መዝሙር 135 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 135:1-21

መዝሙር 135

የምስጋና መዝሙር

135፥15-20 ተጓ ምብ – መዝ 115፥4-11

1ሃሌ ሉያ።135፥1 3 እና 21 ጭምር በአንዳንድ ትርጕሞች እግዚአብሔር ይመስገን ይላሉ።

የእግዚአብሔርን ስም ወድሱ፤

እናንት የእግዚአብሔር አገልጋዮች ሆይ፤ አመስግኑት፤

2በእግዚአብሔር ቤት፣

በአምላካችን ቤት አደባባይ የምትቆሙ አመስግኑት።

3እግዚአብሔር ቸር ነውና እግዚአብሔርን አመስግኑ፤

መልካም ነውና፣ ለስሙ ዘምሩ፤

4እግዚአብሔር ያዕቆብን ለራሱ፣

እስራኤልንም ውድ ንብረቱ አድርጎ መርጧልና።

5እግዚአብሔር ታላቅ እንደ ሆነ፣

ጌታችንም ከአማልክት ሁሉ እንደሚበልጥ ዐውቃለሁና።

6በሰማይና በምድር፣

በባሕርና በጥልቅ ሁሉ ውስጥ፣

እግዚአብሔር ደስ ያሰኘውን ሁሉ ያደርጋል።

7እርሱ ደመናትን ከምድር ዳርቻ ያስነሣል፤

መብረቅ ከዝናብ ጋር እንዲወርድ ያደርጋል፤

ነፋሳትንም ከማከማቻው ያወጣል።

8በኵር ሆኖ በግብፅ የተወለደውን፣

ከሰው ጀምሮ እስከ እንስሳ ቀሠፈ።

9ግብፅ ሆይ፤ በፈርዖንና በአገልጋዮቹ ሁሉ ላይ፣

በመካከልሽ ታምራትንና ድንቅን ሰደደ።

10ብዙ ሕዝቦችን መታ፤

ኀያላን ነገሥታትንም ገደለ።

11የአሞራውያንን ንጉሥ ሴዎንን፣

የባሳንን ንጉሥ ዐግን፣

የከነዓንን ነገሥታት ሁሉ ገደለ፤

12ምድራቸውንም ርስት አድርጎ፣

ለሕዝቡ ርስት እንዲሆን ለእስራኤል ሰጠ።

13እግዚአብሔር ሆይ፤ ስምህ ዘላለማዊ ነው፤

እግዚአብሔር ሆይ፤ መታሰቢያህም ከትውልድ እስከ ትውልድ ይኖራል።

14እግዚአብሔር ለሕዝቡ ይፈርዳልና፣

ለአገልጋዮቹም ይራራላቸዋል።

15የአሕዛብ ጣዖታት ከብርና ከወርቅ የተሠሩ፣

የሰው እጅ ያበጃቸው ናቸው።

16አፍ አላቸው፤ አይናገሩም፤

ዐይን አላቸው፤ አያዩም፤

17ጆሮ አላቸው፤ አይሰሙም፤

በአፋቸውም እስትንፋስ የለም።

18እነዚህን የሚያበጁ፣

የሚታመኑባቸውም ሁሉ እንደ እነርሱ ይሁኑ።

19የእስራኤል ቤት ሆይ፤ እግዚአብሔርን ባርኩ፤

የአሮን ቤት ሆይ፤ እግዚአብሔርን ባርኩ፤

20የሌዊ ቤት ሆይ፤ እግዚአብሔርን ባርኩ፤

እግዚአብሔርን የምትፈሩ ሆይ፤ እግዚአብሔርን ባርኩ።

21በኢየሩሳሌም የሚኖር እግዚአብሔር፣ ከጽዮን ይባረክ።

ሃሌ ሉያ።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 135:1-21

Saamu 135

1Ẹ yin Olúwa.

Ẹ yin orúkọ Olúwa;

ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.

2Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa,

nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.

3Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun;

ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.

4Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀;

àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.

5Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi,

àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.

6Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú,

ní ọ̀run àti ní ayé,

ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.

7Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá:

ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò:

ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.

8Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti,

àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.

9Ẹni tí ó rán iṣẹ́ ààmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti,

sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.

10Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀,

tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.

11Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu,

ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:

12Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,

ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.

13Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé;

ìrántí rẹ Olúwa, láti ìrandíran.

14135.14: Hb 10.30.Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀,

yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.

15Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà,

iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.

16Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀;

wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.

17Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀;

bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn

18Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn:

gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.

19Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa,

ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún Olúwa.

20Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa;

ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, fi ìbùkún fún Olúwa.

21Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá,

tí ń gbé Jerusalẹmu.

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.