阿摩司書 9 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

阿摩司書 9:1-15

耶和華的審判

1我看見主站在祭壇旁,祂說:

「要擊打柱頂,使殿的根基震動;

要打碎柱頂,使殿宇坍塌壓死眾人。

僥倖生還的,我要用刀劍殺掉,

沒有一個能逃脫,沒有一個能倖免。

2即使他們挖洞鑽進陰間,

我也要把他們揪出來;

即使他們爬上高天,

我也要把他們拉下來;

3即使他們藏在迦密山的峰頂,

我也要去搜尋,捉住他們;

即使他們潛到海底,

我也要派海蛇去吞咬他們;

4即使他們被敵人擄去,

我也要命刀劍追殺他們。

我要定睛在他們身上,

不是要賜福而是要降禍。」

5主——萬軍之耶和華觸摸大地,

大地就消融,地上的人都要哀號;

大地如埃及尼羅河漲起退落。

6那位在天上建造樓閣,

在大地之上立定穹蒼,

召來海水澆在大地上的——

祂的名字是耶和華。

7耶和華說:

以色列人啊,

在我眼中,你們不是和古實人一樣嗎?

我不是領你們出埃及

也領非利士人出迦斐托9·7 迦斐托」即克里特島。

亞蘭人出吉珥嗎?

8主耶和華的眼目察看這罪惡的國家,

我要從地上除滅它,

但不會完全毀滅雅各家。

這是耶和華說的。

9「因為我要下令在列國中篩以色列家,

就像人篩穀物,一粒石子也不會落在地上。

10在我的子民中,

所有誇口說『災禍不會追上我們,也不會迎面而來』的罪人,

都要死在刀下。

以色列的復興

11「到那日,

我要重建已傾覆的大衛王朝,

修補它城牆的缺口。

我要從廢墟中重建它,

恢復它往日的榮耀。

12這樣,以色列人必擁有以東所剩的和所有屬於我名下的國家。

這是要成就這事的耶和華說的。」

13耶和華說:

「時候將到,

五穀還未收完又該耕種了,

葡萄還未踩完又該栽種了。

甜酒從群山上滴下,在丘嶺間流淌。

14我要使我被擄的以色列子民返回故鄉,

他們要重建廢城並住在城中,

栽種葡萄園,喝園中釀出的美酒,

整理園圃,吃園中出產的佳果。

15我要將以色列人栽種在他們自己的土地上,

永不再從我賜給他們的土地上拔除他們。」

這是你們的上帝耶和華說的。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 9:1-15

A o pa Israẹli run

1Mo rí Olúwa, ó dúró ní ẹ̀bá pẹpẹ, ó sì wí pé:

“Lu orí àwọn àtẹ́rígbà ìlẹ̀kùn

kí àwọn òpó kí ó lè mì

fọ́ wọn sí orí àwọn gbogbo ènìyàn

àwọn tí ó ṣẹ́kù ni èmi yóò fi idà pa,

Ẹni tí ó sálọ nínú wọn kí yóò sá gbé

Ẹni ti ó sá àsálà nínú wọn kí yóò gbàlà.

2Bí wọ́n tilẹ̀ wa ilẹ̀ lọ sí ipò òkú

Láti ibẹ̀ ni ọwọ́ mi yóò ti tẹ̀ wọ́n

Bí wọ́n tilẹ̀ gun òkè ọ̀run lọ,

láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú wọn sọ̀kalẹ̀.

3Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Karmeli,

èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀.

Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìsàlẹ̀ Òkun,

láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.

4Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọn

láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa.

“Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí,

kì í sì í ṣe fún rere.”

5Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,

ẹni ti ó fi ọwọ́ kan ilẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì ṣọ̀fọ̀;

gbogbo orílẹ̀-èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Naili

tiwọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Ejibiti.

6Òun ni ẹni tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run

ti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayé

Ẹni ti ó pe àwọn omi Òkun

ti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé

Olúwa ni orúkọ rẹ̀.

7“Àbá ẹ̀yin ọmọ Israẹli

kò ha dàbí àwọn ọmọ Kuṣi sí mi?”

ni Olúwa wí.

“Èmi kò ha ti mú Israẹli gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá

àti àwọn Filistini láti ilẹ̀ Kafitori

àti àwọn ará Aramu láti Kiri?

8“Dájúdájú, ojú Olúwa Olódùmarè

ń bẹ̀ lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀.

Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀

Síbẹ̀ Èmi kò nípa ilé Jakọbu run pátápátá,”

ni Olúwa wí.

9“Nítorí Èmi yóò pàṣẹ,

Èmi yóò sì mi ilé Israẹli

ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè

bí a ti ń jọ nǹkan nínú ajọ̀

tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.

10Gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn mi

ni yóò ti ipa idà kú

gbogbo àwọn ti ń wí pé,

‘Aburú kì yóò lé wa bá, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́.’

Ìmúpadàbọ̀ Israẹli

119.11-12: Ap 15.16-17.“Ní ọjọ́ náà ní

Èmi yóò gbé àgọ́ Dafidi tí ó wó ró,

Èmi yóò dí odi rẹ̀ tí ó ya,

Èmi yóò sì gbé ahoro rẹ̀ sókè,

Èmi yóò sì kọ bí ti ọjọ́ ìgbàanì,

12kí wọn le jogún ìyókù Edomu

àti gbogbo àwọn kèfèrí, ti a ń pè nípa orúkọ mi,”

ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.

139.13: Jl 3.18.“Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí,

“tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè bá

Tí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn bá

Àwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀

Tí yóò sì sàn láti ara àwọn òkè kéékèèkéé.

14Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Israẹli ènìyàn mi padà bọ̀.

“Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọn

Wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọn

wọn yóò sì ṣe ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn

15Èmi yóò gbin Israẹli sí orí ilẹ̀ rẹ̀.

A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláé

kúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,”

ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.