耶利米書 21 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

耶利米書 21:1-14

預言耶路撒冷的淪陷

1西底迦王派瑪基雅的兒子巴施戶珥瑪西雅的兒子西番雅祭司來見耶利米的時候,耶利米聽到了耶和華的話。當時,他們對耶利米說: 2「請你為我們求問耶和華,因為巴比倫尼布甲尼撒來攻打我們,或許耶和華會像以往一樣行神蹟,使敵人撤軍。」

3耶利米對他們說:「你們要告訴西底迦4以色列的上帝耶和華說,『看啊,你們與圍城的巴比倫王及其率領的迦勒底人作戰,我要把你們的兵器掉轉過來,我要把它們收集在城中心。 5我要在烈怒中伸出大能的臂膀下手擊打你們, 6我要擊打這城裡的居民和牲畜,使他們死於瘟疫。 7然後,我要把猶大西底迦及其臣僕以及城中逃過瘟疫、戰爭和饑荒的人都交給巴比倫尼布甲尼撒等仇敵,使他們落在想殺滅他們的人手中。巴比倫王必殘酷無情地殺戮他們。這是耶和華說的。』

8耶利米啊,你要告訴百姓,『耶和華說,看啊,我把生命之路和死亡之路擺在你們面前, 9留在這城裡的必死於戰爭、饑荒和瘟疫,出城向迦勒底人投降的必保全性命、逃過一死。 10我必嚴懲這城,向它降禍不降福。它必落在巴比倫王手中,被付之一炬。這是耶和華說的。』

11「你要對猶大的王室說,『你們要聽耶和華的話。 12大衛家啊,耶和華說,

『你們要天天秉公行義,

從壓迫者手中解救受剝削的人,

免得你們的惡行激起我的怒火,

如烈焰燃起,無人能滅。

13耶和華說,耶路撒冷啊,

你座落在山谷之上,

如平原的磐石,

自以為無人能攻擊你,

無人能闖入你的住處。

但我要攻擊你,

14照你的所作所為懲罰你;

我要點燃你的樹林,

燒光你周圍的一切。

這是耶和華說的。』」

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 21:1-14

Ọlọ́run kọ ìbéèrè Sedekiah sílẹ̀

1Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé: 2“Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”

3Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah, 4‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí. 5Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle. 6Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú. 7Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’

8“Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín. 9Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀. 10Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’

11“Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. 12Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ:

“ ‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀;

yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára

ẹni tí a ti jà lólè

bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná.

Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó

láìsí ẹni tí yóò pa á.

13Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu

ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì

lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí.

Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá?

Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”

14Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀

ni Olúwa wí.

Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀;

yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’ ”