伝道者の書 1 – JCB & YCB

Japanese Contemporary Bible

伝道者の書 1:1-18

1

すべてがむなしい

1ダビデ王の子で、エルサレムの王であり、「伝道者」と呼ばれたソロモンの教え。

2思うに、この世に価値のあるものなどない。

すべてがむなしい。

3-7人はあくせく働いた報酬として、

何を手に入れるというのか。

一つの時代が去り、新しい時代が来るが、

少しも変わらない。

太陽は昇っては沈み、また昇ろうと、

急ぎ元の所に帰って行く。

風は南に吹き、北に吹き、あちこち向きを変えるが、

結局行き着く所はない。

川は海に注ぐが、

海は決してあふれることはない。

水は再び川に戻り、また海に流れて行く。

8-11何もかも、くり返すばかりで、

あきあきする。

どれだけ見ていても満足できない。

どれだけ聞いても、

もうこれで良いということはない。

歴史はくり返すだけ。

ほんとうに新しいものなど何もない。

新しいように見えても、必ず前例があるか、すでに言い古されたものです。何か、「これは新しいものだ」と指摘できるものがあるでしょうか。それがずっと昔になかったと、どうしてわかるのですか。私たちは、先の時代にどんなことが起こったのか忘れてしまいます。そればかりか、のちの時代になれば、私たちが今していることを、だれも覚えていないのです。

知恵はむなしい

12-15伝道者である私はイスラエルの王で、エルサレムに住んでいました。私はこの世のあらゆることを理解しようと、全力を注ぎました。その結果、神が人間への分け前としてお与えになったものは、決して楽しいものでないことがわかりました。それはみな愚かに見え、風を追うようにむなしいものです。

間違ってしまったことは、もう正せない。

あったかもしれないものを考えてみたところで、

何の役に立とうか。

16-18私は自分に言い聞かせました。「私はこれまでのエルサレムのどの王より、いろんな勉強もした。どの王より知恵や知識を得た。」私は賢くなろうと、一生懸命に努力しました。しかし、今ではそんな努力さえ、風をつかまえるようにむなしいことだとわかったのです。

賢くなればなるほど、悲しみも増える。

知識を増すことは、悩みを増す。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Oniwaasu 1:1-18

Asán ni ohun ayé

1Ọ̀rọ̀ Oniwaasu, ọmọ Dafidi, ọba Jerusalẹmu:

2“Asán inú asán!”

oníwàásù náà wí pé,

“Asán inú asán!

Gbogbo rẹ̀ asán ni.”

3Kí ni ènìyàn rí jẹ ní èrè lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ̀,

lórí èyí tí ó ń ṣe wàhálà sí lábẹ́ oòrùn?

4Bí ìran kan ti wá ni ìran mìíràn ń kọjá lọ,

síbẹ̀ ayé dúró títí láé.

5Oòrùn ń ràn, oòrùn sì ń wọ̀,

ó sì sáré padà sí ibi tí ó ti yọ.

6Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ lọ sí ìhà gúúsù,

Ó sì ń fẹ́ yípo sí ìhà àríwá,

a sì tún padà sí ọ̀nà rẹ̀.

7Gbogbo odò ń sàn sí inú Òkun,

síbẹ̀síbẹ̀ Òkun kò kún.

Níbi tí àwọn odò ti wá,

níbẹ̀ ni wọ́n tún padà sí.

8Ohun gbogbo ni ó ń mú àárẹ̀ wá,

ju èyí tí ẹnu le è sọ.

Ojú kò tí ì rí ìrírí tí ó tẹ́ ẹ lọ́rùn,

bẹ́ẹ̀ ni, etí kò tí ì kún fún gbígbọ́.

9Ohun tí ó ti wà tẹ́lẹ̀ náà ni yóò sì máa wà, ohun tí a ti ṣe sẹ́yìn

òun ni a ó tún máa ṣe padà

kò sí ohun tuntun lábẹ́ oòrùn.

10Ǹjẹ́ ohun kan wà tí ẹnìkan le è sọ wí pé,

“Wò ó! Ohun tuntun ni èyí”?

Ó ti wà tẹ́lẹ̀ rí ní ọjọ́ tó ti pẹ́,

o ti wà ṣáájú tiwa.

11Kò sí ìrántí ohun ìṣáájú

bẹ́ẹ̀ ni ìrántí kì yóò sí fún

ohun ìkẹyìn tí ń bọ̀

lọ́dọ̀ àwọn tí ń bọ̀ ní ìgbà ìkẹyìn.

Asán ni ọgbọ́n ènìyàn

12Èmi, Oniwaasu ti jẹ ọba lórí Israẹli ní Jerusalẹmu rí. 13Mo fi àsìkò mi sílẹ̀ láti kọ́ àti láti ṣe àwárí pẹ̀lú ọgbọ́n, gbogbo ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ ọ̀run. Háà! Ẹrù wúwo tí Ọlọ́run ti gbé lé àwọn ènìyàn: 14Èmi ti rí ohun gbogbo tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn, gbogbo rẹ̀ kò ní ìtumọ̀ bí ẹní gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.

15Ohun tí ó ti wọ́ kò le è ṣe é tọ́ mọ́,

ohun tí kò sí kò le è ṣe é kà.

16Mo rò nínú ara mi, “Wò ó, mo ti dàgbà, ọgbọ́n mi sì ti pọ̀ ju ti ẹnikẹ́ni tí ó ti ṣe alákòóso Jerusalẹmu síwájú mi lọ, mo ti ní ìrírí púpọ̀ nípa ọgbọ́n àti ìmọ̀.” 17Nígbà náà ni mo fi ara jì láti ní ìmọ̀ nípa ọgbọ́n, àti pàápàá àìgbọ́n àti òmùgọ̀, ṣùgbọ́n mo rí, wí pé èyí pẹ̀lú bí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.

18Nítorí pé ọgbọ́n púpọ̀ ìbànújẹ́ púpọ̀ ní ń mú wá,

bí ìmọ̀ bá sì ṣe pọ̀ tó náà ni ìbànújẹ́ ń pọ̀ tó.