Maliro 1 – CCL & YCB

Mawu a Mulungu mu Chichewa Chalero

Maliro 1:1-22

1Haa! Mzinda uja wasiyidwa wokhawokha,

umene kale unali wodzaza ndi anthu!

Kale unali wotchuka pakati pa mitundu ya anthu!

Tsopano wasanduka ngati mkazi wamasiye.

Kale unali mfumukazi ya onse pa dziko lapansi,

tsopano wasanduka kapolo.

2Ukulira mowawidwa mtima usiku wonse,

misozi ili pa masaya pake.

Mwa abwenzi ake onse,

palibe ndi mmodzi yemwe womutonthoza.

Abwenzi ake onse amuchitira chiwembu;

onse akhala adani ake.

3Yuda watengedwa ku ukapolo,

kukazunzika ndi kukagwira ntchito yolemetsa.

Iye akukhala pakati pa anthu a mitundu ina;

ndipo alibe malo opumulira.

Onse omuthamangitsa iye amupitirira,

ndipo alibe kwina kothawira.

4Misewu yopita ku Ziyoni ikulira,

chifukwa palibe ndi mmodzi yemwe akubwera ku maphwando ake.

Zipata zake zonse zili pululu,

ansembe akubuwula.

Anamwali ake akulira,

ndipo ali mʼmasautso woopsa.

5Adani ake asanduka mabwana ake;

odana naye akupeza bwino.

Yehova wamubweretsera mavuto

chifukwa cha machimo ake ambiri.

Ana ake atengedwa ukapolo

pamaso pa mdani.

6Ulemerero wonse wa mwana wamkazi wa Ziyoni

wachokeratu.

Akalonga ake ali ngati mbawala

zosowa msipu;

alibe mphamvu zothawira

owathamangitsa.

7Pa masiku a masautso ndi kuzunzika kwake,

Yerusalemu amakumbukira chuma chonse

chimene mʼmasiku amakedzana chinali chake.

Anthu ake atagwidwa ndi adani ake,

panalibe aliyense womuthandiza.

Adani ake ankamuyangʼana

ndi kumuseka chifukwa cha kuwonongeka kwake.

8Yerusalemu wachimwa kwambiri

ndipo potero wakhala wodetsedwa.

Onse amene ankamulemekeza pano akumunyoza,

chifukwa aona umaliseche wake.

Iye mwini akubuwula

ndipo akubisa nkhope yake.

9Uve wake umaonekera pa zovala zake;

iye sanaganizire za tsogolo lake.

Nʼchifukwa chake kugwa kwake kunali kwakukulu;

ndipo analibe womutonthoza.

“Inu Yehova, taonani masautso anga,

pakuti mdani wapambana.”

10Adani amulanda

chuma chake chonse;

iye anaona mitundu ya anthu achikunja ikulowa mʼmalo ake opatulika,

amene Inu Mulungu munawaletsa

kulowa mu msonkhano wanu.

11Anthu ake onse akubuwula

pamene akufunafuna chakudya;

asinthanitsa chuma chawo ndi chakudya

kuti akhale ndi moyo.

“Inu Yehova, taonani ndipo ganizirani,

chifukwa ine ndanyozeka.”

12“Kodi zimenezi mukuziyesa zachabe, inu nonse mukudutsa?

Yangʼanani ndipo muone.

Kodi pali mavuto ofanana ndi

amene andigwerawa,

amene Ambuye anandibweretsera

pa tsiku la ukali wake?

13“Anatumiza moto kuchokera kumwamba,

unalowa mpaka mʼmafupa anga.

Anayala ukonde kuti ukole mapazi anga

ndipo anandibweza.

Anandisiya wopanda chilichonse,

wolefuka tsiku lonse.

14“Wazindikira machimo anga onse

ndipo ndi manja ake anawaluka pamodzi.

Machimowa afika pakhosi panga,

ndipo Ambuye wandithetsa mphamvu.

Iye wandipereka

kwa anthu amene sindingalimbane nawo.

15“Ambuye wakana

anthu anga onse amphamvu omwe ankakhala nane:

wasonkhanitsa gulu lankhondo kuti lilimbane nane,

kuti litekedze anyamata anga;

mʼmalo ofinyira mphesa Ambuye wapondereza

anamwali a Yuda.

16“Chifukwa cha zimenezi ndikulira

ndipo maso anga adzaza ndi misozi.

