詩篇 42 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

詩篇 42:1-11

卷二:詩篇42—72

第 42 篇

流落異鄉者的禱告

可拉後裔作的訓誨詩,交給樂長。

1上帝啊,我的心切慕你,

像鹿切慕溪水。

2我心裡渴慕上帝,

渴慕永活的上帝,

我何時才能去朝拜祂呢?

3我不吃不喝,晝夜以淚洗面,

人們整天譏笑我:

「你的上帝在哪裡?」

4從前我帶領眾人浩浩蕩蕩去上帝的殿,

在歡呼、感恩聲中一起過節。

我回想這些事,

心中無限憂傷。

5我的心啊!

你為何沮喪?為何煩躁?

要仰望上帝,

因為我還要讚美祂——我的救主,我的上帝。

6我的上帝啊,我心中沮喪,

便在約旦河、黑門山和米薩山想起你。

7你的瀑布發出巨響,

迴盪在深淵之間,

你的洪濤巨浪淹沒我。

8白天耶和華將祂的慈愛澆灌我;

夜間我歌頌祂,

向賜我生命的上帝禱告。

9我對上帝——我的磐石說:

「你為何忘記我?

為何要我受仇敵的攻擊,使我哀傷不已呢?」

10仇敵的辱罵刺骨鑽心。

他們整天對我說:

「你的上帝在哪裡?」

11我的心啊!

你為何沮喪?為何煩躁?

要仰望上帝,

因為我還要讚美祂——我的救主,我的上帝。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 42:1-11

ÌWÉ KEJÌ

Saamu 42–72

Saamu 42

Fún adarí orin. Maskili ti àwọn ọmọ Kora.

1Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi,

bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.

2Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè.

Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?

3Oúnjẹ mi ni omijé mi

ní ọ̀sán àti ní òru,

nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́ pé,

“Ọlọ́run rẹ dà?”

4Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí,

èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi:

èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ,

èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́run

pẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn,

pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.

5Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?

Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?

Ìwọ ṣe ìrètí ní ti Ọlọ́run,

nítorí èmi yóò sá à máa yìn ín,

Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.

6Ọlọ́run mi, ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi:

nítorí náà, èmi ó rántí rẹ

láti ilẹ̀ Jordani wá,

láti Hermoni láti òkè Mibsari.

7Ibú omi ń pe ibú omi

nípa híhó omi ṣíṣàn rẹ̀

gbogbo rírú omi àti bíbì omi rẹ̀

bò mí mọ́lẹ̀.

8Ní ọ̀sán ní Olúwa ran ìfẹ́ rẹ̀,

àti ni àṣálẹ́ ni orin rẹ̀ wà pẹ̀lú mi

àdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.

9Èmi wí fún Ọlọ́run àpáta mi,

“Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi?

Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́,

nítorí ìnilára ọ̀tá?”

10Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tí

àwọn ọ̀tá mi ń gàn mí,

Bí wọn ti ń béèrè ní gbogbo ọjọ́.

“Níbo ni Ọlọ́run rẹ wà?”

11Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi?

Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi?

Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run,

nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun ni

Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.