መዝሙር 17 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 17:1-15

መዝሙር 17

የንጹሕ ሰው አቤቱታ

የዳዊት ጸሎት።

1እግዚአብሔር ሆይ፤ በቅንነት የቀረበውን አቤቱታዬን ስማ፤

ጩኸቴንም አድምጥ፤

ከአታላይ ከንፈር ያልወጣውን፣

ጸሎቴን አድምጥ።

2ጽድቄ ከአንተ ዘንድ ይምጣ፤

ዐይኖችህም ፍትሕን ይዩ።

3ልቤን መረመርኸው፣ በሌሊት ጠጋ

ብለህ ፈተንኸኝ፤

ፈተሽኸኝ አንዳች አላገኘህብኝም፤

አንደበቴም ዕላፊ አልሄደም።

4ከሰዎች ተግባር፣

በከንፈርህ ቃል፣

ከዐመፀኞች መንገድ፣

ራሴን ጠብቄአለሁ።

5አረማመዴ በመንገድህ ጸንቷል

እግሮቼም አልተንሸራተቱም።

6አምላክ ሆይ፤ ስለምትመልስልኝ አንተን እጣራለሁ፤

ጆሮህን ወደ እኔ ጣል አድርገህ ጸሎቴን ስማ።

7ከጠላቶቻቸው መተገኛ ያደረጉህን፣

በቀኝ እጅህ የምትታደግ ሆይ፤

ጽኑ ፍቅርህን ድንቅ አድርገህ ግለጥ።

8እንደ ዐይንህ ብሌን ጠብቀኝ፤

በክንፎችህም ጥላ ሰውረኝ፤

9ከሚያስጨንቁኝ ከክፉዎች፣

ከሚከብቡኝ አደገኛ ባላንጣዎቼ ጋርደኝ።

10ደንዳና ልባቸውን ደፈኑት፤

በአፋቸውም ትዕቢት ይናገራሉ።

11አሳድደው ደረሱብኝ፤ ከበቡኝም፤

መሬት ላይ ሊዘርሩኝም አፈጠጡብኝ።

12እነርሱ ለንጥቂያ እንደሚጓጓ አንበሳ፣

በስውርም እንደሚያደባ ደቦል አንበሳ ናቸው።

13እግዚአብሔር ሆይ፤ ተነሥተህ ግጠማቸውና ጣላቸው፤

በሰይፍህም ከክፉዎች ታደገኝ።

14እግዚአብሔር ሆይ፤ እንዲህ ካሉት ሰዎች በክንድህ አድነኝ፤

ዕድል ፈንታቸው ይህችው ሕይወት ብቻ ከሆነች፣ ከዚህ ዓለም ሰዎች ታደገኝ።

ከመዝገብህ ሆዳቸውን ሞላህ፤

ልጆቻቸውም ተትረፍርፎላቸዋል፤

ለልጆቻቸውም ሀብት ያከማቻሉ።

15እኔ ግን በጽድቅ ፊትህን አያለሁ፤

ስነቃም ክብርህን አይቼ እረካለሁ።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 17:1-15

Saamu 17

Àdúrà ti Dafidi

1Gbọ́, Olúwa, ẹ̀bẹ̀ òtítọ́ mi;

fi etí sí igbe mi.

Tẹ́tí sí àdúrà mi

tí kò ti ètè ẹ̀tàn jáde.

2Kí ìdáláre mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ;

kí ojú rẹ kí ó rí ohun tí ó tọ́.

3Ìwọ ti dán àyà mi wò,

ìwọ sì bẹ̀ mí wò ní òru, o sì ti wádìí mi,

ìwọ kì yóò rí ohunkóhun èmi ti pinnu pé,

ẹnu mi kì yóò ṣẹ̀.

4Bí ó ṣe ti iṣẹ́ ènìyàn nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ,

èmi ti pa ara mi mọ́

kúrò ní ọ̀nà àwọn ìkà.

5Ìrìn mí ti jẹ mọ́ ọ̀nà rẹ;

ẹsẹ̀ mi kì yóò yọ̀.

6Èmi ké pè ọ́, Ọlọ́run, nítorí tí ìwọ yóò dá mi lóhùn

dẹ etí rẹ sí mi kí o sì gbọ́ àdúrà mi.

7Fi ìṣeun ìyanu ìfẹ́ ńlá rẹ hàn

ìwọ tí ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gba àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ là

lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.

8Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú rẹ;

fi mí pamọ́ sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ,

9lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú tí ń fóròó mi,

kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá apani tí ó yí mi ká.

10Wọ́n pa ọkàn aláìláàánú wọn mọ́,

wọ́n sì fi ẹnu wọn sọ̀rọ̀ ìgbéraga.

11Wọ́n sì mú mi mọ́lẹ̀, wọ́n sì yí mi ká,

pẹ̀lú ojú ìṣọ́ra láti ṣọ́ mi sílẹ̀.

12Wọn dàbí i kìnnìún tí ebi ń pa fún ìjẹ,

àní bí kìnnìún ńlá tí ó ń ba níbi ìkọ̀kọ̀.

13Dìde, Olúwa, dojúkọ wọ́n, rẹ̀ wọ́n sílẹ̀;

gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ẹni búburú nípa idà rẹ.

14Olúwa, nípa ọwọ́ rẹ, gbà mí kúrò lọ́wọ́ irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀,

kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn ayé yìí, tí èrè wọn wà nínú ayé yìí.

Ìwọ ń pa ebi àwọn tí ìwọ fẹ́ràn lẹ́nu mọ́;

àwọn ọmọ wọn sì ní ọ̀pọ̀lọpọ̀,

wọ́n sì kó ọrọ̀ jọ fún àwọn ọmọ wọn.

15Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi yóò máa wo ojú rẹ ní òdodo;

nígbà tí èmi bá jí, èmi yóò ní ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí èmi bá rí àwòrán rẹ.