希伯來書 8 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

希伯來書 8:1-13

更美之約的大祭司

1我們所講的要點是:我們有這樣一位大祭司,祂現在已經坐在天上至高上帝的寶座右邊, 2並在聖所裡供職。這聖所就是真正的聖幕,不是人建立的,而是主親手建立的。 3所有的大祭司都是為了向上帝獻禮物和祭物而設立的,因此我們這位大祭司也必須有所獻上。 4祂如果是在地上,根本不會做祭司,因為地上已經有照律法向上帝獻禮物的祭司了。 5這些祭司的事奉都是仿效和反映天上的事,正如摩西建聖幕的時候,上帝指示他說:

「你務要照著在山上指示你的樣式造各樣的器具。」

6但如今,基督得到了一個更超越的職任,正如祂擔任了更美之約的中保,這約是根據更美的應許所立的。 7因為如果第一個約沒有缺點,就不必另立新約了。 8然而,上帝指責祂的百姓,說:

「看啊,時候將到,

我要與以色列家和猶大家另立新約,

9這約不同於我與他們祖先所立的約,

就是我牽著他們祖先的手領他們離開埃及時所立的。

因為他們不持守我的約,

所以我不再理會他們。

這是主說的。

10主又說,那些日子以後,

我將與以色列家立這樣的約,

我要把我的律法放在他們腦中,

寫在他們心上。

我要作他們的上帝,

他們要作我的子民。

11誰都無需再教導自己的鄰居和弟兄,

說,『你要認識主。』

因為他們無論尊卑都必認識我。

12我要赦免他們的過犯,

忘掉他們的罪惡。」

13上帝既然說要立新約,就是把以前的約當作舊的了,那漸漸過時、陳舊的東西很快就會消失。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Heberu 8:1-13

Olórí àlùfáà ti májẹ̀mú tuntun

18.1: Sm 110.1.Nísinsin yìí, kókó ohun tí à ń sọ nìyí: Àwa ní irú olórí àlùfáà bẹ́ẹ̀, tí ó jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún ìtẹ́ Ọláńlá nínú àwọn ọ̀run: 2ìránṣẹ́ ibi mímọ́, àti ti àgọ́ tòótọ́, tí Olúwa pa, kì í ṣe ènìyàn.

3Nítorí a fi olórí àlùfáà kọ̀ọ̀kan jẹ láti máa mú ẹ̀bùn wá láti máa rú ẹbọ: Nítorí náà ó ṣe pàtàkì fún eléyìí náà láti ní nǹkan tí ó máa fi sílẹ̀. 4Tí ó bá jẹ́ pé ó wà ní ayé ni, òun kì bá ti jẹ́ àlùfáà, nítorí pé àwọn ọkùnrin tí ó ń fi ẹ̀bùn sílẹ̀ ti wà bí òfin ṣe là á sílẹ̀. 58.5: Ek 25.40.Àwọn ẹni tí ń jọ́sìn nínú pẹpẹ kan tí ó jẹ́ àpẹẹrẹ àti òjìji ohun tí ń bẹ ní ọ̀run. Ìdí abájọ nìyí tí a fi kìlọ̀ fún Mose nígbà tí ó fẹ́ kọ́ àgọ́: Nítorí ó wí pé, “Kíyèsí i, kí ìwọ kí ó ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ wọn, ti a fi hàn ọ́ ni orí òkè.” 6Ṣùgbọ́n nísinsin yìí o ti gba iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ó ni ọlá jù, níwọ̀n bí o ti jẹ pé alárinà májẹ̀mú tí o dára jù ní i ṣe, èyí tí a fi ṣe òfin lórí ìlérí tí o sàn jù bẹ́ẹ̀ lọ.

7Nítorí ìbá ṣe pé májẹ̀mú ìṣáájú nì kò ní àbùkù, ǹjẹ́ a kì bá ti wá ààyè fún èkejì. 88.8-12: Jr 31.31-34.Nítorí tí ó rí àbùkù lára wọn, ó wí pé,

“Ìgbà kan ń bọ̀, ni Olúwa wí,

tí Èmi yóò bá ilé Israẹli

àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.

9Kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú

tí mo ti bá àwọn baba baba wọn dá,

nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́ láti mú wọn jáde

kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, nítorí wọn kò jẹ́ olóòtítọ́ sí májẹ̀mú mi

èmi kò sì ta wọ́n nu, ni Olúwa wí

10Nítorí èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli

dá lẹ́yìn àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, ni Olúwa wí.

Èmi ó fi òfin mi sí inú wọn,

èmi ó sì kọ wọ́n sí ọkàn wọn,

èmi ó sì máa jẹ́ Ọlọ́run fún wọn,

wọn ó sì máa jẹ́ ènìyàn fún mi.

11Olúkúlùkù kò ní tún máa kọ́ ara ìlú rẹ̀,

tàbí olúkúlùkù arákùnrin rẹ̀, pé, ‘mọ Olúwa,’

Nítorí pé gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí,

láti kékeré dé àgbà.

12Nítorí pé èmi ó ṣàánú fún àìṣòdodo wọn,

àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn àti àìṣedéédéé wọn lèmi ki yóò sì rántí mọ́.”

13Ní èyí tí ó wí pé, májẹ̀mú títún ó ti sọ ti ìṣáájú di ti láéláé. Ṣùgbọ́n èyí tí ó ń di i ti láéláé tí ó sì ń gbó, o múra àti di asán.