시편 56 – KLB & YCB

Korean Living Bible

시편 56:1-13

하나님을 신뢰하는 기도

(다윗이 가드에서 블레셋 사람들에게 잡혔을 때 지은 시. 성가대 지휘자를 따라 ‘멀리 상수리나무에 앉은 비둘기’ 란 곡조에 맞춰 부른 노래)

1하나님이시여,

나를 불쌍히 여기소서.

사람들이 나를 짓밟고

하루 종일 몰아붙이고 있습니다.

2내 원수들이 종일

나를 추격합니다.

교만하게 나를 대적하는 자

많습니다.

3내가 두려울 때

주를 신뢰하겠습니다.

4내가 하나님을 신뢰하고

주의 말씀을 찬양합니다.

내가 하나님을 신뢰하므로

두려워하지 않겠습니다.

사람에 불과한 자가

나를 어떻게 하겠습니까?

5내 원수들이 하루 종일

내 말을 곡해하며

항상 나를 해할 음모를

꾸미고 있습니다.

6그들이 공모하고 숨어서

내 거동을 일일이 살피며

나를 죽일 기회만 엿보고 있습니다.

7하나님이시여,

그들이 결코 피하지 못하게 하시고

주의 분노로 그들을 벌하소서.

8주는 나의 슬픔을 아십니다.

내 눈물을 주의 병에 담으소서.

내 눈물이

주의 책에 기록되지 않았습니까?

9내가 소리쳐 주를 부를 때

내 원수들이 물러갈 것이므로

내가 이것으로 하나님이

내 편에 계시는 것을 알 것입니다.

10내가 하나님을 신뢰하고

주의 말씀을 찬양합니다.

내가 여호와를 신뢰하고

주의 말씀을 찬양합니다.

11내가 하나님을 신뢰하고

두려워하지 않을 것입니다.

사람이 나를 어찌하겠습니까?

12하나님이시여,

내가 주께 약속한 것이 있으니

감사제를 주께 드리겠습니다.

13주께서는

나를 죽음에서 건져 주시고

넘어지지 않게 하셨으며

나를 56:13 또는 ‘하나님’주 앞에서 생명의 빛 가운데

다니도록 하셨습니다.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 56:1-13

Saamu 56

Fún adarí orin. Ti ohùn “Àdàbà lórí Óákù òkè réré.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí àwọn ará Filistini ka mọ́ ní Gati.

1Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, nítorí àwọn ènìyàn ń fi ìgbónára lépa mi;

ní gbogbo ọjọ́ ni wọn ń kọjú ìjà

sí mi, wọn ń ni mi lára.

2Àwọn ọ̀tá mi ń lé mi ní gbogbo ọjọ́,

àwọn ènìyàn ń kọjú ìjà sí mi nínú ìgbéraga wọn.

3Nígbà tí ẹ̀rù bà ń bà mí,

èmi o gbẹ́kẹ̀lé ọ.

4Nínú Ọlọ́run èmi yóò máa yìn ọ̀rọ̀ rẹ,

nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi; ẹ̀rù kì yóò bà mí

kí ni ẹran-ara lè ṣe sí mi?

5Wọn ń yí ọ̀rọ̀ mí ní gbogbo ọjọ́,

wọn ń gbèrò nígbà gbogbo láti ṣe mí níbi.

6Wọn kó ara wọn jọ, wọ́n ba

Wọ́n ń ṣọ́ ìgbésẹ̀ mi

wọn ń làkàkà láti gba ẹ̀mí mi.

7San ẹ̀san iṣẹ́ búburú wọ́n fún wọn;

Ní ìbínú rẹ, Ọlọ́run, wọ́ àwọn ènìyàn náà bọ́ sílẹ̀.

8Kọ ẹkún mi sílẹ̀;

kó omijé mi sí ìgò rẹ,

wọ́n kò ha sí nínú ìkọ̀sílẹ̀ rẹ bí?

9Nígbà náà ni àwọn ọ̀tá mi yóò pẹ̀yìndà

nígbà tí mo bá pè fún ìrànlọ́wọ́

nípa èyí ni mo mọ̀ pé Ọlọ́run ń bẹ fún mi.

10Nínú Ọlọ́run, ẹni tí mo yìn ọ̀rọ̀ rẹ̀

nínú Olúwa, ẹni tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀:

11Nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi:

ẹ̀rù kì yóò bà mí.

Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?

12Mo jẹ́ ẹ̀jẹ́ lábẹ́ rẹ Ọlọ́run:

èmi o mú ìyìn mi wá fún ọ.

13Nítorí ìwọ tí gbà mí lọ́wọ́ ikú

àti ẹsẹ̀ mi lọ́wọ́ ìṣubú,

kí èmí lè máa rìn níwájú Ọlọ́run

ní ìmọ́lẹ̀ àwọn alààyè.