ሆሴዕ 4 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ሆሴዕ 4:1-19

በእስራኤል ላይ የቀረበ ክስ

1በምድሪቱ በምትኖሩ በእናንተ ላይ

እግዚአብሔር የሚያቀርበው ክስ ስላለው፣

እናንት እስራኤላውያን ይህን የእግዚአብሔርን ቃል ስሙ፤

“ታማኝነት የለም፤ ፍቅርም የለም፤

እግዚአብሔርንም ማወቅ በምድሪቱ የለም።

2በዚያ ያለው ርግማን4፥2 መርገምን ያመለክታል፣ መዋሸት፣ መግደል፣

መስረቅና ማመንዘር ብቻ ነው፤

ቃል ኪዳንን ሁሉ ያፈርሳሉ፤

ደም ማፍሰስና ግድያ ይበዛል።

3ስለዚህ ምድሪቱ አለቀሰች፤4፥3 ወይም ደረቀች

በውስጧም የሚኖሩ ሁሉ ኰሰመኑ፤

የምድር አራዊት፣ የሰማይ ወፎች፣

የባሕርም ዓሦች ዐለቁ።

4“ነገር ግን ማንም ሰው አይከራከር፤

ማንም ሌላውን አይወንጅል፤

በካህናት ላይ ክስን እንደሚያቀርቡ፣

ሕዝብህ እንደዚያው ናቸውና።

5ቀንና ሌሊት ትደናበራላችሁ፤

ነቢያትም ከእናንተ ጋር ይደናበራሉ፤

ስለዚህ እናታችሁን አጠፋታለሁ፤

6ሕዝቤ ዕውቀት ከማጣቱ የተነሣ ጠፍቷል።

“ዕውቀትን ስለ ናቃችሁ፣

እኔም ካህናት እንዳትሆኑ ናቅኋችሁ፤

የአምላካችሁን ሕግ ስለ ረሳችሁ፣

እኔም ልጆቻችሁን እረሳለሁ።

7ካህናት በበዙ ቍጥር፣

በእኔ ላይ የሚያደርጉት ኀጢአት በዝቷል፤

ክብራቸውንም4፥7 ማሶሬቲክ የሚለው እንዲሁ ሲሆን የጥንት ዕብራውያን ጸሐፍት ትውፊት ግን ክብሬን ይላል። በውርደት ለውጠዋል።4፥7 ሱርስትና የጥንት ዕብራውያን ጸሐፍት ትውፊት የሚሉት እንዲሁ ሲሆን፣ ማሶሬቲክ ግን እለውጠዋለሁ ይላል።

8የሕዝቤ ኀጢአት ለመብል ሆኖላቸዋል፤

ርኩሰታቸውንም እጅግ ወደዱ።

9ካህናትም ከሕዝቡ የተለዩ አይደሉም፤

ሁሉንም እንደ መንገዳቸው እቀጣቸዋለሁ፤

እንደ ሥራቸውም እከፍላቸዋለሁ።

10“ይበላሉ ግን አይጠግቡም፤

ያመነዝራሉ ግን አይበዙም፤

እግዚአብሔርን በመተው፣

ራሳቸውን 11ለአመንዝራነት፣

ለአሮጌና ለአዲስ የወይን ጠጅ አሳልፈው ሰጡ፤

በእነዚህም የሕዝቤ ማስተዋል ተወሰደ፤

12ከዕንጨት የተሠራውን ጣዖት ምክር ይጠይቃሉ፤

ዘንጋቸውም ይመልስላቸዋል።

የአመንዝራነት መንፈስ ያስታቸዋል፤

ለአምላካቸውም ታማኝ አልሆኑም።

13በተራሮችም ጫፍ ላይ ይሠዋሉ፤

መልካም ጥላ ባለው፣ በባሉጥ፣

በኮምቦልና በአሆማ ዛፍ ሥር፣

በኰረብቶችም ላይ የሚቃጠል ቍርባን ያቀርባሉ።

ስለዚህ ሴቶች ልጆቻችሁ ዘማውያን፣

ምራቶቻችሁም አመንዝራዎች ይሆናሉ።

14“ሴቶች ልጆቻችሁ ዘማውያን ሲሆኑ፣

የልጆቻችሁም ሚስቶች ሲያመነዝሩ

አልቀጣቸውም።

ወንዶች ከጋለሞቶች ጋር ይሴስናሉ፤

ከቤተ ጣዖት ዘማውያን ጋር ይሠዋሉና፤

የማያስተውል ሕዝብ ወደ ጥፋት ይሄዳል!

15“እስራኤል ሆይ፤ አንቺ ብታመነዝሪም፣

ይሁዳ በበደለኛነት አትጠየቅ።

“ወደ ጌልገላ አትሂዱ፤

ወደ ቤትአዌንም4፥15 ቤትአዌን የእግዚአብሔር ቤት የተባለችው ቤቴል ስትሆን፣ የቃሉ ትርጕም የክፋት ቤት ማለት ነው። አትውጡ፤

‘ሕያው እግዚአብሔርን’ ብላችሁም አትማሉ።

16እስራኤላውያን እንደ እልኸኛ ጊደር፣

እልኸኞች ናቸው፤

ታዲያ እግዚአብሔር እነርሱን በመልካም መስክ ውስጥ እንዳሉ የበግ ጠቦቶች

እንዴት ያሰማራቸዋል?

17ኤፍሬም ከጣዖት ጋር ተጣምሯል፤

እስቲ ተዉት፤

18መጠጣቸው ባለቀ ጊዜ እንኳ፣

ዘማዊነታቸውን አያቆሙም፤

ገዦቻቸውም ነውርን አጥብቀው ይወድዳሉ።

19ዐውሎ ነፋስ ጠራርጎ ይወስዳቸዋል፤

መሥዋዕቶቻቸውም ኀፍረት ያመጡባቸዋል።”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Hosea 4:1-19

Ẹ̀sùn tí Ọlọ́run fi kan Israẹli

1Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli,

nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn

kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà.

“Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́

Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà

2Àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn

olè jíjà àti panṣágà.

Wọ́n rú gbogbo òfin,

ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.

3Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo

olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù.

Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run

àti ẹja inú omi ló ń kú.

4“Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá,

kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì

nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí

àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà

5Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru

àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín

Èmi ó pa ìyá rẹ run

6Àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀.

“Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀.

Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi;

nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀

Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.

7Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i

bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi.

Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú

8wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi

Wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.

9Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́: bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí

Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn.

Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.

10“Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó;

wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i,

nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa

sílẹ̀ 11‘Wọ́n sì ti fi ara wọn’ fún àgbèrè,

wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́

àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù 12Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi

ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn.

Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà

wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.

13Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá,

Wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré

Lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari

àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára

Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè

àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.

14“Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín

ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè

tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín,

nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè

nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́.

Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà.

Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!

15“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli

Ìdájọ́ yìí wà fún un yín Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi.

“Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali.

Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni

ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’

16Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí

bí alágídí ọmọ màlúù

Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn

bí àgùntàn ní pápá oko tútù?

17Efraimu ti darapọ̀ mọ́

òrìṣà Ẹ fi sílẹ̀!

18Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán

wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè

Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.

19Ìjì ni yóò gbá wọn lọ.

Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.