耶利米書 37 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

耶利米書 37:1-21

西底迦求耶利米代禱

1巴比倫尼布甲尼撒約西亞的兒子西底迦代替約雅敬的兒子哥尼雅做猶大王。 2西底迦和他的臣僕及人民卻沒有聽從耶和華藉耶利米先知說的話。 3西底迦王派示利米雅的兒子猶甲瑪西雅的兒子祭司西番雅來對耶利米先知說:「求你為我們向我們的上帝耶和華禱告。」 4當時,耶利米還可以自由來往,沒有被他們囚在獄中。 5那時,法老的軍隊已從埃及出發,正在圍攻耶路撒冷迦勒底人聽見消息就退兵了。

6耶和華對耶利米先知說: 7「這是以色列的上帝耶和華的話,『猶大王派你們來求問我,你們告訴他,前來支援你們的法老軍隊必中途返回埃及8迦勒底人必捲土重來,攻佔這城,將它付之一炬。 9耶和華說,你們不要自欺,以為迦勒底人必撤軍。其實他們不會撤軍。 10即使你們能打敗迦勒底全軍,他們營中受傷的殘兵也必起來燒毀這城。』」

11迦勒底人因害怕法老的軍隊而撤軍的時候, 12耶利米起身離開耶路撒冷,前往便雅憫境內去接收他在同族中應得的地業。 13耶利米先知來到便雅憫門時,哈拿尼亞的孫子、示利米雅的兒子守門官伊利雅逮捕了他,說:「你想去投奔迦勒底人!」 14耶利米說:「不,我不是去投奔迦勒底人。」但伊利雅不信,把他押到眾官長那裡。 15官長們大怒,命人鞭打耶利米,把他囚禁在書記約拿單的房子裡,因為他們已把這房子改作監牢。 16耶利米被囚禁在地牢中許多天。

17後來,西底迦王派人把他帶到自己的宮中,私下問他:「耶和華有什麼話給你嗎?」耶利米說:「有,你要被交在巴比倫王手中。」 18耶利米又問他:「我在什麼事上得罪了你、你的臣僕或人民,以致你們把我囚在監牢中? 19那些曾向你們預言『巴比倫王絕不會來這裡攻打你們』的先知如今在哪裡呢? 20現在,我主我王啊,請聽我說!求你不要把我送回書記約拿單的房子,免得我死在那裡。」

21於是,西底迦王下令把耶利米囚在護衛兵的院子裡,派人每天從餅鋪取一個餅給他,直到城中絕糧。耶利米就這樣住在護衛兵的院子裡。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 37:1-21

Jeremiah nínú túbú

1Sedekiah ọmọ Josiah sì jẹ ọba ní ipò Jehoiakini ọmọ Jehoiakimu ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli fi jẹ ọba ní ilẹ̀ Juda. 2Ṣùgbọ́n àti òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kò fetísí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípa wòlíì Jeremiah.

3Sedekiah ọba sì rán Jehukali ọmọ Ṣelemiah àti Sefaniah ọmọ Maaseiah sí Jeremiah wòlíì wí pé, “Jọ̀wọ́ gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”

4Nígbà yìí Jeremiah sì ń wọlé, ó sì ń jáde láàrín àwọn ènìyàn nítorí wọ́n ti fi sínú túbú. 5Àwọn ọmọ-ogun Farao ti jáde kúrò nílẹ̀ Ejibiti àti nígbà tí àwọn ará Babeli tó ń ṣàtìpó ní Jerusalẹmu gbọ́ ìròyìn nípa wọn, wọ́n kúrò ní Jerusalẹmu.

6Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì Ọlọ́run wá: 7“Èyí ni, ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ fún ọba àwọn Juda tó rán ọ láti wádìí nípa mi. ‘Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáde láti kún ọ lọ́wọ́ yóò padà sílẹ̀ wọn sí Ejibiti. 8Nígbà náà ni àwọn ará Babeli yóò padà láti gbógun ti ìlú. Wọn yóò mú wọn nígbèkùn, wọn yóò sì fi iná jó ìlú náà kanlẹ̀.’

9“Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Ẹ má ṣe tan ara yín jẹ ní èrò wí pé, ‘Àwọn ará Babeli yóò fi wá sílẹ̀ pẹ̀lú ìdánilójú;’ wọn kò ní ṣe bẹ́ẹ̀. 10Kódà tó bá ṣe pé wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọmọ-ogun Babeli tí ń gbóguntì yín àti àwọn tí ìjàǹbá ṣe, tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ibùdó wọn; wọn yóò jáde láti jó ìlú náà kanlẹ̀.”

11Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ-ogun Babeli ti kúrò ní Jerusalẹmu nítorí àwọn ọmọ-ogun Farao. 12Jeremiah múra láti fi ìlú náà sílẹ̀, láti lọ sí olú ìlú Benjamini láti gba ẹ̀tọ́ rẹ̀ nínú ohun ìní láàrín àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀. 13Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ẹnu ibodè Benjamini, olórí àwọn olùṣọ́ tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Irijah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Hananiah mú un, ó wí pé, “Ìwọ ń fi ara mọ́ àwọn ará Babeli.”

14Jeremiah sọ wí pé, “Èyí kì í ṣe òtítọ́! Èmi kò yapa sí àwọn ará Babeli.” Ṣùgbọ́n Irijah ko gbọ́ tirẹ̀, dípò èyí a mú Jeremiah, ó sì mú un lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ìjòyè. 15Nítorí náà ni àwọn ìjòyè ṣe bínú sí Jeremiah, wọ́n jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n tún fi sí túbú nílé Jonatani akọ̀wé nítorí wọ́n ti fi èyí ṣe ilé túbú.

16Wọ́n fi Jeremiah sínú túbú tí ó ṣókùnkùn biribiri; níbi tí ó wà fún ìgbà pípẹ́. 17Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ sí i, tí ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n mú wá sí ààfin níbi tí ó ti bi í ní ìkọ̀kọ̀ pé, “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ kan wà láti ọ̀dọ̀ Olúwa?”

“Bẹ́ẹ̀ ni,” Jeremiah fèsì pé, “wọn ó fi ọ́ lé ọwọ́ ọba Babeli.”

18Nígbà náà, Jeremiah sọ fún ọba Sedekiah pé, “Irú ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ yín, àwọn ìjòyè yín pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ẹ fi sọ mí sínú túbú? 19Níbo ni àwọn wòlíì yín tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín wí pé ọba Babeli kò ní gbóguntì yín wá? 20Ṣùgbọ́n ní báyìí, olúwa mi ọba, èmí bẹ̀ ọ. Jẹ́ kí n mú ẹ̀dùn ọkàn mi tọ̀ ọ́ wá; má ṣe rán mi padà sí ilé Jonatani akọ̀wé, àfi kí n kú síbẹ̀.”

21Ọba Sedekiah wá pàṣẹ pé kí wọ́n fi Jeremiah sínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́, àti kí wọn sì fún ní àkàrà ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan títí tí àkàrà tó wà ní ìlú yóò fi tán; bẹ́ẹ̀ ni Jeremiah wà nínú àgbàlá náà.