시편 42 – KLB & YCB

Korean Living Bible

시편 42:1-11

제 2 권

(42-72)

하나님을 사모하는 영혼

(고라 자손의 교훈시. 성가대 지휘자를 따라 부른 노래)

1하나님이시여,

사슴이 시냇물을 갈망하듯이

내 영혼이 주를 갈망합니다.

2내 영혼이 살아 계신 하나님을

애타게 그리워하는데

내가 언제나 나아가서

하나님을 뵐 수 있을까?

3내가 밤낮 부르짖어

눈물이 내 음식이 되었으나

사람들은

“네 하나님이 어디 있느냐?”

하고 종일 나를 비웃는구나.

4내가 전에 기쁨의 찬송을 부르며

명절을 지키러 가는 군중들을

하나님의 집으로 곧잘 인도했는데

내가 지난 일을 생각하니

마음이 상하는구나.

5내 영혼아, 어째서 네가 낙심하며

내 속에서 불안해 하는가?

너는 네 희망을 하나님께 두어라.

나는 내 구원이 되시는

하나님을 찬양하리라.

6내 하나님이시여,

내 영혼이 내 속에서 낙심하므로

요단강이 흐르고

헤르몬산과 미살산이

우뚝 선 이 곳에서

내가 주를 기억합니다.

7주의 파도와 물결이 나를 엄습하고

슬픔의 홍수가 폭포같이

나에게 쏟아집니다.

8낮에는 여호와께서 나에게

한결같은 사랑을 베푸시니

밤에는 내가 그에게 찬송하고

내 생명의 하나님께 기도하리라.

9내가 나의 반석 되시는 하나님께

“어째서 나를 잊으셨습니까?

어째서 내가 내 원수들에게

이런 고통을

받아야 합니까?” 하나

10그들은 항상 나를 조롱하며

“네 하나님이 어디 있느냐?”

하고 말하니

내가 뼈에 사무치도록 괴롭구나.

11내 영혼아, 어째서 네가 낙심하며

내 속에서 불안해 하는가?

너는 네 희망을 하나님께 두어라.

나는 내 구원이 되시는

하나님을 찬양하리라.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 42:1-11

ÌWÉ KEJÌ

Saamu 42–72

Saamu 42

Fún adarí orin. Maskili ti àwọn ọmọ Kora.

1Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi,

bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.

2Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè.

Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?

3Oúnjẹ mi ni omijé mi

ní ọ̀sán àti ní òru,

nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́ pé,

“Ọlọ́run rẹ dà?”

4Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí,

èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi:

èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ,

èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́run

pẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn,

pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.

5Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?

Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?

Ìwọ ṣe ìrètí ní ti Ọlọ́run,

nítorí èmi yóò sá à máa yìn ín,

Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.

6Ọlọ́run mi, ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi:

nítorí náà, èmi ó rántí rẹ

láti ilẹ̀ Jordani wá,

láti Hermoni láti òkè Mibsari.

7Ibú omi ń pe ibú omi

nípa híhó omi ṣíṣàn rẹ̀

gbogbo rírú omi àti bíbì omi rẹ̀

bò mí mọ́lẹ̀.

8Ní ọ̀sán ní Olúwa ran ìfẹ́ rẹ̀,

àti ni àṣálẹ́ ni orin rẹ̀ wà pẹ̀lú mi

àdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.

9Èmi wí fún Ọlọ́run àpáta mi,

“Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi?

Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́,

nítorí ìnilára ọ̀tá?”

10Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tí

àwọn ọ̀tá mi ń gàn mí,

Bí wọn ti ń béèrè ní gbogbo ọjọ́.

“Níbo ni Ọlọ́run rẹ wà?”

11Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?

Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?

Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run,

nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun ni

Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.