雅各书 4 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

雅各书 4:1-17

不要与世俗为友

1你们彼此冲突、互相斗殴的起因是什么呢?不就是你们身体中不断交战的欲望吗? 2你们贪心,得不到就去杀人。你们嫉妒,得不到就争吵、打斗。你们得不到是因为你们不向上帝祈求。 3你们求也得不到是因为你们动机不纯,只求享乐和满足自己的欲望。 4你们这些对主不忠的人啊,难道还不明白与世俗为友就是与上帝为敌吗?所以,凡是与世俗为友的,都是上帝的敌人。 5圣经上说:“上帝所赐、住在我们心里的圣灵深愿我们完全属于祂。”你们以为这是空谈吗? 6但上帝赐给我们更大的恩典,所以圣经上说:“上帝阻挡骄傲的人,恩待谦卑的人。”

7因此,你们要服从上帝,抵挡魔鬼,魔鬼必逃离你们。 8你们亲近上帝,上帝就必亲近你们。有罪的人啊,洗净你们的手吧!三心二意的人啊,洁净你们的心吧! 9你们要悲伤、忧愁、痛哭,转欢笑为悲哀,变欢乐为愁苦。 10你们要在主面前谦卑,祂必擢升你们。

不要论断

11弟兄姊妹,不要彼此批评。批评、论断弟兄姊妹就等于是批评、论断律法。如果你论断律法,你就不是遵行律法的人,而是以审判者自居。 12设立律法和审判人的只有一位,就是能拯救人也能毁灭人的上帝。你是谁,竟然论断别人呢?

警戒自夸

13你们有些人说:“今天或是明天,我们要往某某城去,在那里逗留一年半载,做生意赚钱。” 14其实你们根本不知道明天会发生什么事。你们的生命是什么呢?你们只不过像一阵雾气,出现片刻,就无影无踪了。 15你们只当说:“如果主许可,我们就可以活着,可以做这事或做那事。” 16现在,你们竟敢傲慢自夸,这实属邪恶。 17所以人若知道善而不去行,就是犯罪。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jakọbu 4:1-17

Ìyọ̀ǹda ara ẹni fún Ọlọ́run

1Níbo ni ogun ti wá, níbo ni ìjà sì ti wá láàrín yín? Ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara yín ha kọ́ ni tí ó ń jagun nínú àwọn ẹ̀yà ara yín bí? 2Ẹ̀yin ń fẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, ẹ kò sì ní: ẹ̀yin ń pànìyàn, ẹ sì ń ṣe ìlara, ẹ kò sì le ní: ẹ̀yin ń jà, ẹ̀yin sì ń jagun; ẹ kò ní, nítorí tí ẹ̀yin kò béèrè. 3Ẹ̀yin béèrè, ẹ kò sì rí gbà, nítorí tí ẹ̀yin ṣì béèrè, kí ẹ̀yin kí ó lè lò ó fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara yín.

4Ẹ̀yin panṣágà ọkùnrin, àti panṣágà obìnrin, ẹ kò mọ̀ pé ìbárẹ́ ayé ìṣọ̀tá Ọlọ́run ni? Nítorí náà ẹni tí ó bá fẹ́ láti jẹ́ ọ̀rẹ́ ayé di ọ̀tá Ọlọ́run. 5Ẹ̀yin ṣe bí Ìwé mímọ́ sọ lásán pé, Ẹ̀mí tí ó fi sínú wa ń jowú gidigidi lórí wa? 64.6: Òw 3.34.Ṣùgbọ́n ó fún ni ní oore-ọ̀fẹ́ sí i. Nítorí náà ni ìwé mímọ́ ṣe wí pé,

“Ọlọ́run kọ ojú ìjà sí àwọn agbéraga,

ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún àwọn onírẹ̀lẹ̀ ọkàn.”

7Nítorí náà, ẹ tẹríba fún Ọlọ́run. Ẹ kọ ojú ìjà sí èṣù, òun ó sì sá kúrò lọ́dọ̀ yín. 8Ẹ súnmọ́ Ọlọ́run, òun ó sì súnmọ́ yín. Ẹ wẹ ọwọ́ yín mọ́, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀; ẹ sì ṣe ọkàn yín ní mímọ́, ẹ̀yin oníyèméjì. 9Ẹ banújẹ́, ẹ ṣọ̀fọ̀, kí ẹ sì hu fún ẹkún. Ẹ jẹ́ kí ẹ̀rín yín kí ó di ọ̀fọ̀, àti ayọ̀ yín kí ó di ìbànújẹ́. 10Ẹ rẹ ara yín sílẹ̀ níwájú Olúwa, òun ó sì gbé yín ga.

11Ará, ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ ibi sí ara yín. Ẹni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ibi sí arákùnrin rẹ̀, tí ó ń dá arákùnrin rẹ̀ lẹ́jọ́, ó ń sọ̀rọ̀ ibi sí òfin, ó sì ń dá òfin lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n bí ìwọ bá ń dá òfin lẹ́jọ́, ìwọ kì í ṣe olùfẹ́ òfin, bí kò ṣe onídàájọ́. 12Aṣòfin àti onídàájọ́ kan ṣoṣo ní ó ń bẹ, àní ẹni tí ó lè gbàlà tí ó sì le parun, ṣùgbọ́n ta ni ìwọ tí ó ń dá ẹnìkejì rẹ lẹ́jọ́?

Má ṣe ìlérí nípa ọjọ́ ọ̀la

13Ẹ wá nísinsin yìí, ẹ̀yin tí ó ń wí pé, “Lónìí tàbí lọ́la àwa ó lọ sí ìlú báyìí, a ó sì ṣe ọdún kan níbẹ̀, a ó sì ṣòwò, a ó sì jèrè.” 14Nígbà tí ẹ̀yin kò mọ ohun tí yóò hù lọ́la. Kí ni ẹ̀mí yín? Ìkùùkuu sá à ni yín, tí ó hàn nígbà díẹ̀, lẹ́yìn náà a sì túká lọ. 15Èyí tí ẹ̀ bá fi wí pé, “Bí Olúwa bá fẹ́, àwa yóò wà láààyè, àwa ó sì ṣe èyí tàbí èyí i nì.” 16Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin ń gbéraga nínú ìfọ́nnu yín, gbogbo irú ìfọ́nnu bẹ́ẹ̀, ibi ni. 17Nítorí náà ẹni tí ó bá mọ rere í ṣe tí kò sì ṣe é, ẹ̀ṣẹ̀ ni fún un.