耶利米書 39 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

耶利米書 39:1-18

耶路撒冷淪陷

1猶大西底迦執政第九年十月,巴比倫尼布甲尼撒率領全軍包圍耶路撒冷2西底迦執政第十一年四月九日,耶路撒冷淪陷。 3尼甲·沙利薛三甲·尼波撒西金和另一個尼甲·沙利薛巴比倫王的所有將領都進城坐在中門。 4猶大西底迦和所有軍兵見勢不妙,便在夜間穿過御花園,從兩城牆中間的門逃往亞拉巴5迦勒底的軍隊追上來,在耶利哥的平原擒住西底迦,把他帶到哈馬利比拉去見巴比倫尼布甲尼撒,接受審判。 6巴比倫王在利比拉當著西底迦的面殺了他的眾子和猶大所有的貴族, 7並且挖去他的雙眼,把他用銅鏈鎖著帶到巴比倫8迦勒底人放火焚燒王宮和民居,拆毀耶路撒冷的城牆。 9護衛長尼布撒拉旦把城中的餘民以及投降的人都擄到巴比倫10卻讓那些一貧如洗的窮人留在猶大,將葡萄園和田地分給他們。

耶利米獲釋

11至於耶利米巴比倫尼布甲尼撒吩咐護衛長尼布撒拉旦12「你好好照顧耶利米,切不可傷害他。他有什麼要求,你都要滿足。」 13於是,護衛長尼布撒拉旦尼布沙斯班尼甲·沙利薛巴比倫王的所有將領, 14便派人把耶利米從護衛兵的院子提出來,讓沙番的孫子、亞希甘的兒子基大利帶他回家。從此,耶利米就生活在百姓當中。

15耶利米被監禁在護衛兵院子裡的時候,耶和華對他說: 16「你去告訴古實以伯·米勒以色列的上帝——萬軍之耶和華說,『看啊,我必照我說的使這城遭受災禍,得不到祝福。你必親眼看見這一切發生。』 17耶和華說,『但那時,我必拯救你,使你不致落在你所懼怕的人手中。 18我必拯救你,使你保全性命,不致喪身刀下,因為你信靠我。這是耶和華說的。』」

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 39:1-18

Ìṣubú Jerusalẹmu

1Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í. 2Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà. 3Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú. 4Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.

5Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀. 6Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda. 7Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.

8Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu. 9Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú. 10Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.

11Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé: 12“Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.” 13Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli, 14ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.

15Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé: 16“Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ. 17Ṣùgbọ́n Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù. 18Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’ ”