列王紀上 5 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

列王紀上 5:1-18

預備建造聖殿

1泰爾希蘭素來與大衛修好,他聽說以色列人膏立了所羅門繼承大衛的王位,就遣使者來見所羅門2所羅門也派人去見希蘭,說: 3「你知道,我父大衛因周圍戰事連連,未能為他的上帝耶和華建殿,要等到耶和華使仇敵伏在他腳下後再建。 4現在我的上帝耶和華使我四境太平,內外無憂, 5我想為我的上帝耶和華建殿,因為耶和華曾對我父大衛說,『我必使你的兒子繼承你的王位,他必為我的名建殿。』 6請你命人為我砍伐黎巴嫩的香柏木。我會派人幫助你的人,並按你的要求付你的人工錢。因為你知道,我們沒有人像西頓人那樣善於砍伐樹木。」

7希蘭聽了所羅門的話後,非常高興,說:「今天當讚美耶和華!祂賜給大衛一個有智慧的兒子治理這偉大的民族。」 8他派人回覆所羅門說:「我已收到你派人帶來的口信。我一定會照你的心願提供香柏木和松木。 9我的工人會將這些木料從黎巴嫩紮成木筏,經海道運到你指定的地點。木筏拆散以後,你就可以點收了。你也要成全我的心願,供應我家食糧。」 10於是,希蘭供應所羅門需用的香柏木和松木, 11所羅門每年供應希蘭四百四十萬升麥子和四千四百升橄欖油。 12耶和華照著應許賜給所羅門智慧。他跟希蘭修好,締結盟約。

13所羅門王從以色列徵集了三萬勞工, 14派他們每月輪班到黎巴嫩工作,每班一萬人,在黎巴嫩一個月,在家兩個月。亞多尼蘭做他們的總管。 15所羅門又徵用了七萬名搬運工,八萬名在山上鑿石的匠人。 16此外,他還派了三千三百名監工,監督工人做工。 17他們按照王的命令在山上鑿出珍貴的巨石,用來作殿的根基。 18於是,所羅門希蘭的工匠及迦巴勒人鑿好石頭,備好木料,準備建殿。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Ọba 5:1-18

Ìmúrasílẹ̀ láti kọ́ ilé fún Olúwa

1Nígbà tí Hiramu ọba Tire sì gbọ́ pé, a ti fi òróró yan Solomoni ní ọba ní ipò Dafidi baba rẹ̀, ó sì rán àwọn ikọ̀ rẹ̀ sí Solomoni, nítorí ó ti fẹ́ràn Dafidi ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo. 25.2-11: 2Ki 2.3-16.Solomoni sì ránṣẹ́ yìí padà sí Hiramu pé:

3“Ìwọ mọ̀ pé Dafidi baba mi kò le kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, nítorí ogun tí ó wà yí i káàkiri, títí Olúwa fi fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀. 4Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run mi ti fún mi ní ìsinmi ní ibi gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni kò sì sí ọ̀tá tàbí ìjàǹbá kan tí ó ṣe. 55.5: 2Ki 2.1.Nítorí náà mo gbèrò láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi, bí Olúwa ti sọ fún Dafidi baba mi, nígbà tí ó wí pé, ‘Ọmọ rẹ tí èmi yóò gbé ka orí ìtẹ́ rẹ ní ipò rẹ ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’

6“Nítorí náà ni kí o pàṣẹ pé kí wọn kí ó gé igi kedari Lebanoni fún mi wá. Àwọn ènìyàn mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú tìrẹ, Èmi yóò sì san owó ọ̀yà tí ìwọ bá ránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn rẹ. Ìwọ mọ̀ pé, a kò ní ẹnìkan nínú wa tí ó mọ bí a ti ń gé igi bí àwọn ará Sidoni.”

7Nígbà tí Hiramu sì gbọ́ iṣẹ́ Solomoni, inú rẹ̀ sì dùn gidigidi, ó sì wí pé, “Ògo ni fún Olúwa lónìí, nítorí tí ó ti fún Dafidi ní ọlọ́gbọ́n ọmọ láti ṣàkóso àwọn ìlú ńlá yìí.”

8Hiramu sì ránṣẹ́ sí Solomoni pé:

“Èmi ti gbọ́ iṣẹ́ tí ìwọ rán sí mi, èmi yóò sì ṣe gbogbo èyí tí o fẹ́ ní pípèsè igi kedari àti ní ti igi firi. 9Àwọn ènìyàn mi yóò mú igi náà sọ̀kalẹ̀ láti Lebanoni wá sí Òkun, èmi ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí ọ ní fífò lójú omi Òkun títí dé ibi tí ìwọ ó na ìka sí fún mi. Níbẹ̀ ni èmi yóò ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ìwọ yóò sì kó wọn lọ. Ìwọ yóò sì gba ìfẹ́ mi nípa pípèsè oúnjẹ fún ilé mi.”

10Báyìí ni Hiramu sì pèsè igi kedari àti igi firi tí Solomoni ń fẹ́ fún un, 11Solomoni sì fún Hiramu ní ẹgbàáwàá (20,000) òṣùwọ̀n ọkà oúnjẹ fún ilé rẹ̀, àti ogún (20) òṣùwọ̀n òróró dáradára. Solomoni sì ń tẹ̀síwájú láti ṣe èyí fún Hiramu lọ́dọọdún. 12Olúwa sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún un. Ìrẹ́pọ̀ àlàáfíà sì wà láàrín Hiramu àti Solomoni, àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn.

13Solomoni ọba sì ṣa asìnrú ènìyàn jọ ní gbogbo Israẹli; àwọn tí ń sìnrú náà jẹ́ ẹgbàá-mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ènìyàn (30,000). 14Ó sì rán wọn lọ sí Lebanoni, ẹgbàárùn-ún (10,000) lóṣooṣù, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n lo oṣù kan ní Lebanoni, wọn a sì gbé ilé ní oṣù méjì. Adoniramu ni ó ṣe olórí àwọn asìnrú náà. 155.15,16: 2Ki 2.2,18.Solomoni sì ní ẹgbàá-márùn-dínlógójì (70,000) ènìyàn tí ń ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin (80,000) gbẹ́nàgbẹ́nà lórí òkè, 16àti àwọn ìjòyè nínú àwọn tí a fi ṣe olórí iṣẹ́ Solomoni jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún ó-lé-ọgọ́rùn-ún (3,300) ènìyàn, tí ó ń ṣe aláṣẹ àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ náà. 17Ọba sì pàṣẹ, wọ́n sì mú òkúta wá, òkúta iyebíye, àti òkúta gbígbẹ́ láti fi ìpìlẹ̀ ilé náà lé ilẹ̀. 18Àwọn oníṣọ̀nà Solomoni àti Hiramu àti àwọn òṣìṣẹ́ láti Gebali sì gbẹ́ wọn, wọ́n sì pèsè igi àti òkúta láti fi kọ́ ilé náà.