詩篇 44 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

詩篇 44:1-26

第 44 篇

祈求上帝保護

可拉後裔作的訓誨詩,交給樂長。

1上帝啊,

我們親耳聽過祖先講述你在古時,

在我們祖先時代的作為。

2你親手趕出外族,

把我們的祖先安置在那裡;

你擊潰列邦,

使我們的祖先興旺發達。

3他們不是靠自己的刀劍征服那裡,

不是靠自己的臂膀得勝,

而是靠你的權能、力量和恩惠,

因為你愛他們。

4你是我的君王,我的上帝;

你讓雅各得勝。

5我們靠你擊退敵人,

靠你的名踐踏仇敵。

6我不倚靠我的弓,

我的劍不能使我得勝。

7只有你使我們戰勝敵人,

使我們的仇敵蒙羞。

8上帝啊,我們終日以你為榮,

我們永遠讚美你。(細拉)

9現在你卻丟棄我們,

讓我們受辱,

不再幫我們的軍隊作戰。

10你使我們在仇敵面前敗退,

遭敵人擄掠。

11你使我們如被宰殺的羊,

將我們分散在列國。

12你把我們廉價賣掉,

視我們一文不值。

13你使我們遭四鄰辱罵,

被周圍人譏諷、嘲笑。

14你使我們成為列國的笑柄,

人們對我們連連搖頭。

15我終日受辱,滿面羞愧,

16因為咒罵和譭謗我的人譏笑我,仇敵報復我。

17雖然這一切臨到我們身上,

我們卻沒有忘記你,

也沒有違背你的約。

18我們對你沒有異心,

也沒有偏離你的道路。

19你在豺狼出沒的地方壓碎我們,

使死亡的陰影籠罩我們。

20倘若我們忘記我們的上帝,

或舉手向外邦的神明禱告,

21上帝怎會不知道呢?

祂洞悉人心中的秘密。

22為了你,我們終日出生入死,

被視為待宰的羊。

23主啊,求你醒來,

你為何沉睡?

求你起來,不要永遠丟棄我們。

24你為何掩面不理我們,

不理會我們所受的苦難和壓迫?

25我們仆倒在地,橫臥在塵土中。

26求你起來幫助我們,

施慈愛救贖我們。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 44:1-26

Saamu 44

Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Maskili.

1À ti fi etí wa gbọ́, Ọlọ́run

àwọn baba wa tí sọ fún wa

ohun tí ìwọ ṣe ní ọjọ́ wọn,

ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn.

2Ìwọ fi ọwọ́ rẹ lé orílẹ̀-èdè jáde

Ìwọ sì gbin àwọn baba wa;

Ìwọ run àwọn ènìyàn náà

Ìwọ sì mú àwọn baba wa gbilẹ̀.

3Kì í ṣe nípa idà wọn ni wọ́n gba ilẹ̀ náà,

bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe apá wọn ní ó gbà wọ́n bí kò ṣe;

ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti, apá rẹ;

àti ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ̀, nítorí ìwọ fẹ́ wọn.

4Ìwọ ni ọba àti Ọlọ́run mi,

ẹni tí ó pàṣẹ ìṣẹ́gun fún Jakọbu.

5Nípasẹ̀ rẹ ni àwa ó bi àwọn ọ̀tá wa ṣubú;

nípasẹ̀ orúkọ rẹ ni àwa ó tẹ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wa mọ́lẹ̀

6Èmi kì yóò gbẹ́kẹ̀lé ọrun mi

idà mi kì yóò mú ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wá,

7Ṣùgbọ́n ìwọ fún wa ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wa,

ìwọ sì ti dójúti àwọn tí ó kórìíra wa.

8Nínú Ọlọ́run àwa ń ṣògo ní gbogbo ọjọ́,

àwa ó sì yin orúkọ rẹ títí láé. Sela.

9Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ ti kọ̀ wá, ìwọ sì ti dójútì wá;

Ìwọ kò sì bá àwọn ọmọ-ogun wa jáde mọ́.

10Ìwọ ti bá wa jà,

ìwọ sì ti ṣẹ́gun wa níwájú àwọn ọ̀tá wa,

àwọn ọ̀tá wa ti gba ilẹ̀ wa,

wọ́n sì fi ipá gba oko wa.

11Ìwọ fi wá fún jíjẹ bí ẹran àgùntàn

Ìwọ sì ti tú wa ká sí àárín àwọn kèfèrí.

12Ìwọ ta àwọn ènìyàn rẹ fún owó kékeré,

Ìwọ kò sì jẹ èrè kankan lórí iye tí ìwọ tà wọ́n.

13Ìwọ sọ wá di ẹni ẹ̀sín ní ọ̀dọ̀ àwọn aládùúgbò wa,

ẹlẹ́yà àti ẹni àbùkù sí àwọn tí ó yí wa ká.

14Ìwọ ti sọ wá di ẹni ìfisọ̀rọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè;

àwọn ènìyàn ń mi orí wọn sí wa.

15Ìdójútì mi ń bẹ pẹ̀lú mi ní gbogbo ọjọ́,

ìtìjú sì bojú mi mọ́lẹ̀,

16nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn

ní ojú àwọn ọ̀tá àti olùgbẹ̀san.

17Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ń ṣẹlẹ̀ sí wa,

síbẹ̀ àwa kò gbàgbé rẹ

bẹ́ẹ̀ ni a kò ṣèké sí májẹ̀mú rẹ̀.

18Ọkàn wa kò padà sẹ́yìn;

bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wa kò yẹ̀ kúrò ní ọ̀nà rẹ̀.

19Ṣùgbọ́n wọ́n kọlù wá,

ìwọ sì sọ wá di ẹran ọdẹ fún àwọn ẹranko búburú,

tí wọn sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.

20Bí àwa bá ti gbàgbé orúkọ Ọlọ́run wa

tàbí tí a na ọwọ́ wa sí ọlọ́run àjèjì.

21Ǹjẹ́ Ọlọ́run kì yóò rí ìdí rẹ̀,

níwọ̀n ìgbà tí ó mọ ohun ìkọ̀kọ̀ inú ọkàn?

2244.22: Ro 8.36.Síbẹ̀, nítorí rẹ̀ àwa da àyà kọ ikú, ní ojoojúmọ́

a ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.

23Jí, Olúwa! Èéṣe tí ìwọ ń sùn?

Dìde fúnrarẹ̀! Má ṣe kọ̀ wá sílẹ̀ láéláé.

24Èéṣe tí ìwọ ń pa ojú rẹ mọ́

tí ìwọ sì gbàgbé ìpọ́njú àti ìnira wa?

25Nítorí a tẹrí ọkàn wa ba sínú eruku;

ara wa sì dì mọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀.

26Dìde kí o sì ràn wá lọ́wọ́;

rà wá padà nítorí ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.