Palibe aliyense pafupi woti anditonthoze,

palibe aliyense wondilimbitsa mtima.

Ana anga ali okhaokha

chifukwa mdani watigonjetsa.

17“Ziyoni wakweza manja ake,

koma palibe aliyense womutonthoza.

Yehova walamula kuti abale ake

a Yakobo akhale adani ake;

Yerusalemu wasanduka

chinthu chodetsedwa pakati pawo.

18“Yehova ndi wolungama,

koma ndine ndinawukira malamulo ake.

Imvani inu anthu a mitundu yonse;

onani masautso anga.

Anyamata ndi anamwali anga

agwidwa ukapolo.

19“Ndinayitana abwenzi anga

koma anandinyenga.

Ansembe ndi akuluakulu anga

anafa mu mzinda

pamene ankafunafuna chakudya

kuti akhale ndi moyo.

20“Inu Yehova, onani mmene ine ndavutikira!

Ndikuzunzika mʼkati mwanga,

ndipo mu mtima mwanga ndasautsidwa

chifukwa ndakhala osamvera.

Mʼmisewu anthu akuphedwa,

ndipo ku mudzi kuli imfa yokhayokha.

21“Anthu amva kubuwula kwanga,

koma palibe wonditonthoza.

Adani anga onse amva masautso anga;

iwo akusangalala pa zimene Inu mwachita.

Lifikitseni tsiku limene munalonjeza lija

kuti iwonso adzakhale ngati ine.

22“Lolani kuti ntchito zawo zoyipa zifike pamaso panu;

muwalange

ngati mmene mwandilangira ine

chifukwa cha machimo anga onse.

Ndikubuwula kwambiri

ndipo mtima wanga walefuka.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ẹkun Jeremiah 1:1-22

1Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan,

nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn!

Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,

tí ó wà ní ipò opó,

Ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú

ni ó padà di ẹrú.

2Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò

pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀.

Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀

kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún.

Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀

wọ́n ti di alátakò rẹ̀.

3Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú,

Juda lọ sí àjò

Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,

ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi.

Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́

ibi tí kò ti le sá àsálà.

4Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀,

nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn.

Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro,

àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn,

àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú,

òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.

5Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀,

nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀,

Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́

nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú,

ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.

6Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé

kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni.

Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín

tí kò rí ewé tútù jẹ;

nínú àárẹ̀ wọ́n sáré

níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.

7Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni

Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀

tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́.

Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá,

kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un.

Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó

wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.

8Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀

ó sì ti di aláìmọ́.

Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀,

nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀;

ó kérora fúnrarẹ̀,

ó sì lọ kúrò.

9Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀,

Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu;

olùtùnú kò sì ṣí fún un.

“Wo ìpọ́njú mi, Olúwa,

nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”

10Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé

gbogbo ìní rẹ;

o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè

tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ—

àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀

láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.

11Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora

bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ;

wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ

láti mú wọn wà láààyè.

“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó,

nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”

12“Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín?

Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá,

Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà

tí a fi fún mi, ti

Olúwa mú wá fún mi

ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.

13“Ó rán iná láti òkè

sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi.

Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi,

ó sì yí mi padà.

Ó ti pa mí lára

mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.

14“Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà;

ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀.

Wọ́n ti yí ọrùn mi ká

Olúwa sì ti dín agbára mi kù.

Ó sì ti fi mí lé

àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.

15“Olúwa kọ

àwọn akọni mi sílẹ̀,

ó rán àwọn ológun lòdì sí mi

kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run.

Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́

àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.

16“Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún

tí omijé sì ń dà lójú mi,

Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi,

kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà.

Àwọn ọmọ mi di aláìní

nítorí ọ̀tá ti borí.”

17Sioni na ọwọ́ jáde,

ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un.

Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu

pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un

Jerusalẹmu ti di

ohun aláìmọ́ láàrín wọn.

18“Olóòtítọ́ ni Olúwa,

ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀.

Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn;

ẹ wò mí wò ìyà mi.

Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi

ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.

19“Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi

ṣùgbọ́n wọ́n dà mí.

Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi

ṣègbé sínú ìlú

nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ

tí yóò mú wọn wà láààyè.

20Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira!

Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi,

ìdààmú dé bá ọkàn mi

nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi.

Ní gbangba ni idà ń parun;

ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.

21“Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi,

ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi.

Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi;

wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe.

Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde,

kí wọ́n le dàbí tèmi.

22“Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ;

jẹ wọ́n ní yà

bí o ṣe jẹ mí ní yà

nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi.

Ìrora mi pọ̀

ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”