箴言 31 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

箴言 31:1-31

利慕伊勒王的箴言

1以下是利慕伊勒王的箴言,

是他母親給他的教誨:

2我兒,我親生的骨肉,

我許願得來的孩子啊,

我該怎樣教導你呢?

3不要在女人身上耗費精力,

不要迷戀那些能毀滅王的人。

4利慕伊勒啊,

君王不可喝酒,

不可喝酒,

首領不宜喝烈酒,

5免得喝酒後忘記律例,

不為困苦人伸張正義。

6把烈酒給滅亡的人,

把淡酒給憂傷的人,

7讓他們喝了忘掉貧窮,

不再記得自己的痛苦。

8要為不能自辯者說話,

為一切不幸的人伸冤。

9你要發言,秉公審判,

為貧窮困苦者主持公道。

賢德的妻子

10誰能找到賢德之妻?

她的價值遠勝過珠寶。

11她丈夫信賴她,

什麼也不缺乏。

12她一生對丈夫有益無損。

13她尋找羊毛和細麻,

愉快地親手做衣。

14她好像商船,

從遠方運來糧食。

15天未亮她就起床,

為全家預備食物,

分派女僕做家事。

16她選中田地便買下來,

親手賺錢栽種葡萄園。

17她精力充沛,

雙臂有力。

18她深諳經營之道,

她的燈徹夜不熄。

19她手拿捲線杆,

手握紡線錘。

20她樂於賙濟窮人,

伸手幫助困苦者。

21她不因下雪而為家人擔心,

因為全家都穿著朱紅暖衣。

22她為自己縫製繡花毯,

用細麻和紫布做衣服。

23她丈夫在城門口與當地長老同坐,

受人尊重。

24她縫製細麻衣裳出售,

又製作腰帶賣給商人。

25她充滿力量和尊榮,

她以笑顏迎接未來。

26她說的話帶著智慧,

她的訓言充滿慈愛。

27她料理一切家務,

從不偷懶吃閒飯。

28她的兒女肅立,

為她祝福,

她的丈夫也稱讚她,

29說:「世上賢德的女子很多,

唯有你無與倫比。」

30豔麗是虛假的,

美貌是短暫的,

唯有敬畏耶和華的女子配得稱讚。

31願她享受自己的勞動成果,

願她的事蹟使她在城門口受稱讚。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 31:1-31

1Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba,

ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ.

2“Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi!

Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.

3Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,

okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.

4“Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli

kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì

kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle

5Kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí

kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n

6Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé

wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora;

7Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn

kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.

8“Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnrawọn

fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun

9Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè

jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”

10Ta ni ó le rí aya oníwà rere?

Ó níye lórí ju iyùn lọ

11Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀

kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.

12Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi

ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

13Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀

Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.

14Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò;

ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn

15Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn;

ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀

àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.

16Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á;

nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀

17Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára

apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́

18Ó rí i pé òwò òun pé

fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru

19Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú

ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú

20O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà

ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.

21Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀

nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.

22Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;

ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀

23A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú

níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú

24Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n

ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò

25Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ

ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.

26A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n

ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀

27Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀

kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́

28Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún

ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un

29“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá

ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ”

30Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán

nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn

31Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i

kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.