歷代志上 13 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

歷代志上 13:1-14

運回約櫃

1大衛跟千夫長、百夫長等所有的首領商議, 2然後對以色列全體會眾說:「如果你們贊成,而且這是我們上帝耶和華的旨意,我們就派人到以色列各地把其他同胞,包括住在城邑及草場的祭司和利未人召集來。 3我們要將我們上帝的約櫃運到這裡來,因為在掃羅執政期間,我們忽視了它。」 4會眾都表示贊同,認為這樣做很好。

5於是,大衛召集了從埃及西曷河一直到哈馬口的全體以色列人,要將上帝的約櫃從基列·耶琳運來。 6大衛率領以色列眾人到巴拉,即猶大基列·耶琳,要將上帝的約櫃運回來。這約櫃以坐在基路伯天使上面的耶和華的名字命名。 7他們把上帝的約櫃從亞比拿達家抬出來,放在一輛新車上,由烏撒亞希約趕車。 8大衛以色列眾人就在上帝面前用琴、瑟、鼓、鈸和號奏樂,盡情歌舞。 9他們來到基頓麥場的時候,拉車的牛失蹄,烏撒就伸手去扶約櫃。 10因他伸手碰了約櫃,上帝便向他發怒,擊殺了他,他就死在上帝面前。 11大衛因耶和華擊殺烏撒而煩惱,就稱那地方為毗列斯·烏撒13·11 毗列斯·烏撒」意思是「向烏撒發怒」。,沿用至今。 12那天,大衛懼怕上帝,他說:「我怎能將上帝的約櫃運到我這裡?」 13因此,大衛沒有將約櫃運到大衛城,而是把它運到迦特俄別·以東家。 14上帝的約櫃在俄別·以東家存放了三個月。耶和華使俄別·以東家及其擁有的一切都蒙福。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Kronika 13:1-14

Gbígbé padà àpótí ẹ̀rí

113.1-14: 2Sa 6.1-11.Dafidi sì gbèrò pẹ̀lú olúkúlùkù àwọn ìjòyè rẹ̀, àwọn aláṣẹ ẹgbẹgbẹ̀rún àti àwọn aláṣẹ ọgọ́rùn-ún 2Dafidi sì wí fún gbogbo àwọn ìjọ Israẹli pé, Tí ó bá dára lójú yín àti tí ó bá ṣe jẹ́ àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa, jẹ́ kí a ránṣẹ́ sí ọ̀nà jíjìn àti gbígbòòrò sí àwọn arákùnrin wa tókù ní gbogbo àwọn agbègbè ìlú Israẹli àti pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn nínú ìlú wọn àti pápá oko tútù, láti wá kó ara wọn jọ pọ̀ sọ́dọ̀ wa. 3Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa padà sọ́dọ̀ wa, nítorí wí pé àwa kò ṣe ìwádìí nípa rẹ̀ ní àsìkò ìjọba Saulu. 4Gbogbo ìjọ náà sì gbà láti ṣe èyí nítorí ó dàbí wí pé ó tọ lójú gbogbo àwọn ènìyàn.

5Nígbà náà ni Dafidi pe gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ, láti ọ̀dọ̀ Ṣihori ní Ejibiti lọ sí Lebo ní ọ̀nà à bá wọ Hamati, láti gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run padà láti Kiriati-Jearimu. 6Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ lọ sí Baalahi ti Juda (Kiriati-Jearimu) láti gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run Olúwa tí a fi orúkọ rẹ̀ pè, tí ó jókòó láàrín kérúbù—gòkè wá.

7Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run láti ilé Abinadabu lórí kẹ̀kẹ́ tuntun, Ussa àti Ahio ń ṣọ́ ọ. 8Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ni wọ́n ṣe àjọyọ̀ pẹ̀lú gbogbo agbára wọn níwájú Ọlọ́run, pẹ̀lú orin àti pẹ̀lú dùùrù, ohun èlò orin olókùn, tambori, kimbali pẹ̀lú ìpè.

9Nígbà tí wọ́n dé sí ilẹ̀ ìpakà Kidoni, Ussa sì na ọwọ́ rẹ̀ síta láti di àpótí ẹ̀rí Olúwa mú, nítorí màlúù kọsẹ̀. 10Ìbínú Olúwa, sì ru sí Ussa, ó sì lù ú bolẹ̀ nítorí o ti fi ọwọ́ rẹ̀ lórí àpótí ẹ̀rí. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kú síbẹ̀ níwájú Ọlọ́run.

11Nígbà náà Dafidi sì bínú nítorí ìbínú Olúwa ké jáde lórí Ussa, àti títí di òní, wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Pereṣi-Uṣa.

12Dafidi sì bẹ̀rù Ọlọ́run ní ọjọ́ náà, ó sì béèrè pé, Báwo ni èmi náà ó ṣe gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ mi? 13Kò gbé àpótí ẹ̀rí náà wá sí ọ̀dọ̀ ará rẹ̀ ní ìlú ti Dafidi dípò èyí, ó sì gbé e yà sí ilé Obedi-Edomu ará Gitti. 14Àpótí ẹ̀rí Olúwa sì wà lọ́dọ̀ àwọn ará ilé Obedi-Edomu ní ilé rẹ̀ fún oṣù mẹ́ta, Olúwa sì bùkún agbo ilé àti gbogbo ohun tí ó ní.