箴言 16 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

箴言 16:1-33

1心中的策劃在於人,

應對之言來自耶和華。

2人看自己的行為都純全,

但是耶和華卻衡量人心。

3把你的事交托耶和華,

你的計劃必實現。

4耶和華所造的萬物各有其用,

連惡人也是為災難之日所造。

5耶和華厭惡心驕氣傲者,

他們必逃不過祂的責罰。

6慈愛和忠信可讓罪惡得贖,

敬畏耶和華使人遠離罪惡。

7人所行的若蒙耶和華喜悅,

耶和華必使仇敵與他和好。

8財物雖少但行事公義,

勝過家財萬貫卻不公義。

9人心中籌畫自己的道路,

但耶和華決定他的腳步。

10王口中有上帝的話,

斷案時必無差錯。

11公道的秤與天平屬於耶和華,

袋中一切的法碼由祂制定。

12君王憎恨惡行,

因王位靠公義而立。

13王喜愛公義的言詞,

器重說話正直的人。

14王的烈怒如死亡使者,

然而智者能平息王怒。

15王的笑容帶給人生命,

他的恩惠像春雨之雲。

16得智慧勝過得黃金,

獲悟性勝過獲白銀。

17正直人的大道遠離罪惡,

堅守正道的保全性命。

18驕橫是淪亡的前奏,

狂傲是敗落的預兆。

19寧可謙卑地與貧寒人相處,

也不跟狂傲人共享戰利品。

20聽從訓言的人受益匪淺,

信靠耶和華的人蒙祝福。

21智者以明辨著稱,

甜言能說服人心。

22智慧是智者的生命泉,

愚昧為愚人帶來懲罰。

23智者三思而後言,

其言使人長見識。

24良言如蜜,

使人心靈甘甜、身體康健。

25有一條路看似正確,

最終卻通向死亡。

26工人的胃口促他工作,

口腹之需是他的動力。

27不務正業的人圖謀惡事,

他的口舌如烈焰般危險。

28邪僻的人散播紛爭,

造謠的人破壞友情。

29殘暴之徒引誘鄰舍走入歧途。

30惡人眯起眼睛圖謀不軌,

歹徒咬著嘴唇策劃惡事。

31白髮是榮耀的冠冕,

行為公義方能得到。

32不輕易發怒者勝過勇士,

能自我控制勝過攻陷城池。

33人可以搖籤求問,

但耶和華決定一切。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 16:1-33

1Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn

ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.

2Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀

ṣùgbọ́n Olúwa ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.

3Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé Olúwa lọ́wọ́

Èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.

4Olúwa ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́

kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.

5Olúwa kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀

mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.

6Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀

nípasẹ̀ ìbẹ̀rù Olúwa ènìyàn sá fún ibi.

7Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ Olúwa lọ́rùn,

yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.

8Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo

ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ.

9Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀

ṣùgbọ́n Olúwa ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.

10Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i

ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké.

11Òdínwọ̀n àti òṣùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa;

gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.

12Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́

nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.

13Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́,

wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́.

14Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́

ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.

15Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè;

ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.

16Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ

àti láti yan òye dípò o fàdákà!

17Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi,

ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.

18Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun,

agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú.

19Ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrín àwọn olùpọ́njú

jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.

20Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ìre,

ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.

21Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye

ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.

22Òye jẹ́ orísun ìyè fún àwọn tí ó ní i,

ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.

23Ọkàn ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀

ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ dàgbà.

24Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin

ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.

25Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn

ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.

26Ọkàn alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún ara rẹ̀;

nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ lọ.

27Ènìyàn búburú ń pète

ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.

28Aláyídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀

olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn ní yà.

29Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀

ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.

30Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte;

ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.

31Adé ògo ni ewú orí jẹ́,

ìgbé ayé òdodo ní í mú ni dé bẹ̀.

32Ó sàn láti jẹ́ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ,

ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun ṣẹ́gun ìlú lọ.

33A ṣẹ́ kèké si ìṣẹ́po aṣọ,

ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.