድ እስከ ትውልድም መኖሪያቸው ይሆናል።

12ሰው በሀብቱ እንደ ተከበረ አይዘልቅም፤

ታይተው የሚጠፉ እንስሳትን ይመስላል።49፥12 በሰብዓ ሊቃናት ትርጕምና በሱርስቱ ቅጅ 12 ከ20 ጋር አንድ ዐይነት ነው፤ ዕብራይስጡ ግን ከዚህ ይለያል።

13ይህ የተላላዎች ዕድል ፈንታ፣

የእነርሱንም አባባል ተቀብለው ለሚከተሏቸው፣

መጨረሻ ግብ ነው። ሴላ

14እንደ በጎች ለሲኦል49፥14 በዚህ እና በ15 ላይ ዕብራይስጡ ከዚህ ጋር ይስማማል፤ አንዳንድ የእንግሊዝኛ ቅጆች ግን መቃብር ይላሉ። የተዳረጉ ናቸው፤

ሞትም እረኛቸው ይሆናል፤

ቅኖች በማለዳ ይገዟቸዋል፤

አካላቸው ከክብር ቤታቸው ርቆ፣

በሲኦል ይፈራርሳል።

15እግዚአብሔር ግን ነፍሴን49፥15 ወይም ሕይወቴን ከሲኦል እጅ ይቤዣታል፤

በርግጥም በእርሱ ዘንድ ተቀባይነት አለኝ። ሴላ

16ሰው ባለጠጋ ሲሆን፣

የቤቱም ክብር ሲበዛለት አትፍራ፤

17በሚሞትበትም ጊዜ ይዞት የሚሄደው አንዳች የለምና፤

ክብሩም አብሮት አይወርድም።

18በሕይወት ሳለ ራሱን እንደ ተባረከ ቢቈጥርም፣

ሰዎች በበለጸግህ ጊዜ ቢያወድሱህም፣

19ብርሃን ከቶ ወደማያዩት፣

ወደ አባቶች ማኅበር ይቀላቀላል።

20ሰው በሀብቱ እንደ ተከበረ አይዘልቅም፤

ታይተው የሚጠፉ እንስሳትን ይመስላል።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 49:1-20

Saamu 49

Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu.

1Ẹ gbọ́ èyí, gbogbo ènìyàn!

Ẹ fi etí sí i, gbogbo ẹ̀yin aráyé.

2Àti ẹni tí ó ga àti ẹni tí ó kéré

tálákà àti ọlọ́lá pẹ̀lú!

3Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,

èrò láti ọkàn mi yóò mú òye wá

4Èmi yóò dẹ etí mi sílẹ̀ sí òwe,

èmi yóò ṣí ọ̀rọ̀ ìkọ̀kọ̀ mi sílẹ̀ lójú okùn dùùrù.

5Èéṣe ti èmi yóò bẹ̀rù nígbà tí ọjọ́ ibi dé?

Nígbà tí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ajinnilẹ́sẹ̀ mi yí mi ká,

6Àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn,

tí wọn sì ń ṣe ìlérí ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ wọn.

7Kò sí ọkùnrin tí ó lè ra ẹ̀mí ẹnìkejì rẹ̀

padà tàbí san owó ìràpadà fún

Ọlọ́run.

8Nítorí ìràpadà fún ẹni jẹ́ iyebíye

kò sì sí iye owó tó tó fún sísan rẹ̀,

9Ní ti kí ó máa wà títí ayé

láìrí isà òkú.

10Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rí ọkùnrin ọlọ́gbọ́n tí ó kú,

bẹ́ẹ̀ ni aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n pẹ̀lú ṣègbé

wọ́n sì fi ọrọ̀ wọn sílẹ̀ fún ẹlòmíràn.

11Ibojì wọn ni yóò jẹ́ ilé wọn láéláé,

ibùgbé wọn láti ìrandíran,

wọn sọ orúkọ ilẹ̀ wọn ní orúkọ ara wọn.

12Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí o wà nínú ọlá kò dúró pẹ́

ó sì dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.

13Èyí ni òtítọ́ àwọn ènìyàn tí ó

gbàgbọ́ nínú ara wọn,

àti àwọn tí ń tẹ̀lé wọn,

tí ó gba ọ̀rọ̀ wọn. Sela.

14Gẹ́gẹ́ bí àgùntàn ni a tẹ́ wọn sínú isà òkú

ikú yóò jẹun lórí wọn;

ẹni tí ó dúró ṣinṣin ni yóò,

jẹ ọba lórí wọn ní òwúrọ̀;

Ẹwà wọn yóò díbàjẹ́,

isà òkú ni ibùgbé ẹwà wọn.

15Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ra ọkàn mi padà

kúrò nínú isà òkú,

yóò gbé mi lọ sọ́dọ̀ òun fún rara rẹ̀.

16Má ṣe bẹ̀rù nígbà tí ẹnìkan bá di ọlọ́rọ̀.

Nígbà tí ìyìn ilé rẹ̀ ń pọ̀ sí i.

17Nítorí kì yóò mú ohun kan lọ nígbà tí ó bá kú,

ògo rẹ̀ kò ní bá a sọ̀kalẹ̀ sí ipò òkú

18Nígbà tí ó wà láyé, ó súre fún ọkàn ara rẹ̀.

Àwọn ènìyàn yìn ọ́ nígbà tí ìwọ ṣe rere.

19Òun yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ìran àwọn baba rẹ̀

àwọn tí ki yóò ri ìmọ́lẹ̀ ayé.

20Ọkùnrin tí ó ní ọlá tí kò ní òye dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.